ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w11 10/1 ojú ìwé 3
  • Ǹjẹ́ Wọ́n Ti Parọ́ fún Ẹ Rí?

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ǹjẹ́ Wọ́n Ti Parọ́ fún Ẹ Rí?
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2011
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Àbájáde Irọ́ Àkọ́kọ́
    Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2020
  • Pétérù Parọ́, Ananíà Náà Parọ́​—⁠Ẹ̀kọ́ Wo Ni Èyí Kọ́ Wa?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2013
  • Eeṣe Ti Ó Fi Rọrùn Tobẹẹ Lati Purọ́
    Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1992
  • Kí Nìdí Tó Fi Yẹ Kó O Jẹ́ Olóòótọ́?
    Àwọn Ọ̀dọ́ Béèrè Pé
Àwọn Míì
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2011
w11 10/1 ojú ìwé 3

Ǹjẹ́ Wọ́n Ti Parọ́ fún Ẹ Rí?

ṢÀṢÀ nǹkan ló lè dunni tó kí ẹni tá a fọkàn tán purọ́ fúnni. Irú nǹkan bẹ́ẹ̀ lè dójú tini, ó lè múnú bíni tàbí kẹ̀, ó lè bani nínú jẹ́. Irọ́ máa ń ba àárín ọ̀rẹ́ àti tọkọtaya jẹ́, àwọn èèyàn sì máa ń purọ́ láti lu àwọn míì ní jìbìtì ọ̀kẹ́ àìmọye owó.

Wá fojú inú wo bó ṣe máa rí lára rẹ tí o bá mọ̀ pé ohun tí wọ́n sọ fún ẹ nípa Ọlọ́run kì í ṣe òótọ́. Tí o bá jẹ́ olùfọkànsin Ọlọ́run, ọ̀rọ̀ náà á dùn ẹ́ jù, gẹ́gẹ́ bó ṣe rí lára àwọn tó ń lọ sí ṣọ́ọ̀ṣì tí wọ́n sọ̀rọ̀ yìí:

● “Ó dùn mí gan-an nígbà tí mo mọ̀ pé irọ́ ni wọ́n ń pa fún mi ní ṣọ́ọ̀ṣì.”—DEANNE.

● “Inú bí mi. Wọ́n ti tàn mí jẹ, gbogbo ìrètí mi àti ohun tí mo fojú sùn ti já sí òfo.”—LUIS.

O lè má tètè gbà pé wọ́n lè sọ ohun tí kì í ṣe òótọ́ fún ẹ nípa Ọlọ́run. Ó lè jẹ́ àwọn òbí rẹ, àlùfáà kan, pásítọ̀ kan tàbí ọ̀rẹ́ rẹ àtàtà kan tí kò lè mọ̀ọ́mọ̀ ṣì ọ́ lọ́nà ló kọ́ ẹ ni nǹkan tó o mọ̀. O sì lè ní ohun tó o gbà gbọ́ látìbẹ̀rẹ̀ ayé rẹ. Àmọ́, ṣé o gbà pé ohun kan tí ọ̀pọ̀ èèyàn gbà gbọ́ lè jẹ́ irọ́? Ààrẹ orílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà nígbà kan rí, ìyẹn Franklin D. Roosevelt mọ̀ bẹ́ẹ̀, ó ní: “Kò sí bó o ṣe lè sọ ọ́ tó, irọ́ kò lè di òótọ́ láé.”

Báwo lo ṣe lè mọ̀ bóyá wọ́n ti purọ́ fún ẹ? Lákòókò kan tí Jésù ń gbàdúrà sí Ọlọ́run, ó sọ pé: “Òtítọ́ ni ọ̀rọ̀ rẹ.” (Jòhánù 17:17) Bẹ́ẹ̀ ni, Bíbélì Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ní àwọn ohun tí a lè fi dá òtítọ́ mọ̀ yàtọ̀ sí irọ́.

O ò ṣe kà nípa bí Bíbélì ṣe tú àṣírí irọ́ márùn-ún táwọn èèyàn sábà máa ń pa nípa Ọlọ́run? Wàá rí i bí òtítọ́ ṣe lè yí ìgbésí ayé rẹ pa dà sí rere.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́