ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 11/01 ojú ìwé 1
  • “Ibo Ni Màá Ti Rí Àyè?”

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • “Ibo Ni Màá Ti Rí Àyè?”
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2001
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ríra Àkókò Padà Láti Kàwé Àti Láti Kẹ́kọ̀ọ́
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2000
  • Ìwọ Ha Ń Jẹun Kánú Nípa Tẹ̀mí Bí?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1997
  • Bí A Ṣe Lè Ra Àkókò Tí Ó Rọgbọ Padà
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—1996
  • Jẹ́ Kí Iṣẹ́ Ìsìn Jèhófà Jẹ́ Ohun Tó Ṣe Pàtàkì Jù Lọ ní Ìgbésí Ayé Rẹ
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—1999
Àwọn Míì
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2001
km 11/01 ojú ìwé 1

“Ibo Ni Màá Ti Rí Àyè?”

1 Àròyé tí ọ̀pọ̀ wa máa ń ṣe nìyẹn nítorí ọwọ́ wa máa ń dí. Wọ́n sọ pé àkókò ló ṣe pàtàkì jù lọ tó sì máa ń tètè lọ mọ́ wa lọ́wọ́ jù lọ nínú gbogbo ohun tá a ní. Ibo la wá ti lè ráyè fún àwọn nǹkan tó ṣe pàtàkì ní tòótọ́, irú bíi kíka Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run àti kíkẹ́kọ̀ọ́ rẹ̀?—Fílí. 1:10.

2 Kókó pàtàkì ibẹ̀ ni pé a ní láti pinnu ohun tí a fẹ́ ṣe láàárín àkókò tí a ní, kì í ṣe pé ká gbìyànjú láti wá àkókò púpọ̀ sí i. Wákàtí méjìdínláàádọ́sàn-án [168] ni gbogbo wa ní lọ́sẹ̀, ó sì ṣeé ṣe ká lo ọgọ́rùn-ún lára rẹ̀ fún oorun sísùn àti iṣẹ́ ṣíṣe. Nígbà náà, báwo la ṣe lè lo wákàtí tó ṣẹ́ kù lọ́nà tí yóò ṣàǹfààní jù lọ? Éfésù 5:15-17 dámọ̀ràn pé ká máa rìn “kì í ṣe gẹ́gẹ́ bí aláìlọ́gbọ́n ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí ọlọ́gbọ́n, ní ríra àkókò tí ó rọgbọ padà . . . , ní ríróye ohun tí ìfẹ́ Jèhófà jẹ́.” Èyí fi hàn pé ó yẹ láti máa lo gbogbo àǹfààní tó bá ṣí sílẹ̀ láti ṣe àwọn ohun tí Jèhófà sọ pé ó ṣe pàtàkì.

3 Jésù fi ọjọ́ wa wé ọjọ́ Nóà. (Lúùkù 17:26, 27) Ìgbòkègbodò ìgbésí ayé gba gbogbo àfiyèsí àwọn èèyàn nígbà náà lọ́hùn-ún. Ṣùgbọ́n, Nóà wá àyè láti kan áàkì gìrìwò kan, ó sì wàásù. (Héb. 11:7; 2 Pét. 2:5) Báwo ló ṣe ráyè? Ó jẹ́ nípa fífi ìfẹ́ Ọlọ́run ṣáájú àti nípa ṣíṣe àwọn nǹkan lọ́nà “bẹ́ẹ̀ gẹ́ẹ́.”—Jẹ́n. 6:22.

4 Kí Ló Yẹ Kó Ṣáájú? Jésù sọ pé: “Ènìyàn kì yóò wà láàyè nípasẹ̀ oúnjẹ nìkan ṣoṣo, bí kò ṣe nípasẹ̀ gbogbo àsọjáde tí ń jáde wá láti ẹnu Jèhófà.” (Mát. 4:4) Lọ́sọ̀ọ̀sẹ̀, a máa ń rí “ìwọ̀n ìpèsè oúnjẹ [tẹ̀mí] ní àkókò tí ó bẹ́tọ̀ọ́ mu” gbà. (Lúùkù 12:42) Bí a óò bá jàǹfààní ní tòótọ́, ó ń béèrè dídá kàwé déédéé àti ṣíṣètò ìdákẹ́kọ̀ọ́ tó ṣe déédéé láti mú kí gbogbo ẹ̀kọ́ náà wọni lọ́kàn. Nítorí ìmọrírì tá a ní fún oúnjẹ tẹ̀mí, a kì í kà á sí oúnjẹ ṣákálá kan, kí a kàn jẹ ẹ́ wọ̀mùwọ̀mù bí ìgbà téèyàn bá ń sáré jẹ oúnjẹ ti ara. Kàkà bẹ́ẹ̀, ìmọrírì yíyẹ máa ń jẹ́ ká fara balẹ̀ kẹ́kọ̀ọ́ ká sì gbádùn àwọn ohun tẹ̀mí.

5 Jíjẹ oúnjẹ tẹ̀mí lè ṣamọ̀nà sí ìyè àìnípẹ̀kun. (Jòh. 17:3) Ipò pàtàkì ló yẹ kí ó wà nínú ìtòlẹ́sẹẹsẹ wa ojoojúmọ́. Ǹjẹ́ a lè wá àyè láti máa ka Bíbélì lójoojúmọ́ ká sì máa múra sílẹ̀ fún àwọn ìpàdé Kristẹni? Bẹ́ẹ̀ ni, a lè ṣe bẹ́ẹ̀. Bí a bá ṣe bẹ́ẹ̀, a óò rí “èrè ńlá” gbà, èyí tó máa ń wá látinú mímọ ohun tí Ọlọ́run fẹ́ àti ṣíṣe é.—Sm. 19:7-11.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́