ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • T-33 ojú ìwé 1-4
  • Ta Ló Ń Darí Ayé Yìí?

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ta Ló Ń Darí Ayé Yìí?
  • Ta Ló Ń Darí Ayé Yìí?
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Kí Ló Máa Ṣẹlẹ̀ Lọ́jọ́ Ọ̀la?
    Kí Ló Máa Ṣẹlẹ̀ Lọ́jọ́ Ọ̀la?
  • Kí Ni Ìjọba Ọlọ́run?
    Kí ni Ìjọba Ọlọ́run?
  • Ǹjẹ́ Àwọn Òkú Lè Jíǹde?
    Ǹjẹ́ Àwọn Òkú Lè Jíǹde?
  • Ǹjẹ́ Ìyà Lè Dópin?
    Ǹjẹ́ Ìyà Lè Dópin?
Àwọn Míì
Ta Ló Ń Darí Ayé Yìí?
T-33 ojú ìwé 1-4

Ta Ló Ń Darí Ayé Yìí?

Ṣé o rò pé . . .

  • Ọlọ́run ni?

  • àbí àwọn èèyàn?

  • àbí ẹlòmíì?

OHUN TÍ BÍBÉLÌ SỌ

“Gbogbo ayé patapata wà lábẹ́ Èṣù.”​—1 Jòhánù 5:19.

“Ọmọ Ọlọrun . . . wá, kí ó lè pa àwọn iṣẹ́ Èṣù run.”​—1 Jòhánù 3:8, Bíbélì Ìròyìn Ayọ̀.

ÀǸFÀÀNÍ TÓ O MÁA RÍ

Á jẹ́ kó o mọ àlàyé tó bọ́gbọ́n mu nípa ohun tó fa ìṣòro tó kún inú ayé yìí.​—Ìfihàn 12:12.

Wàá mọ ìdí tó fi yẹ kó o gbà gbọ́ pé ayé yìí ṣì ń bọ̀ wá dáa.​—1 Jòhánù 2:17.

Sátánì ń darí ètò ìṣèlú, àwọn ológun, ẹ̀sìn àti àwọn èèyàn inú ayé

ṢÉ A LÈ GBA OHUN TÍ BÍBÉLÌ SỌ GBỌ́?

Bẹ́ẹ̀ ni. Mẹ́ta lára ìdí tó fi yẹ ká gba ọ̀rọ̀ Bíbélì gbọ́ rèé:

  • Ọlọ́run máa fòpin sí àkóso Èṣù. Jèhófà ti pinnu pé òun ò ní jẹ́ kí Sátánì máa darí àwọn èèyàn mọ́. Ó ṣèlérí pé òun máa “sọ agbára Satani . . . di asán,” òun sì máa tún gbogbo ohun tí Sátánì ti bà jẹ́ ṣe.​—Hébérù 2:14, Bíbélì Ìròyìn Ayọ̀.

  • Ọlọ́run ti yan Jésù pé òun ló máa ṣàkóso ayé. Jésù yàtọ̀ pátápátá sí alákòóso ayé yìí tó jẹ́ ìkà, tí kò mọ̀ ju tara rẹ̀ lọ. Ọlọ́run ṣèlérí nípa àkóso Jésù pé: “Yóò ṣàánú aláìní àti tálákà . . . Yóò gbà wọ́n lọ́wọ́ ìnira àti ìwà ipá.”​—Sáàmù 72:13, 14.

  • Ọlọ́run kò lè parọ́. Bíbélì sọ ní kedere pé: ‘Ọlọ́run ò lè parọ́.’ (Hébérù 6:18) Tí Jèhófà bá ṣèlérí pé òun máa ṣe nǹkan kan, bíi pé ó ti ṣe é tán ló máa ń rí! (Àìsáyà 55:10, 11) “A máa lé alákòóso ayé yìí jáde.”​—Jòhánù 12:31.

RÒ Ó WÒ NÁ

Ìdílé aláyọ̀ kan jọ ń ṣeré níta

Tí ẹni tó ń ṣàkóso ayé yìí bá kúrò, báwo ni nǹkan ṣe máa rí?

Bíbélì dáhùn ìbéèrè yìí nínú ìwé SÁÀMÙ 37:10, 11 àti ÌFIHÀN 21:3, 4.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́