ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 9/02 ojú ìwé 1
  • Máa Náání Àwọn Ohun Ìní Ètò Àjọ Ọlọ́run

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Máa Náání Àwọn Ohun Ìní Ètò Àjọ Ọlọ́run
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2002
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ẹ Jẹ́ Ká Máa Fi Ọgbọ́n Lo Àwọn Ìwé Ìkẹ́kọ̀ọ́ Wa
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2005
  • Máa Fi Ìmọrírì Àtọkànwá Hàn fún Àwọn Ìwé Ìkẹ́kọ̀ọ́ Wa
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2002
  • Máa Lo Àwọn Ìtẹ̀jáde Wa Lọ́nà Tó Dáa
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2009
  • Fífi Ìwé Ìkẹ́kọ̀ọ́ Lọni ní Ìpínlẹ̀ Tí Wọ́n Ti Ń Sọ Onírúurú Èdè
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2003
Àwọn Míì
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2002
km 9/02 ojú ìwé 1

Máa Náání Àwọn Ohun Ìní Ètò Àjọ Ọlọ́run

1 Nígbà tí ètò ń lọ lọ́wọ́ láti ṣàtúnṣe tẹ́ńpìlì, Jòsáyà Ọba gbóríyìn fún àwọn tí a yanṣẹ́ náà fún nípa sísọ pé: “Kí a má ṣe ṣírò owó tí ó wà lọ́dọ̀ wọn sí ọwọ́ ẹni tí a ń fi í sí, nítorí pé ìṣòtítọ́ ni wọ́n fi ń ṣiṣẹ́.” (2 Ọba 22:3-7) Ìmọrírì tí àwọn ọkùnrin wọ̀nyẹn ní fún àwọn nǹkan tẹ̀mí fara hàn kedere nínú bí wọ́n ṣe bójú tó ohun tá a fi síkàáwọ́ wọn. Lónìí, bá a ṣe ń nípìn-ín nínú iṣẹ́ mímọ́ ti ìhìn rere Ọlọ́run, ó yẹ kí àwa náà máa fi ìṣòtítọ́ hàn nínú bí a ṣe ń bójú tó àwọn ohun tí a pèsè fún wa.

2 Nínú Iṣẹ́ Ìsìn Pápá: Tí a bá ń náání àwọn ìsọfúnni pàtàkì tó wà nínú àwọn ìtẹ̀jáde wa àti iye tó ń ná wa láti tẹ̀ wọ́n jáde èyí á máa sún wa láti mọyì wọn gidigidi. Kò yẹ ká máa pín àwọn ìwé wa fún irú-wá-ògìrì-wá, ìyẹn àwọn ẹni tí kò ní ojúlówó ìmọrírì fún ìhìn Bíbélì. Bí ẹnì kan kò bá fi bẹ́ẹ̀ fìfẹ́ hàn nínú ìhìn rere náà, a lè fún un ní ìwé àṣàrò kúkúrú dípò tí a ó fi fún un ní ìwé ìkẹ́kọ̀ọ́.

3 Máa pín àwọn ìwé wa lọ́nà tó máa fi hàn pé o mọyì ìjẹ́pàtàkì wọn. Má kàn máa kó wọn sílẹ̀ ní gbangba, níbi tí atẹ́gùn á ti máa gbá wọn káàkiri. Láti yẹra fún ìfiṣòfò, yẹ àwọn ìwé tó o ní lọ́wọ́ nílé wò kó o tó gba àfikún ìwé ìkẹ́kọ̀ọ́. Bí ọ̀pọ̀ ẹ̀dà ìwé ìròyìn bá sábà máa ń ṣẹ́ jọ sí ọ lọ́wọ́, o lè dín iye tó ò ń gbà kù.

4 Àwọn Ìtẹ̀jáde Tí A Fẹ́ Lò Fúnra Wa: Àwọn ìtẹ̀jáde tá a dìídì nílò nìkan ló yẹ ká béèrè fún. Ó ṣe pàtàkì gan-an pé ká lo ìwọ̀ntúnwọ̀nsì nígbà tá a bá fẹ́ béèrè fún àwọn ìtẹ̀jáde àkànṣe, irú bíi Bíbélì olómi góòlù (deluxe), Bíbélì atọ́ka lédè Gẹ̀ẹ́sì (Reference Bible), àtàwọn ìtẹ̀jáde ńlá mìíràn bí ìwé Concordance, ìwé Index, àwọn ìdìpọ̀ Insight, àti ìwé Proclaimers, nítorí pé owó gọbọi ló ń ná wa láti tẹ̀ wọ́n jáde.

5 Ṣé o máa ń rántí láti kọ orúkọ àti àdírẹ́sì rẹ sínú àwọn ẹ̀dà ìtẹ̀jáde tó jẹ́ tìrẹ? Bó o bá ń ṣe èyí, kò ní fi bẹ́ẹ̀ pọn dandan láti máa gba àwọn ìtẹ̀jáde mìíràn láti fi rọ́pò àwọn tó o ṣèèṣì sọ síbì kan. Bó o bá sọ ìwé orin, Bíbélì, tàbí ìwé tá a fi ń kẹ́kọ̀ọ́ nù, ó ṣeé ṣe kó o rí i láàárín àwọn nǹkan tó sọ nù tí wọ́n sì rí he ní Gbọ̀ngàn Ìjọba tàbí ní ilẹ̀ àpéjọ.—Lúùkù 15:8, 9.

6 Ẹ jẹ́ ká sapá láti rí i pé à ń fi ọgbọ́n lo àwọn ìwé ìkẹ́kọ̀ọ́ wa. Èyí jẹ́ ọ̀nà kan láti fi ìṣòtítọ́ wa hàn nínú bí a ṣe ń bójú tó àwọn ohun ìní Ìjọba náà tí Jèhófà ti fi sí ìkáwọ́ wa.—Lúùkù 16:10.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́