ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 4/03 ojú ìwé 1
  • ‘Títàn bí Atànmọ́lẹ̀’

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • ‘Títàn bí Atànmọ́lẹ̀’
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2003
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Àwọn Ọ̀dọ́ Tó Ń Tàn bí Ìmọ́lẹ̀
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2006
  • Jíjẹ́ Kí Ìmọ́lẹ̀ Wá Máa Tàn Ṣáá
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—1996
  • “Kí Ìmọ́lẹ̀ Yín Máa Tàn”
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2001
  • Àwọn Iṣẹ́ Àtàtà Tí Ń Yin Jehofa Lógo
    Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1996
Àwọn Míì
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2003
km 4/03 ojú ìwé 1

‘Títàn bí Atànmọ́lẹ̀’

1 Lójú òkùnkùn biribiri nípa tẹ̀mí tó bolẹ̀ ayé àti ìlànà ìwà rere tó ń jó rẹ̀yìn nínú ètò àwọn nǹkan ìsinsìnyí, nǹkan bíi mílíọ̀nù mẹ́fà àwọn olùjọ́sìn Ọlọ́run tòótọ́ náà, Jèhófà, “ń tàn bí atànmọ́lẹ̀” ní ilẹ̀ tó tó igba ó lé mẹ́rìnlélọ́gbọ̀n [234] jákèjádò ayé. (Fíl. 2:15) Èyí ló jẹ́ ká dá yàtọ̀ gedegbe. Báwo la ṣe lè fi ìmọ́lẹ̀ òtítọ́ ṣíṣeyebíye tó ń wá látọ̀dọ̀ Jèhófà hàn?—2 Kọ́r. 3:18.

2 Ìwà Wa: Àwọn èèyàn máa ń tètè kíyè sí ìwà tí à ń hù. (1 Pét. 2:12) Obìnrin kan kíyè sí i pé Ẹlẹ́rìí kan tó jẹ́ òṣìṣẹ́ ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ jẹ́ onínúure àti ọmọlúwàbí, kì í sì í sọ ọ̀rọ̀ rírùn tàbí kó máa rẹ́rìn-ín sí àwọn àpárá tí kò bójú mu. Nígbà tí àwọn ẹlòmíràn bá gbìyànjú láti mú Ẹlẹ́rìí náà bínú nípa sísọ àwọn ọ̀rọ̀ rírùn níbi tó wà, ńṣe ló máa ń dákẹ́ jẹ́ẹ́, síbẹ̀ á dúró lórí ìpinnu rẹ̀ láti ṣe ohun tó tọ́. Ipa wo ni ìwà rẹ̀ ní lórí obìnrin náà? Ó sọ pé: “Ìwà rẹ̀ wú mi lórí gan-an débi pé mo bẹ̀rẹ̀ sí béèrè àwọn ìbéèrè kan nípa Bíbélì. Mo bẹ̀rẹ̀ sí kẹ́kọ̀ọ́ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run mo sì ṣèrìbọmi lẹ́yìn ìgbà náà.” Ó fi kún un pé: “Ìwà rẹ̀ lohun tó sún mi láti ṣàgbéyẹ̀wò ohun tí àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà gbà gbọ́.”

3 Ìṣarasíhùwà wa sí àwọn tó wà ní ipò àṣẹ, ojú tí a fi ń wo àwọn àṣà ayé, àti ọ̀rọ̀ tó bójú mu tí à ń sọ, ló ń mú kí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà dá yàtọ̀ gedegbe gẹ́gẹ́ bí àwọn èèyàn tó ń gbé níbàámu pẹ̀lú àwọn ìlànà ṣíṣeyebíye tó wà nínú Bíbélì. Irú àwọn iṣẹ́ àtàtà bẹ́ẹ̀ ń fi ògo fún Jèhófà, wọ́n sì lè mú kí àwọn ẹlòmíràn nífẹ̀ẹ́ sí ìjọsìn rẹ̀.

4 Ọ̀rọ̀ Tí À Ń Sọ: Ká sòótọ́, àwọn tó ń rí ìwà rere wa lè má mọ ìdí tí a fi yàtọ̀, àyàfi bí a bá sọ fún wọn nípa àwọn ohun tí a gbà gbọ́. Ǹjẹ́ àwọn òṣìṣẹ́ ẹlẹgbẹ́ rẹ tàbí àwọn ọmọléèwé rẹ mọ̀ pé ọ̀kan lára àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà ni ọ́? Ǹjẹ́ o máa ń lo àwọn àǹfààní tó o bá ní láti jẹ́rìí nígbà tó o bá ń ní ìfọ̀rọ̀wérọ̀ ọlọ́rẹ̀ẹ́sọ́rẹ̀ẹ́ pẹ̀lú àwọn èèyàn? Ǹjẹ́ o ti pinnu láti jẹ́ “kí ìmọ́lẹ̀ [rẹ] máa tàn níwájú àwọn ènìyàn” ní gbogbo ìgbà tó bá ti ṣeé ṣe?—Mát. 5:14-16.

5 Pípa àṣẹ tí a fún wa mọ́ láti jẹ́ atànmọ́lẹ̀ ń béèrè pé ká ní ẹ̀mí ìfara-ẹni-rúbọ. Ìfẹ́ láti ṣiṣẹ́ tọkàntọkàn yóò sún wa láti yẹra fún àwọn nǹkan tí kò fi bẹ́ẹ̀ ṣe pàtàkì, ká bàa lè ṣe púpọ̀ sí i dé ibi tí agbára wa bá gbé e dé nínú iṣẹ́ ìgbẹ̀mílà náà, ìyẹn wíwàásù àti sísọ àwọn èèyàn di ọmọ ẹ̀yìn.—2 Kọ́r. 12:15.

6 Nípa ọ̀rọ̀ àti ìṣe wa, ẹ jẹ́ ká máa bá a lọ láti tàn bí atànmọ́lẹ̀. Bí a bá ń ṣe bẹ́ẹ̀, ó lè sún àwọn ẹlòmíràn láti dara pọ̀ mọ́ wa nínú fífi ògo fún Jèhófà.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́