ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • mwb16 February ojú ìwé 8
  • Pe Àwọn Èèyàn ní Ìpínlẹ̀ Ìwàásù Yín Wá sí Ìrántí Ikú Kristi!

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Pe Àwọn Èèyàn ní Ìpínlẹ̀ Ìwàásù Yín Wá sí Ìrántí Ikú Kristi!
  • Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Àwa Kristẹni​—Ìwé Ìpàdé (2016)
  • Ìsọ̀rí
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • OHUN TÓ O LÈ ṢE
  • Àwọn Ọ̀nà Ìgbọ́rọ̀kalẹ̀ Tá A Lè Lò
    Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Àwa Kristẹni​—Ìwé Ìpàdé (2016)
  • A Máa Pín Ìwé Ìkésíni Síbi Ìrántí Ikú Kristi Kárí Ayé!
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2010
  • Jèhófà Máa Ń Bù Kún Wa Tá A Bá Ṣe Ìrántí Ikú Kristi
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2023
  • A Máa Bẹ̀rẹ̀ Sí Í Pín Ìwé Ìkésíni Síbi Ìrántí Ikú Kristi Ní March 17
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2012
Àwọn Míì
Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Àwa Kristẹni​—Ìwé Ìpàdé (2016)
mwb16 February ojú ìwé 8

MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI

Pe Àwọn Èèyàn ní Ìpínlẹ̀ Ìwàásù Yín Wá sí Ìrántí Ikú Kristi!

Bíi Ti Orí Ìwé
Ìkésíni sí Ìrántí Ikú Kristi Ti Ọdún 2016

Tá a bá ti bẹ̀rẹ̀ sí í pín ìwé ìkésíni yìí láti February 27, a máa pe àwọn èèyàn ní ìpínlẹ̀ ìwàásù wa bó bá ti lè ṣeé ṣe tó ká lè jọ ṣe Ìrántí Ikú Kristi. Ó tún yẹ ká kíyè sí àwọn tá a bá sọ̀rọ̀, tí wọ́n nífẹ̀ẹ́ sí ọ̀rọ̀ wa, ká lè pa dà lọ bẹ̀ wọ́n wò.

OHUN TÓ O LÈ ṢE

O LÈ SỌ PÉ

“À ń fún àwọn èèyàn ní ìwé ìkésíni síbi ìṣẹ̀lẹ̀ pàtàkì kan. Ní March 23, ọ̀kẹ́ àìmọye èèyàn kárí ayé ló máa kóra jọ láti rántí ikú Jésù Kristi, kí wọ́n sì gbọ́ àsọyé Bíbélì kan lọ́fẹ̀ẹ́ tó dá lórí bí ikú Jésù ṣe ṣe wá láǹfààní. Ìwé ìkésíni yìí máa jẹ́ kẹ́ ẹ mọ ibi tá a ti máa ṣe é ládùúgbò wa àti àkókò tó máa wáyé. Ẹ jọ̀wọ́, a fẹ́ kẹ́ ẹ wá.”

Tí onílé bá nífẹ̀ẹ́ sí ọ̀rọ̀ rẹ . . .

  • FI ÌLÉ ÌṢỌ́ LỌ̀ Ọ́

    Sọ ohun tí wàá bá ẹni náà jíròrò nígbà tó o bá pa dà wá.

  • JẸ́ KÓ WO FÍDÍÒ ÌRÁNTÍ IKÚ KRISTI

    Sọ ohun tí wàá bá ẹni náà jíròrò nígbà tó o bá pa dà wá.

Tó o bá pa dà lọ bẹ̀ ẹ́ wò, o lè . . .

  • JẸ́ KÓ WO FÍDÍÒ KÍ NÌDÍ TÓ FI YẸ KÓ O KẸ́KỌ̀Ọ́ BÍBÉLÌ?

    Fi ìwé ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì kan lọ̀ ọ́.

  • FI ÌWÉ KÍ NI BÍBÉLÌ FI KỌ́NI GAN-AN? LỌ̀ Ọ́

    Fi àfikún àlàyé tó wà lójú ìwé 206 sí 208 ṣàlàyé púpọ̀ sí i nípa Ìrántí Ikú Kristi fún ẹni náà. Kó o sì fi ìwé náà lọ̀ ọ́.

  • FI ÌWÉ TẸ́TÍ SÍ ỌLỌ́RUN LỌ̀ Ọ́

    Bá onílé jíròrò ohun tí ikú Jésù mú kó ṣeé ṣe tó wà lójú ìwé 18 àti 19. Kó o sì fi ìwé náà lọ̀ ọ́.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́