ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • T-34 ojú ìwé 1-2
  • Ǹjẹ́ Ìyà Lè Dópin?

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ǹjẹ́ Ìyà Lè Dópin?
  • Ǹjẹ́ Ìyà Lè Dópin?
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Kí Ló Máa Ṣẹlẹ̀ Lọ́jọ́ Ọ̀la?
    Kí Ló Máa Ṣẹlẹ̀ Lọ́jọ́ Ọ̀la?
  • Ǹjẹ́ Àwọn Òkú Lè Jíǹde?
    Ǹjẹ́ Àwọn Òkú Lè Jíǹde?
  • Kí Ni Ìjọba Ọlọ́run?
    Kí ni Ìjọba Ọlọ́run?
  • Ta Ló Ń Darí Ayé Yìí?
    Ta Ló Ń Darí Ayé Yìí?
Àwọn Míì
Ǹjẹ́ Ìyà Lè Dópin?
T-34 ojú ìwé 1-2

Ǹjẹ́ Ìyà Lè Dópin?

Kí ni ìdáhùn rẹ?

  • Bẹ́ẹ̀ ni.

  • Bẹ́ẹ̀ kọ́.

  • Kò dá mi lójú.

OHUN TÍ BÍBÉLÌ SỌ

“Ọlọ́run yóò sì nu omijé gbogbo nù kúrò ní ojú wọn; kì yóò sì sí ikú mọ́, tàbí ọ̀fọ̀, tàbí ẹkún, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò sí ìrora mọ́.”​—Ìfihàn 21:4, Bíbélì Mímọ́.

ÀǸFÀÀNÍ TÓ O MÁA RÍ

Á jẹ́ kó dá ẹ lójú pé Ọlọ́run kọ́ ló ń fa àwọn ìṣòro wa.​—Jémíìsì 1:13.

Ara máa tù ẹ́ láti mọ̀ pé àánú wa máa ń ṣe Ọlọ́run tá a bá ń jìyà.​—Sekaráyà 2:8.

Ọkàn rẹ á balẹ̀ pé gbogbo ìyà máa dópin.​—Sáàmù 37:9-11.

Ọkùnrin kan tó ń ka Bíbélì ń fojú inú wo ìgbà tí kò ní sí ìyà àti ìwà ìrẹ́jẹ mọ́ láyé

ṢÉ A LÈ GBA OHUN TÍ BÍBÉLÌ SỌ GBỌ́?

Bẹ́ẹ̀ ni. Méjì lára ìdí tó fi yẹ ká gba ọ̀rọ̀ Bíbélì gbọ́ rèé:

  • Ọlọ́run ò fẹ́ ká máa jìyà, kò sì fẹ́ kí wọ́n rẹ́ wa jẹ. Wo bó ṣe rí lára Jèhófà Ọlọ́run nígbà tí àwọn kan fìyà jẹ àwọn èèyàn rẹ̀ láyé ìgbà tí wọ́n ń kọ Bíbélì. Bíbélì sọ pé inú Jèhófà kò dùn rárá nítorí “àwọn tó ń ni wọ́n lára.”​—Àwọn Onídàájọ́ 2:18, Bíbélì Ìtumọ̀ Ayé Tuntun.

    Ọlọ́run kórìíra àwọn tó ń ṣe ìkà sí ọmọnìkejì wọn. Bí àpẹẹrẹ, Bíbélì sọ pé Jèhófà kórìíra “ọwọ́ tó ń ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀.”​—Òwe 6:16, 17.

  • Ọlọ́run ń bójú tó ẹnì kọ̀ọ̀kan wa. Yàtọ̀ sí pé kálukú mọ “ìṣòro rẹ̀ àti ìrora rẹ̀,” Jèhófà náà mọ ohun tó ń bá ẹnì kọ̀ọ̀kan wa fínra.​—2 Kíróníkà 6:29, 30.

    Láìpẹ́, Jèhófà máa lo Ìjọba rẹ̀ láti fòpin sí gbogbo ìyà tó ń jẹ ẹnì kọ̀ọ̀kan wa. (Mátíù 6:9, 10) Àmọ́ ní báyìí, Jèhófà ń jẹ́ kí àwọn tó ń fi gbogbo ọkàn wá a rí ìtùnú.​—Ìṣe 17:27; 2 Kọ́ríǹtì 1:3, 4.

RÒ Ó WÒ NÁ

Àwọn obìnrin méjì ń kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì

Kí nìdí tí Ọlọ́run fi fàyè gba ìyà tó ń jẹ àwọn èèyàn?

Bíbélì dáhùn ìbéèrè yìí nínú ìwé RÓÒMÙ 5:12 àti 2 PÉTÉRÙ 3:9.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́