ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 11/04 ojú ìwé 4
  • Ohun Tí O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ohun Tí O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2004
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ohun Tó O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2006
  • Ohun Tí O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2005
  • Ohun Tí O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2003
  • Ohun Tí O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2003
Àwọn Míì
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2004
km 11/04 ojú ìwé 4

Ohun Tí O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn

Ile Ìṣọ́ Nov. 15

“Ọ̀pọ̀ èèyàn ló ń fẹ́ kí ara àwọn dá ṣáṣá kí ẹ̀mí àwọn sì gùn. Ṣùgbọ́n ká ní ó ṣeé ṣe, ṣé wàá fẹ́ wà láàyè títí láé? [Jẹ́ kó fèsì. Lẹ́yìn náà ka Jòhánù 17:3.] Ìwé ìròyìn yìí ṣàlàyé ìlérí ìyè ayérayé tó wà nínú Bíbélì. Ó tún sọ bí ìgbésí ayé ṣe máa dùn tó nígbà tí ìlérí yẹn bá ṣẹ.”

Ile Ìṣọ́ Dec. 1

“Ohun kan tí àwa ẹ̀dá èèyàn fi yàtọ̀ sí àwọn ẹranko ni pé a mọ ìyàtọ̀ tó wà láàárín ohun tó tọ́ àtèyí tí kò tọ́. Àmọ́, ó bani nínú jẹ́ pé ohun búburú ni ọ̀pọ̀ èèyàn ń ṣe. Kí lo rò pé ó fa èyí? [Jẹ́ kó fèsì. Lẹ́yìn náà ka Jeremáyà 17:9 tàbí Ìṣípayá 12:9.] Ìwé ìròyìn yìí ṣàlàyé bá a ṣe lè mọ ohun tó tọ́ àti bá a ṣe lè máa ṣe é.”

Jí! Dec. 8

“Láti nǹkan bí ogún ọdún wá, ìmọ̀ àwọn oníṣègùn nípa àrùn éèdì àti bí wọ́n ṣe lè tọ́jú rẹ̀ ti jinlẹ̀ sí i. Síbẹ̀, ọ̀pọ̀ èèyàn ò tíì ní ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ òye nípa àrùn yìí. [Fi àpótí tó ní àkọlé náà “Àwọn Èrò Èké Nípa Àrùn Éèdì” han onílé, kó o sì jẹ́ kó fèsì.] Ìwé ìròyìn yìí ṣàlàyé bí àwọn òbí ṣe lè dáàbò bo àwọn ọmọ wọn.” Ka Diutarónómì 6:6, 7.

“Òótọ́ ni pé aráyé ti tẹ̀ síwájú gan-an nínú ìmọ̀ ẹ̀rọ, síbẹ̀ èyí ò lè rọ́pò báwa èèyàn ṣe ń bá ara wa ṣọ̀rẹ́. Àmọ́, ǹjẹ́ o ti ṣàkíyèsí pé bí ayé ṣe ń yí padà lónìí lè máà jẹ́ kó rọrùn fún àwọn èèyàn láti ní ọ̀rẹ́ tímọ́tímọ́? [Jẹ́ kó fèsì. Lẹ́yìn náà ka Òwe 18:24.] Ìwé ìròyìn yìí ṣàlàyé bá a ṣe lè ní àwọn ọ̀rẹ́ gidi, kí ọ̀rẹ́ wa má sì já.”

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́