ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w95 5/15 ojú ìwé 3-4
  • Olóyè kan Ṣàyẹ̀wò Ọjọ́-Ọ̀la Rẹ̀

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Olóyè kan Ṣàyẹ̀wò Ọjọ́-Ọ̀la Rẹ̀
  • Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1995
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ibo Làwọn Baba Ńlá Wa Wà?
    Ọ̀nà Tó Lọ sí Ìyè Àìnípẹ̀kun—Ṣé O Ti Rí I?
  • Àwọn Òkú Ha Lè Rí Wa Bí?
    Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1994
  • Àwọn Wo Ní Ń Gbé Ilẹ̀ Ọba Ẹ̀mí?
    Jí!—1996
  • Kíkàn sí Ilẹ̀ Ọba ẹ̀mí
    Jí!—1996
Àwọn Míì
Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1995
w95 5/15 ojú ìwé 3-4

Olóyè kan Ṣàyẹ̀wò Ọjọ́-Ọ̀la Rẹ̀

OLÓYÈ náà ní Ìwọ̀-Oòrùn Africa jẹ́ olórí tí a fẹ́ràn gan-an tí a sì fún ní ọ̀wọ̀ tí ó jinlẹ̀ ní àdúgbò rẹ̀. Nígbà ọjọ́-ìbí ọdún kejìdínláàdọ́rín-in rẹ̀, àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀, àwọn ẹbí, àti àwọn afẹ́nifẹ́re mìíràn kórajọpọ̀ láti bá a yọ̀. Nínú àsọyé kan, olóyè náà yan ẹsin-ọ̀rọ̀ kan tí kò wọ́pọ̀ ní irú àṣeyẹ-àkànṣe bẹ́ẹ̀. Ó sọ̀rọ̀ nípa èrò rẹ̀ nípa ìwàláàyè lẹ́yìn ikú.

Ó sọ pé lẹ́yìn ayé yìí “ayé titun kan wà níbi tí kò ti sí ẹ̀tàn, ìlara àti ìwọra.” Ó ṣàpèjúwe rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ayé kan tí “a bo àwọn ohun ìjìnlẹ̀ mọ́lẹ̀ sí,” èyí tí kìkì àwọn olódodo ń gbé, tí wọn yóò ní ìbáṣepọ̀ pẹ̀lú Ọlọrun.

Irú ìgbàgbọ́ bẹ́ẹ̀ wọ́pọ̀ láàárín àwọn ènìyàn jákèjádò Africa. Ní ìbámu pẹ̀lú ìsìn àbáláyé Africa, ikú kì í ṣe òpin ìwàláàyè ṣùgbọ́n ó wulẹ̀ jẹ́ ìyípòpadà, kíkọjá lọ sí ìwàláàyè ní ilẹ̀-ọba ẹ̀mí. Nígbà ikú ẹni kan ni a máa ń sọ pé ó rékọjá lọ láti ayé tí a lè fojúrí sí èyí tí a kò lè fojúrí. Gẹ́gẹ́ bí ẹ̀mí, ẹni náà lẹ́yìn náá ti wọ pápá àkóso tí àwọn babańlá rẹ̀ ń gbé.

Ọ̀pọ̀ àwọn ará Ìwọ̀-Oòrùn Africa gbàgbọ́ pé àwọn babańlá, tàbí ẹ̀mí àwọn babańlá, ń mójútó ire-aásìkí àwọn ìdílé wọn lórí ilẹ̀-ayé. Ìwé náà West African Traditional Religion sọ pé: “Kò sí ìyàtọ̀ tí ó fẹsẹ̀múlẹ̀ nípa ipa ìdarí láàárín àwọn mẹ́ḿbà àwùjọ tí ó ṣì wà lórí ilẹ̀-ayé, àti ti àwọn wọnnì tí ó wà ní ayé tọ̀hún. Nígbà tí wọ́n wà níhìn-ín lórí ilẹ̀-ayé, [àwọn babańlá] jẹ́ alábòójútó ìdílé wọn. Nísinsìnyí tí a kò rí wọn mọ́, wọ́n ṣì jẹ́ alábòójútó nínú ayé àwọn ẹ̀mí. Wọn kò jáwọ́ nínú níní ọkàn-ìfẹ́ sí ire gbogbogbòò ti àwọn ìdílé wọn.”

Nítorí náà, àgbàlagbà olóyè tí a mẹ́nukàn lẹ́ẹ̀kan nírètí àti darapọ̀ mọ́ àwọn babańlá rẹ̀ kí ó sì ṣiṣẹ́ papọ̀ pẹ̀lú wọn nínú ilẹ̀-ọba ẹ̀mí. Ó sọ pé: “Mo ní ìdánilójú tí ó lágbára nínú ìwàláàyè lẹ́yìn ikú àti ṣíṣeéṣe náà pé n óò máa báa lọ láti ṣiṣẹ́sìn—àní pàápàá lẹ́yìn ikú.”

Bí ó ti wù kí ó rí, nítorí ohun tí olóyè náà sọ tẹ̀lé e, ìwé ìròyìn Sunday Times dábàá pé ó “dàbí pé kò ní ìdánilójú pátápátá” nípa ìwàláàyè lẹ́yìn ikú. Ó sọ fún àwọn èrò tí ó pésẹ̀ pé òun ti gbọ́ nípa ìwé kan tí ó sọ̀rọ̀ nípa ìwàláàyè lẹ́yìn ikú. Olóyè náà ti ń wá ìwé náà fún ọdún márùn-ún. Ó háragàgà láti kà á débi pé ó ṣetán láti san iye tí ó tó $1,500 (U.S.) fún ẹnikẹ́ni tí ó bá lè mú ẹ̀dà kan wá fún un.

Olóyè náà ìbá ti yọ ara rẹ̀ nínú ìjàngbọ̀n nípa wíwádìí láti inú ìwé kan tí kò ṣòro láti rí. Ó jẹ́ ìwé kan tí ó wà lárọ̀ọ́wọ́tó tí a kò ṣe láti ọwọ́ ènìyàn ṣùgbọ́n láti ọwọ́ Ẹlẹ́dàá gbogbo ènìyàn. (1 Tessalonika 2:13) Ìwé náà ni Bibeli. Kí ni ohun tí ó sọ nípa ìwàláàyè lẹ́yìn ikú?

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́