Ẹ̀KỌ́ 18
Báwo La Ṣe Ń Ṣèrànwọ́ fún Àwọn Ará Wa Tí Àjálù Bá?
Orílẹ̀-èdè Dominican Republic
Orílẹ̀-èdè Japan
Orílẹ̀-èdè Haiti
Tí àjálù bá ṣẹlẹ̀, ẹsẹ̀kẹsẹ̀ ni àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà máa ń ṣètò ìrànwọ́ tó máa mú kí ara tu àwọn ará wa tí àjálù bá. Irú ìrànwọ́ bẹ́ẹ̀ máa ń fi hàn pé ìfẹ́ tòótọ́ ló wà láàárín wa. (Jòhánù 13:34, 35; 1 Jòhánù 3:17, 18) Àwọn ìrànlọ́wọ́ wo la máa ń ṣe?
A máa ń fowó ṣèrànwọ́. Nígbà tí ìyàn ńlá mú ní Jùdíà, àwọn tó kọ́kọ́ di Kristẹni ní ìlú Áńtíókù fi owó ránṣẹ́ láti ṣèrànwọ́ fún àwọn ará wọn ní Jùdíà. (Ìṣe 11:27-30) Lọ́nà kan náà, tá a bá gbọ́ pé nǹkan nira fún àwọn ará wa láwọn apá ibì kan láyé, a máa ń fi owó ṣètìlẹyìn láwọn ìjọ wa, kí wọ́n lè fi pèsè àwọn nǹkan tí àwọn ará náà nílò lásìkò tí nǹkan nira fún wọn.—2 Kọ́ríńtì 8:13-15.
A máa ń pèsè ohun tí wọ́n nílò. Àwọn alàgbà tó bá wà níbi tí àjálù ti ṣẹlẹ̀ máa ń wá ẹnì kọ̀ọ̀kan nínú ìjọ kàn, láti rí i pé gbogbo wọn wà lálàáfíà. Ìgbìmọ̀ tó ń bójú tó ètò ìrànwọ́ máa ń ṣètò oúnjẹ, omi tó mọ́, aṣọ, ilé gbígbé, wọ́n sì ń bójú tó ìlera àwọn tọ́rọ̀ kàn. Ọ̀pọ̀ àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà tí wọ́n mọ iṣẹ́ tí wọ́n lè fi ṣàtúnṣe ibi tí àjálù bà jẹ́, máa ń ná owó ara wọn láti lọ ṣèrànwọ́ fún àwọn tí àjálù bá tàbí kí wọ́n lọ tún àwọn ilé àti Gbọ̀ngàn Ìjọba tó bà jẹ́ ṣe. Bá a ṣe wà níṣọ̀kan nínú ètò wa àti ìrírí tá a ti ní bá a ṣe ń ṣiṣẹ́ pa pọ̀ máa ń jẹ́ ká lè tètè kóra jọ láti ṣèrànwọ́ nígbà ìṣòro. Bí a ṣe ń ṣèrànwọ́ fún “àwọn tó bá wa tan nínú ìgbàgbọ́,” la tún ń ṣèrànwọ́ fún àwọn míì tó bá ṣeé ṣe, láìka ẹ̀sìn tí wọ́n ń ṣe sí.—Gálátíà 6:10.
A máa ń fi Ìwé Mímọ́ tu àwọn èèyàn nínú. Àwọn tí àjálù bá ṣẹlẹ̀ sí máa ń nílò ìtùnú gan-an. Nírú àkókò bẹ́ẹ̀, a máa ń rí okun gbà látọ̀dọ̀ Jèhófà, “Ọlọ́run ìtùnú gbogbo.” (2 Kọ́ríńtì 1:3, 4) Inú wa máa ń dùn láti sọ àwọn ìlérí Ọlọ́run tó wà nínú Bíbélì fún àwọn tí ìdààmú bá, à ń mú un dá wọn lójú pé láìpẹ́ Ìjọba Ọlọ́run máa fòpin sí gbogbo àjálù tó ń fa ìrora àti ìjìyà bá aráyé.—Ìfihàn 21:4.
Kí ló mú kó ṣeé ṣe fún àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà láti máa tètè ṣèrànwọ́ nígbà tí àjálù bá ṣẹlẹ̀?
Ẹsẹ Ìwé Mímọ́ wo la lè fi sọ̀rọ̀ ìtùnú fún àwọn tó yè bọ́ nínú àjálù?