ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • T-36 ojú ìwé 1-2
  • Kí Ni Ìjọba Ọlọ́run?

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Kí Ni Ìjọba Ọlọ́run?
  • Kí ni Ìjọba Ọlọ́run?
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Kí Ló Máa Ṣẹlẹ̀ Lọ́jọ́ Ọ̀la?
    Kí Ló Máa Ṣẹlẹ̀ Lọ́jọ́ Ọ̀la?
  • Ta Ló Ń Darí Ayé Yìí?
    Ta Ló Ń Darí Ayé Yìí?
  • Ǹjẹ́ Àwọn Òkú Lè Jíǹde?
    Ǹjẹ́ Àwọn Òkú Lè Jíǹde?
  • Ǹjẹ́ Ìyà Lè Dópin?
    Ǹjẹ́ Ìyà Lè Dópin?
Àwọn Míì
Kí ni Ìjọba Ọlọ́run?
T-36 ojú ìwé 1-2
Oríṣiríṣi èèyàn ń gbàdúrà pé kí Ìjọba Ọlọ́run dé

Kí Ni Ìjọba Ọlọ́run?

Ṣé o rò pé . . .

  • ohun tó wà lọ́kàn èèyàn ni?

  • àbí àkànlò èdè?

  • àbí ìjọba kan ní ọ̀run?

OHUN TÍ BÍBÉLÌ SỌ

“Ọlọ́run ọ̀run máa gbé ìjọba kan kalẹ̀, tí kò ní pa run láé.”​—Dáníẹ́lì 2:44, Bíbélì Ìtumọ̀ Ayé Tuntun.

“A ti fún wa ní ọmọkùnrin kan; ìjọba sì máa wà ní èjìká rẹ̀.”​—Àìsáyà 9:6; àlàyé ìsàlẹ̀.

ÀǸFÀÀNÍ TÓ O MÁA RÍ

  • Ìjọba kan tó ń fi òdodo ṣàkóso tó máa ṣe ìwọ fúnra rẹ láǹfààní.​—Àìsáyà 48:17, 18.

  • Nínú ayé tuntun tó ń bọ̀, gbogbo èèyàn máa ní ìlera tó pé, wọ́n á sì láyọ̀.​—Ìfihàn 21:3, 4.

Àwọn èèyàn ń kórè, wọ́n sì ń gbádùn ara wọn nínú párádísè orí ilẹ̀ ayé lábẹ́ Ìjọba Ọlọ́run

ṢÉ A LÈ GBA OHUN TÍ BÍBÉLÌ SỌ GBỌ́?

Bẹ́ẹ̀ ni. Méjì lára ìdí tó fi yẹ ká gba ọ̀rọ̀ Bíbélì gbọ́ rèé:

  • Jésù jẹ́ ká rí ohun tí Ìjọba Ọlọ́run máa ṣe fún aráyé. Jésù kọ́ àwọn ọmọlẹ́yìn rẹ̀ kí wọ́n máa gbàdúrà pé kí Ìjọba Ọlọ́run dé, kí àwọn èèyàn sì máa ṣe ìfẹ́ Ọlọ́run ní ayé. (Mátíù 6:9, 10) Jésù ṣe ohun tó jẹ́ ká rí bí Ọlọ́run ṣe máa dáhùn àdúrà yẹn.

    Nígbà tí Jésù wà láyé, ó bọ́ àwọn tí ebi ń pa, ó mú àwọn aláìsàn lára dá, ó sì jí òkú dìde! (Mátíù 15:29-38; Jòhánù 11:38-44) Torí pé Jésù ló máa jẹ́ Ọba Ìjọba Ọlọ́run, ó jẹ́ ká rí ohun tí Ìjọba náà máa ṣe fún àwọn ọmọ abẹ́ rẹ̀.​—Ìfihàn 11:15.

  • Àwọn ohun tó ń ṣẹlẹ̀ láyé báyìí jẹ́ ẹ̀rí pé Ìjọba Ọlọ́run kò ní pẹ́ dé. Jésù sọ tẹ́lẹ̀ pé tó bá kù díẹ̀ kí Ìjọba Ọlọ́run mú kí àlàáfíà jọba ní ayé, ogun, ìyàn àti ìmìtìtì ilẹ̀ kò ní jẹ́ kí aráyé gbádùn.​—Mátíù 24:3, 7.

    Ohun tí à ń rí tó ń ṣẹlẹ̀ gan-an nínú ayé báyìí nìyẹn. Torí náà, ó dá wa lójú pé Ìjọba Ọlọ́run máa tó fòpin sí gbogbo ìṣòro yìí.

RÒ Ó WÒ NÁ

Ìjọba Ọlọ́run ń ṣàkóso lórí ayé tó rẹwà

Báwo ni ìgbésí ayé ṣe máa rí tí Ìjọba Ọlọ́run bá ń ṣàkóso?

Bíbélì dáhùn ìbéèrè yìí nínú ìwé SÁÀMÙ 37:29 àti ÀÌSÁYÀ 65:21-23.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́