ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 5/96 ojú ìwé 7
  • Ọwọ́ Rẹ Ha Dí Jù Bí?

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ọwọ́ Rẹ Ha Dí Jù Bí?
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—1996
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • ‘Ẹ Jẹ Ki Awa Pẹlu Mú Gbogbo Ẹrù Wiwuwo Kuro’
    Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1991
  • Bí A Ṣe Lè Ra Àkókò Tí Ó Rọgbọ Padà
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—1996
  • Iwọ Ha Le Layọ Pẹlu Pupọ Lati Ṣe Bi?
    Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1991
  • Ṣé Ohun Ìdènà Ló Jẹ́ fún Iṣẹ́ Ìwàásù?
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2001
Àwọn Míì
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—1996
km 5/96 ojú ìwé 7

Ọwọ́ Rẹ Ha Dí Jù Bí?

1 Paul gbà wá níyànjú pé kí a “máa ní púpọ̀ rẹpẹtẹ lati ṣe nígbà gbogbo ninu iṣẹ́ Oluwa.” (1 Kor. 15:58) A rọ̀ wá láti ní ìtòlẹ́sẹẹsẹ ojoojúmọ́ fún ìdákẹ́kọ̀ọ́, kí a máa nípìn-ín nínú iṣẹ́ òjíṣẹ́, kí a má máa pa ìpàdé jẹ, kí a sì máa bojú tó àwọn iṣẹ́ tí a yàn fún wa nínú ìjọ taápọntaápọn. Ní àfikún sí ìwọ̀nyẹn, a ní láti pèsè ìrànwọ́ fún àwọn ẹlòmíràn tí wọ́n nílò ìrànlọ́wọ́ wa. Pẹ̀lú ọ̀pọ̀ rẹpẹtẹ láti ṣe a lè ní ìrẹ̀wẹ̀sì ọkàn, nígbà míràn, ní ríronú pé a ní láti wá ọ̀nà láti dín ẹrù iṣẹ́ wa kù.

2 Àwọn ipò kan wà tí ó lè mú kí ó bọ́gbọ́n mu, kí ó sì lọ́gbọ́n nínú láti gé àwọn ìgbòkègbodò pàtó kan kúrò tàbí kí a dín wọn kù. Àwọn ènìyàn kan máa ń rò pé gbogbo ohun tí àwọn ẹlòmíràn bá fẹ́ kí wọ́n ṣe ló yẹ kí wọ́n ṣe. Àìwàdéédéé lọ́nà yìí lè fa ìkìmọ́lẹ̀ àti ìdààmú ọkàn tí ó lè ṣàkóbá fún ẹnì kan lẹ́yìn-ọ̀-rẹyìn.

3 Jẹ́ Ẹni Tí Ó Wà Déédéé: Àṣírí wíwà déédéé ń bẹ nínú fífi ìmọ̀ràn Paulu tí ó sọ pé kí á “wádìí dájú awọn ohun tí ó ṣe pàtàkì jù,” sílò. (Filip. 1:10) Ní ṣókí, ìyẹn túmọ̀ sí pé a ní láti máa pọkàn pọ̀ sórí àwọn ohun tí ó ṣe pàtàkì ní ti gidi, tí àkókò bá sì yọ̀ǹda, kí a wá bojú tó àwọn ohun mìíràn tí kò fi bẹ́ẹ̀ ṣe pàtàkì. Ó dájú pé àwọn ojúṣe ìdílé gba ìpò iwájú nínú àwọn nǹkan tí ó ṣe kókó. A ní láti bójú tó àwọn ẹrù iṣẹ́ ti ara kan. Bí ó ti wù kí ó rí, Jesu kọ́ wa pé a ní láti gbé àwọn ohun tí ó gba ipò iwájú karí ọ̀pá ìdiwọ̀n pé à ń fi Ìjọba náà sí ipò kíní. A gbọ́dọ̀ kọ́kọ́ ṣe àwọn nǹkan tí yóò yọ̀ǹda fún wa láti mú ẹ̀jẹ́ ìyàsímímọ́ wa sí Jehofa ṣẹ.—Matt. 5:3; 6:33.

4 Tí a bá ní èyí lọ́kàn, a óò rí i dájú pé a gé gbogbo àwọn ìlépa ti ara ẹni tí kò pọn dandan, ìgbòkègbodò eré ìtura àṣejù, àti àwọn àdéhùn aláìníláárí pẹ̀lú àwọn ẹlòmíràn kúrò nínú ìtòlẹ́sẹẹsẹ wa tí ó dí pinpin. Tí a bá ń wéwèé ìgbòkègbodò wa fún ọ̀sẹ̀ kan, a óò ya àkókò tí ó pọ̀ tó sọ́tọ̀ fún ìdákẹ́kọ̀ọ́, ìkópa tí ó bójú mu nínú iṣẹ́ ìsìn, lílọ sí àwọn ìpàdé, àti àwọn nǹkan mìíràn tí ó ní í ṣe pẹ̀lú ìjọ́sìn wa. A lè pín àkókò tí ó ṣẹ́kù láti fi ṣe àwọn ohun mìíràn, ní sísinmi lórí bí wọ́n ti ṣe pàtàkì tó nínú jíjẹ́ kí ọwọ́ wa tẹ lájorí góńgó wa tí jíjẹ́ Kristian tí ó wà déédéé, tí ń fi Ìjọba náà sí ipò kíní.

5 Bí a bá tilẹ̀ ṣe gbogbo ìwọ̀nyí, a ṣì lè nímọ̀lára pé ẹrù wa ń wọ̀ wá lọ́rùn. Bí ó bá rí bẹ́ẹ̀, a ní láti tẹ́wọ́ gba ìkésíni Jesu pé: “Ẹ wá sọ́dọ̀ mi, gbogbo ẹ̀yin tí ń ṣe làálàá tí a sì di ẹrù wọ̀ lọ́rùn, dájúdájú emi yoo sì tù yín lára.” (Matt. 11:28) Bákan náà, gbẹ́kẹ̀ lé Jehofa, “ẹni tí ń bá wa gbé ẹrù wa lójoojúmọ́” tí ó sì ń fún aláàárẹ̀ ní agbára. Ó ṣèlérí pé òun kì yóò jẹ́ kí ẹsẹ̀ olódodo yẹ̀ láé. (Orin Da. 55:22, NW; 68:19; Isa. 40:29) A lè ní ìdánilójú pé yóò dáhùn àdúrà wa, yóò sì mú kí ó ṣeé ṣe fún wa láti tẹra mọ́ ìgbésí ayé aláápọn nínú ìgbòkègbodò ìṣàkóso Ọlọrun.

6 Bí ó ti dá wa lójú pé ọwọ́ wa yóò máa dí nínú lílépa àwọn ire Ìjọba tí ó níláárí, a lè rí ayọ̀ nínú mímọ̀ pé iṣẹ́ wa kì í ṣe asán ní ìsopọ̀ pẹ̀lú Oluwa.—1 Kor. 15:58.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́