ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 2/10 ojú ìwé 1
  • A Máa Pín Ìwé Ìkésíni Síbi Ìrántí Ikú Kristi Kárí Ayé!

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • A Máa Pín Ìwé Ìkésíni Síbi Ìrántí Ikú Kristi Kárí Ayé!
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2010
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • A Máa Pín Ìwé Ìkésíni Síbi Ìrántí Ikú Kristi Lákànṣe!
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2009
  • A Máa Pín Ìwé Ìkésíni Síbi Ìrántí Ikú Kristi Bẹ̀rẹ̀ Láti April 2
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2011
  • A Máa Bẹ̀rẹ̀ Sí Í Pín Ìwé Ìkésíni Síbi Ìrántí Ikú Kristi Ní March 17
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2012
  • A Máa Bẹ̀rẹ̀ Sí Í Pín Ìwé Ìkésíni Síbi Ìrántí Ikú Kristi Ní March 22
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2014
Àwọn Míì
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2010
km 2/10 ojú ìwé 1

A Máa Pín Ìwé Ìkésíni Síbi Ìrántí Ikú Kristi Kárí Ayé!

1. Ìpolongo àkànṣe wo la máa ṣe kárí ayé ká tó ṣe Ìrántí Ikú Kristi?

1 “Ẹ máa ṣe èyí ní ìrántí mi.” (Lúùkù 22:19) Láti ṣègbọràn sí àṣẹ Jésù yìí, àwa olùjọsìn Jèhófà pẹ̀lú àwọn olùfìfẹ́hàn máa péjọ ní March 30, ọdún 2010 láti ṣèrántí ikú Jésù. A máa pín àkànṣe ìwé ìkésíni síbi Ìrántí Ikú Kristi kárí ayé láti March 13 sí March 30.

2. Kí la lè sọ tá a bá fẹ́ fún àwọn èèyàn ní ìwé ìkésíni síbi Ìrántí Ikú Kristi?

2 Bá A Ṣe Máa Ṣe É: O lè fún ẹni tó o bá bá nílé ní ìwé náà kó bàa lè rí àwòrán tó wà lẹ́yìn rẹ̀, kó o wá sọ pé: “Nírọ̀lẹ́ March 30, àràádọ́ta ọ̀kẹ́ èèyàn kárí ayé máa péjọ láti ṣèrántí ikú Jésù. Ìdí rèé tí mo fi wá fún ìwọ àti ìdílé rẹ ní ìwé ìkésíni yìí kẹ́ ẹ lè wà níbẹ̀ lọ́jọ́ yẹn. Ẹ lè mú àwọn ọ̀rẹ́ yín dání pẹ̀lú. Jọ̀wọ́, wo àkókò àti ibi tá a ti máa ṣe é.” Bí àyè bá ṣe wà sí, o lè ka Lúùkù 22:19 láti fi àṣẹ tí Jésù pa nínú Ìwé Mímọ́ han onítọ̀hún. Àmọ́, ẹ má gbàgbé pé ìwọ̀nba àkókò díẹ̀ la ní láti kárí àwọn ìpínlẹ̀ ìwàásù wa, torí náà, á dáa ká jẹ́ kí ọ̀rọ̀ wa ṣe ṣókí.

3. Àwọn wo la lè pè?

3 Bí ìjọ yín bá ní ìpínlẹ̀ ìwàásù tó pọ̀, àwọn alàgbà lè sọ pé kẹ́ ẹ máa fi ìwé ìkésíni sílẹ̀ fáwọn tí ò sí nílé nígbà àkọ́kọ́ tẹ́ ẹ débẹ̀. Láwọn ìgbà tó bá yẹ bẹ́ẹ̀, ẹ tún lè fún àwọn èèyàn ní àwọn ìwé ìròyìn. Ẹ rí i dájú pé ẹ pe àwọn ìpadàbẹ̀wò yín, àwọn tẹ́ ẹ̀ ń kọ́ lẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì, àwọn tẹ́ ẹ jọ ń ṣiṣẹ́, àwọn ọmọléèwé yín, àwọn ìbátan yín, àwọn ará àdúgbò yín àtàwọn míì tẹ́ ẹ bá mọ̀.

4. Kí la máa ṣe tá a bá mọrírì bí Jèhófà ṣe fìfẹ́ pèsè ìràpadà fún wa?

4 Múra Tán Láti Kópa ní Kíkún: Àkókò Ìrántí Ikú Kristi jẹ́ ìgbà tó dáa gan-an tá a lè fi kún ìgbòkègbodò iṣẹ́ ìsìn wa. Ṣé o lè ṣètò àkókò rẹ kó o lè ṣe aṣáájú-ọ̀nà olùrànlọ́wọ́? Ṣé o láwọn ọmọ tàbí àwọn tó ò ń kọ́ lẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì tó ń ṣe dáadáa nípa tẹ̀mí? Tó bá rí bẹ́ẹ̀, o ò ṣe sọ fún àwọn alàgbà kí wọ́n lè wò ó bóyá àwọn ẹni tuntun náà ti tóótun láti di akéde tí kò tíì ṣe ìrìbọmi, káwọn náà bàa lè kópa nínú ìgbòkègbodò àkànṣe yìí. Bá a bá mọrírì bí Jèhófà ṣe fìfẹ́ pèsè ìràpadà fún wa, láfikún sí wíwá síbi Ìrántí Ikú Kristi, a máa tún sapá láti pe ọ̀pọ̀ èèyàn, bó bá ti lè ṣeé ṣe tó wá síbẹ̀.—Jòh. 3:16.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́