ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 3/10 ojú ìwé 2
  • Iṣẹ́ Tó Ṣe Pàtàkì Jù Lọ

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Iṣẹ́ Tó Ṣe Pàtàkì Jù Lọ
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2010
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ṣé Ìwọ Náà Lè Sọ Àwọn Èèyàn Di Ọmọ Ẹ̀yìn?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2021
  • Máa Fìtara Wàásù Bíi Jésù
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2025
  • Ẹ Má Ṣe Jẹ́ Kí Iná Ìtara Yín fún Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Jó Rẹ̀yìn
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2007
  • Sísọ Orúkọ Ọlọ́run Di Mímọ̀
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2003
Àwọn Míì
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2010
km 3/10 ojú ìwé 2

Iṣẹ́ Tó Ṣe Pàtàkì Jù Lọ

1. Tá a bá ń ronú jinlẹ̀ lórí iṣẹ́ òjíṣẹ́ wa, kí ni èyí á mú ká ṣe?

1 Kí nìdí tí ètò Ọlọ́run fi ń fún wa níṣìírí láti máa lo àkókò wa, okun wa àti gbogbo ohun tá a ní lẹ́nu iṣẹ́ òjíṣẹ́ wa? Ìdí ni pé iṣẹ́ òjíṣẹ́ wa ni iṣẹ́ tó ṣe pàtàkì jù lọ! Tá a bá ronú lórí bí iṣẹ́ náà ṣe máa ń nípa lórí àwọn èèyàn tó, èyí á jẹ́ ká túbọ̀ fẹ́ nípìn-ín nínú iṣẹ́ tí a kò ní tún ṣe mọ́ yìí.—Ìṣe 20:24.

2. Ọ̀nà wo ni iṣẹ́ ìwàásù wa gbà ń sọ orúkọ títóbi lọ́lá Jèhófà di mímọ́?

2 Ó Ń Sọ Orúkọ Jèhófà Di Mímọ́: Iṣẹ́ ìwàásù wa ń jẹ́ káwọn èèyàn mọ̀ pé Ìjọba Jèhófà lábẹ́ ìdarí Kristi Jésù máa rọ́pò gbogbo ìjọba èèyàn, ó sì máa yanjú gbogbo ìṣòro tó ń bá ìran èèyàn fínra. (Mát. 6:9, 10) Ó ń gbé Jèhófà ga gẹ́gẹ́ bí ẹnì kan ṣoṣo tó lè dá wa sílẹ̀ kúrò lọ́wọ́ àìsàn àti ikú. (Aísá. 25:8; 33:24) Torí à ń jẹ́ orúkọ mọ́ Jèhófà, àwọn tó ń kíyè sí ìwà rere àti ìtara wa lè yìn ín lógo. (1 Pét. 2:12) Inú wa dùn gan-an pé à ń jẹ́ káwọn èèyàn mọ orúkọ Jèhófà Olúwa Ọba Aláṣẹ kárí ayé!—Sm. 83:18.

3. Àwọn ìbùkún wo làwọn tó bá fetí sí ìhìn rere Ìjọba Ọlọ́run máa rí gbà?

3 Ó Ń Gba Ẹ̀mí Là: Jèhófà “kò fẹ́ kí ẹnikẹ́ni pa run ṣùgbọ́n ó fẹ́ kí gbogbo ènìyàn wá sí ìrònúpìwàdà.” (2 Pét. 3:9) Àmọ́, tí kò bá sí ẹni tó máa kọ́ wọn, báwo ni àwọn èèyàn ṣe lè mọ ìwà tó tọ́ àti èyí tí kò tọ́ lójú Jèhófà? (Jónà 4:11; Róòmù 10:13-15) Nígbà táwọn èèyàn bá tẹ́wọ́ gba ìhìn rere, tí wọ́n sì jáwọ́ nínú àwọn àṣà tó lè pa wọ́n lára, ìgbé ayé wọn máa ń sunwọ̀n sí i. (Míkà 4:1-4) Láfikún sí i, wọ́n á wá ní ìrètí aláyọ̀, ìyẹn wíwà láàyè títí láé. Bá a ṣe ń fìtara wàásù tá a sì ń kọ́ni, a máa gba ara wa àtàwọn tó ń gbọ́ wa là. (1 Tím. 4:16) Àǹfààní ńlá gbáà la ní láti nípìn-ín nínú iṣẹ́ tó ṣe pàtàkì jù lọ yìí!

4. Kí nìdí tó fi yẹ ká máa fìtara kópa déédéé nínú iṣẹ́ ìwàásù àti sísọni di ọmọ ẹ̀yìn?

4 Láìpẹ́ ìpọ́njú ńlá máa mú òpin bá ayé aláìṣòdodo yìí lójijì. Àwọn tó bá ṣe ìfẹ́ Jèhófà ló máa yè bọ́. Ó dájú nígbà náà pé iṣẹ́ wíwàásù àti sísọni di ọmọ ẹ̀yìn ni iṣẹ́ kánjúkánjú, tó ṣe pàtàkì tó sì ṣàǹfààní jù lọ tá à ń ṣe lónìí. Ǹjẹ́ kí gbogbo wa kà á sí ohun tó ṣe pàtàkì jù lọ ní ìgbésí ayé wa!—Mát. 6:33.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́