ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 12/05 ojú ìwé 8
  • Ohun Tí O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ohun Tí O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2005
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ohun Tó O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2007
  • Ohun Tó O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2006
  • Ohun Tí O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2004
  • Ohun Tí O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2002
Àwọn Míì
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2005
km 12/05 ojú ìwé 8

Ohun Tí O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn

Ile Iṣọ Dec. 15

“Ọ̀pọ̀ èèyàn ló ń ṣàníyàn nípa bí wọ́n ṣe ń fi àkókò ọdún ṣòwò. Ǹjẹ́ o rò pé ohun tó yẹ kí wọ́n fi àkókò yẹn ṣe ni wọ́n fi ń ṣe? [Jẹ́ kó fèsì.] Ìwé ìròyìn yìí jíròrò bí àwọn àṣà tó ń wáyé lákòókò ọdún ṣe ń yí padà bí ọjọ́ ṣe ń gorí ọjọ́. Ó sì tún jíròrò bá a ṣe lè bọ̀wọ̀ fún Ọlọ́run àti Kristi bó ṣe yẹ.” Ka Jòhánù 17:3.

Ile Iṣọ Jan. 1

“Ẹ̀dá èèyàn lágbára láti ṣe nǹkan tó dáa, àmọ́ ìwà ibi tí wọ́n sábà máa ń hù láyé yìí ò ṣeé fẹnu sọ. Ǹjẹ́ ó ti fìgbà kan rí ṣe ọ́ bíi kó o mọ ohun tó fà á? [Jẹ́ kó fèsì.] Ìwé ìròyìn yìí ṣàlàyé ìdáhùn tó wà nínú Bíbélì. Ó tún ṣàlàyé bí rere á ṣe borí ibi bó pẹ́ bó yá.” Ka Róòmù 16:20.

Awake! Jan.–Mar.

“Ǹjẹ́ o tiẹ̀ ti fìgbà kan ronú nípa bi ayé ṣe máa rí ní nǹkan bí ogún tàbí ọgbọ̀n ọdún sí àsìkò tá a wà yìí? [Jẹ́ kó fèsì. Kó o wá ka Sáàmù 119:105.] Bíbélì tànmọ́lẹ̀ sí ohun tó máa ṣẹlẹ̀ lọ́jọ́ iwájú ká lè mọ ohun tó wà níwájú wa. Ìwé ìròyìn yìí ṣe àyẹ̀wò àwọn àsọtẹ́lẹ̀ tó fi ibi tá a wà nínú ìṣàn àkókò hàn àti ìdí tá a fi lè máa retí ọjọ́ ọ̀la tó sàn jù.”

“Ní nǹkan bí ọdún márùndínláàádọ́rùn-ún sẹ́yìn, àjàkálẹ̀ àrùn kan pa èèyàn tó pọ̀ gan-an láàárín oṣù mẹ́fà péré ju iye tí àrùn éèdì pa láàárín ọdún mẹ́rìnlélógún lọ. Àwọn kan ní àrùn yìí tíì burú jù nínú ìtàn. Ǹjẹ́ o ti gbọ́ nípa àrùn gágá rí. [Jẹ́ kó fèsì.] Ìwé ìròyìn yìí jíròrò bóyá irú ẹ̀ tún lè ṣẹlẹ̀. Ó tún ṣàlàyé ohun tó máa mú ká nírètí.” Ka Aísáyà 33:24.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́