ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 11/05 ojú ìwé 8
  • Ohun Tí O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ohun Tí O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2005
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ohun Tí O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2004
  • Ohun Tó O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2006
  • Ohun Tí O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2003
  • Ohun Tó O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2008
Àwọn Míì
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2005
km 11/05 ojú ìwé 8

Ohun Tí O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn

Ile Iṣọ Nov. 15

“Ọ̀pọ̀ ló ń ṣe kàyéfì nípa báwọn ìṣòro tó ń yọ aráyé lẹ́nu ṣe dà bíi pé ó ń burú sí i dípò kó máa dín kù. Ǹjẹ́ o ti fìgbà kan rí ronú lórí pé ó ṣeé ṣe kó jẹ́ pé ohun tí ẹsẹ Bíbélì yìí sọ ló fà á tí ọ̀ràn fi rí bẹ́ẹ̀? [Ka Ìṣípayá 12:9. Jẹ́ kó fèsì.] Ìwé ìròyìn yìí jíròrò àwọn ọ̀nà àrékérekè tí Èṣù ń gbà ṣi àwọn èèyàn lọ́nà, ó sì tún sọ ohun tá a lè ṣe tí kò fi ní rí wa mú.”

Ile Iṣọ Dec. 1

“Nígbà táwọn èèyàn bá gbọ́ ‘Amágẹ́dọ́nì,’ ọ̀pọ̀ nínú wọn máa ń rò pé ìpakúpa ẹlẹ́rùjẹ̀jẹ̀ kan ló ń jẹ́ bẹ́ẹ̀. [Fi àpótí tó wà lójú ìwé 3 hàn án.] Ǹjẹ́ kò ní yà ọ́ lẹ́nu láti gbọ́ pé ọ̀kan lára ohun táá ṣe wá láǹfààní jù lọ bó bá ṣẹlẹ̀ ni Amágẹ́dọ́nì? [Jẹ́ kó fèsì.] Ìwé ìròyìn yìí ṣàlàyé ìdí tó fi rí bẹ́ẹ̀.” Ka 2 Pétérù 3:13.

Jí Dec. 8

“Bó tilẹ̀ jẹ́ pé oúnjẹ tí gbogbo èèyàn á jẹ́ ní àjẹtẹ́rùn wà, síbẹ̀ ọgọ́rùn-ún mẹ́jọ mílíọ̀nù èèyàn ni kì í rí oúnjẹ jẹ kánú. Ǹjẹ́ ìyẹn ò ṣèèyàn ní kàyéfì? [Jẹ́ kó fèsì.] Ìwé ìròyìn yìí tú iṣu dé ìsàlẹ̀ ìkòkò lórí ọ̀ràn ìṣòro àìróúnjẹ jẹ tó túbọ̀ ń pọ̀ sí i, èyí tó ń ṣẹlẹ̀ láwọn ìlú ńlá. Ó tún jíròrò ìlérí tó wà nínú Bíbélì pé ayé kan ń bọ̀ tí kò ti ní sí pé ebi ń pààyàn.” Ka Sáàmù 72:16a.

“Mo fẹ́ láti sọ fún ọ nípa àkókò kan tí kálukú á ní ibùgbé tó dáa. Etí wo ló ń gbọ́ ọ pé ọ̀pọ̀ èèyàn ni ò rílé gbé? [Jẹ́ kó fèsì. Lẹ́yìn náà ka, Aísáyà 65:21, 22.] Ìwé ìròyìn ṣàlàyé lẹ́kùn-ún rẹ́rẹ́ lórí àwọn ohun tó ń fa àìrílégbé. Ó sì tún ṣàlàyé ọ̀nà tí Ọlọ́run máa gbà mú ìlérí tá a ṣẹ̀ṣẹ̀ kà tán yìí ṣẹ.”

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́