ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 1/01 ojú ìwé 1
  • Máa Fetí Sílẹ̀ Dáadáa

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Máa Fetí Sílẹ̀ Dáadáa
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2001
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • “Ẹ Máa Fiyè sí Bí Ẹ Ṣe Ń Fetí Sílẹ̀”
    Jàǹfààní Nínú Ilé Ẹ̀kọ́ Ìjọba Ọlọ́run
  • Bí Jèhófà Ṣe Ń ṣamọ̀nà Wa
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2000
  • Ìpàdé Máa Ń Ṣe Àwọn Ọ̀dọ́ Láǹfààní
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2000
  • Báwo Ni Mo Ṣe Lè Máa Pọkàn Pọ̀?
    Jí!—1998
Àwọn Míì
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2001
km 1/01 ojú ìwé 1

Máa Fetí Sílẹ̀ Dáadáa

1 Fífetí sílẹ̀ dáadáa gba pé kí èèyàn lè kó ara rẹ̀ níjàánu. Ó tún gba pé kí ẹni tó ń fetí sílẹ̀ náà fẹ́ láti kẹ́kọ̀ọ́, kó sì jàǹfààní nínú ohun tó bá gbọ́. Nítorí náà, Jésù tẹnu mọ́ ọn pé ó ṣe pàtàkì láti “fiyè sí bí [a] ṣe ń fetí sílẹ̀.”—Lúùkù 8:18.

2 Èyí rí bẹ́ẹ̀ ní pàtàkì nígbà tí a bá lọ sí àwọn ìpàdé ìjọ, àpéjọ, àti àpéjọpọ̀. Àkókò tí a gbọ́dọ̀ fetí sílẹ̀ dáadáa nìwọ̀nyí. (Héb. 2:1) Ìwọ̀nyí ni àwọn kókó díẹ̀ tí yóò ràn ọ́ lọ́wọ́ láti máa fetí sílẹ̀ dáadáa ní àwọn àpéjọ Kristẹni.

◼ Mọrírì ìníyelórí àwọn ìpàdé. Wọ́n jẹ́ ọ̀nà pàtàkì kan tí ‘Jèhófà ń gbà kọ́’ wa nípasẹ̀ “olóòótọ́ ìríjú náà.”—Aísá. 54:13; Lúùkù 12:42.

◼ Múra sílẹ̀ ṣáájú. Yẹ ohun tí wọ́n máa jíròrò wò, sì rí i dájú pé o mú Bíbélì tìrẹ àti ìtẹ̀jáde tí a ń kẹ́kọ̀ọ́ dání.

◼ Nígbà tí ìpàdé bá ń lọ lọ́wọ́, sapá gidigidi láti pọkàn pọ̀. Yéé bá àwọn tó jókòó tì ọ́ sọ̀rọ̀, sì yéé wo nǹkan tí àwọn tó wà nínú àwùjọ ń ṣe. Má ṣe jẹ́ kí ìrònú nípa ohun tí o máa ṣe nígbà tí ìpàdé bá parí tàbí àwọn ọ̀ràn mìíràn tó jẹ́ tìrẹ mú kí ọkàn rẹ pínyà.

◼ Ṣe ìfọ́síwẹ́wẹ́ ohun tí wọ́n sọ. Bi ara rẹ pé: ‘Báwo lèyí ṣe kàn mí? Ìgbà wo ni màá fi í sílò?’

◼ Kọ àkọsílẹ̀ ṣókí nípa àwọn kókó pàtàkì àti àwọn ọ̀rọ̀ ẹsẹ Ìwé Mímọ́. Èyí yóò ràn ọ́ lọ́wọ́ láti pa ìrònú rẹ pọ̀ sórí ohun tí wọ́n ń jíròrò, yóò sì jẹ́ kí o lè rántí àwọn kókó pàtàkì nígbà tí o bá fẹ́ lò wọ́n.

3 Kọ́ Àwọn Ọmọ Rẹ Láti Máa Fetí Sílẹ̀: Ìtọ́ni tẹ̀mí ṣe pàtàkì fún àwọn ọmọ. (Diu. 31:12) Nígbà àtijọ́, “gbogbo àwọn tí ó ní làákàyè tó láti fetí sílẹ̀” láàárín àwọn èèyàn Ọlọ́run ló gbọ́dọ̀ tẹ́tí sílẹ̀ bí wọ́n ṣe ń ka Òfin Ọlọ́run sétíìgbọ́ wọn. (Neh. 8:1-3) Bí àwọn òbí bá ń fara balẹ̀ ní ìpàdé tí wọ́n sì ń fetí sílẹ̀ dáadáa, àwọn ọmọ wọn pẹ̀lú yóò ṣe bẹ́ẹ̀. Kò bọ́gbọ́n mu láti mú ohun ìṣeré tàbí ìwé àwòrán tí ọmọdé á máa kùn wá sí ìpàdé láti mú inú àwọn ọmọ dùn. Kí wọ́n máa lọ sí ilé ìgbọ̀nsẹ̀ ṣáá láìjẹ́ pé ó pọndandan kì í jẹ́ kí wọ́n fetí sílẹ̀ pẹ̀lú. Níwọ̀n bó ti jẹ́ pé “ọkàn-àyà ọmọdékùnrin ni ìwà òmùgọ̀ dì sí” àwọn òbí gbọ́dọ̀ sapá gidigidi láti rí i pé àwọn ọmọ wọn ń jókòó jẹ́ẹ́ tí wọ́n sì ń fetí sílẹ̀ ní àwọn ìpàdé.—Òwe 22:15.

4 Nípa fífetí sílẹ̀ dáadáa, a ń fi hàn pé a jẹ́ ọlọgbọ́n ní tòótọ́, a sì ń fẹ́ láti máa “gba ìtọ́ni púpọ̀ sí i.”—Òwe 1:5.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́