ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 8/05 ojú ìwé 1
  • Àǹfààní Ṣíṣeyebíye Ni Wíwàásù Ìjọba Ọlọ́run

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Àǹfààní Ṣíṣeyebíye Ni Wíwàásù Ìjọba Ọlọ́run
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2005
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Mọyì Àǹfààní Iṣẹ́ Ìsìn Tó O Ní
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2011
  • Ìṣúra Tó Wà Níkàáwọ́ Wa
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2007
  • A Mọyì Àǹfààní Iṣẹ́ Ìsìn Tá A Ní!
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2007
  • Máa Ṣìkẹ́ Àǹfààní Tó O Ní Láti Jẹ́ Alábàáṣiṣẹ́pọ̀ Pẹ̀lú Jèhófà!
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2014
Àwọn Míì
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2005
km 8/05 ojú ìwé 1

Àǹfààní Ṣíṣeyebíye Ni Wíwàásù Ìjọba Ọlọ́run

1 Lójúmọ́, ẹgbàágbèje èèyàn ló ń jọlá ìwà ọ̀làwọ́ Jèhófà tó mú kó fi ìwàláàyè jíǹkí wa. (Mát. 5:45) Àmọ́, díẹ̀ ló mọyì àǹfààní àrà ọ̀tọ̀ tó wà nínú kéèyàn fi ìmoore hàn sí Ẹlẹ́dàá nípa wíwàásù ìhìn rere Ìjọba Ọlọ́run. (Mát. 24:14) Báwo lo ṣe mọyì àǹfààní ṣíṣeyebíye yìí tó?

2 Bá a bá ń wàásù ìhìn rere Ìjọba náà, ńṣe là ń gbé Ọlọ́run lárugẹ, a sì ń jẹ́ káwọn èèyàn tí ọkàn wọn kò balẹ̀ ní àkókò onírúkèrúdò tá à ń gbé yìí ní ìrètí àti àlàáfíà. (Héb. 13:15) Àwọn tó bá gbọ́ tí wọ́n sì yí ìgbésí ayé wọn padà máa jogún ìyè àìnípẹ̀kun. (Jòh. 17:3) Èwo nínú iṣẹ́ téèyàn ń ṣe láyé yìí lèèyàn lè rí àǹfààní tó tóyẹn nínú ẹ̀? Ọ̀nà tí àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù gbà ṣe iṣẹ́ òjíṣẹ́ rẹ̀ fi hàn pé ó mọrírì rẹ̀. Ohun ìṣúra ló kà á sí.—Ìṣe 20:20, 21, 24; 2 Kọ́r. 4:1, 7.

3 Bá A Ṣe Lè Máa Mọyì Àǹfààní Ṣíṣeyebíye Tá A Ní: Fífi ọwọ́ pàtàkì mú ẹ̀kọ́ tá à ń kọ́ àwọn èèyàn wà lára ọ̀nà tá a lè gbà fi hàn pé a mọyì àǹfààní tá a ní láti wàásù. Ṣé a máa ń múra láti gbọ́rọ̀ wa kalẹ̀ lọ́nà tó fi máa wọ àwọn tó ń gbọ́ wa lọ́kàn? Ǹjẹ́ àwọn nǹkan kan wà tá a lè ṣe ká lè túbọ̀ jáfáfá lọ́nà tá a gbà ń fèrò wérò pẹ̀lú àwọn èèyàn àti bá a ṣe ń lo Ìwé Mímọ́? Ṣé a máa ń jẹ́rìí kúnnákúnná ní ìpínlẹ̀ ìwàásù wa? Ṣé a mọ bó ṣe yẹ ká bẹ̀rẹ̀ ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì àti bó ṣe yẹ ká máa darí rẹ̀? Bíi tàwọn Kristẹni olùṣòtítọ́, nígbà láéláé àti lóde òní, a mọyì àǹfààní tá a ní yìí gan-an ni, ìyẹn la ṣe máa ń fọwọ́ tó yẹ mú un.—Mát. 25:14-23.

4 Bá a bá wà lára àwọn òjíṣẹ́ onítara tí ọjọ́ ogbó, àìlera tàbí àwọn ìṣòro líle koko mìíràn ń dà láàmú, á tù wá nínú láti mọ̀ pé Ọlọ́run mọrírì ipá tá à ń sà láti lè máa kópa nínú iṣẹ́ òjíṣẹ́ náà gidigidi. Ọ̀rọ̀ rẹ̀ fi dá wa lójú pé Jèhófà mọyì irú ìsapá bẹ́ẹ̀ tá à ń ṣe láti sìn ín, kódà bí kò tiẹ̀ jọ àwọn míì lójú.—Lúùkù 21:1-4.

5 Iṣẹ́ ìwàásù Ìjọba Ọlọ́run jẹ́ ọ̀nà kan tá a lè gbà ní ìtẹ́lọ́rùn gan-an. Arábìnrin ẹni ọdún méjìléláàádọ́rùn-ún kan sọ pé: “Àǹfààní ńlá gbáà ló jẹ́ fún mi láti sin Ọlọ́run nírú ọ̀nà àkànṣe bẹ́ẹ̀ fún ọgọ́rin ọdún gbáko, tí mi ò sì kábàámọ̀ níṣẹ̀ẹ́jú àáyá kan rí! Ká ní mo lè padà dọmọdé ni, bí mo ṣe gbé ìgbésí ayé mi yìí gẹ́lẹ́ ni ǹ bá gbé e. Ká sòótọ́, ‘inú rere onífẹ̀ẹ́ Ọlọ́run sàn ju ìyè.’” (Sm. 63:3) Ǹjẹ́ káwa náà fi hàn pé a mọyì àǹfààní ṣíṣeyebíye tó wà níkàáwọ́ wa, ìyẹn iṣẹ́ ìwàásù Ìjọba Ọlọ́run.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́