ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 5/02 ojú ìwé 8
  • Ohun Tí O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ohun Tí O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2002
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ohun Tó O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2010
  • Ohun Tó O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2011
  • Ohun Tó O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2006
  • Ohun Tó O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2011
Àwọn Míì
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2002
km 5/02 ojú ìwé 8

Ohun Tí O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn

Ilé Ìṣọ́ May 15

“Ǹjẹ́ o rò pé ó ṣeé ṣe láti mọ irú ẹni tí Ọlọ́run jẹ́? [Jẹ́ kí ó fèsì.] Wàá gbà pẹ̀lú mi pé ó ṣòro láti gbà gbọ́ nínú ẹnì kan téèyàn ò fi bẹ́ẹ̀ mọ̀. Ńṣe ni Bíbélì dìídì rọ̀ wá pé ká wá Ọlọ́run. [Ka Ìṣe 17:27.] Àwọn àpilẹ̀kọ yìí fi bí a ṣe lè túbọ̀ mọ Ọlọ́run dáadáa hàn wá.”

Ilé Ìṣọ́ June 1

“Àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ tó ń ṣẹlẹ̀ lẹ́nu lọ́ọ́lọ́ọ́ yìí ń mú kí ọ̀pọ̀ èèyàn máa ṣe kàyéfì pé, kí ló dé táwọn aláìmọwọ́mẹsẹ̀ fi ń kú ikú òjijì. Ǹjẹ́ o ti ronú rí nípa ìdí tí àwọn èèyàn fi ń kú? [Jẹ́ kí ó fèsì, lẹ́yìn náà fi ṣáàtì tó wà ní ojú ewé 7 hàn án.] Ṣé wàá fẹ́ láti mọ ohun tí Bíbélì sọ nípa ọ̀kan lára àwọn èrò èké tó wọ́pọ̀ yìí?” Tó bá ṣeé ṣe, ka ẹsẹ Ìwé Mímọ́ kan tá a tọ́ka sí nínú ìwé ìròyìn náà.

Jí! June 8

“Oríṣiríṣi ètò làwọn aṣáájú ayé ti ṣe láti rí i pé àwọ́n bá wa yanjú àwọn ìṣòro wa. Ètò tuntun kan tí wọ́n tún ṣe báyìí la mọ̀ sí ètò sayé dọ̀kan. Nínú ìwé ìròyìn yìí, o lè kà nípa ọ̀nà tí akitiyan tuntun yìí ti lè gbà máa nípa lórí ìgbésí ayé rẹ ní lọ́wọ́lọ́wọ́. O tún lè kà nípa ojútùú kárí ayé kan tí Bíbélì ti sàsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀.” Lẹ́yìn náà ka Mátíù 6:9, 10.

“Ọ̀pọ̀ èèyàn máa ń rò pé sáyẹ́ǹsì àti ìsìn kò bára wọn rẹ́ rárá. Àwọn kan tiẹ̀ máa ń wò ó pé kò ṣeé ṣe rárá kí ẹnì kan tí sáyẹ́ǹsì jẹ lọ́kàn gan-an ní ìgbàgbọ́ nínú Ọlọ́run. Kí lèrò tìẹ lórí ọ̀ràn yìí? [Jẹ́ kí ó fèsì.] Ìwé ìròyìn Jí! yìí ṣàlàyé kókó yìí lọ́nà tó máa yéni gan-an.”

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́