ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 6/07 ojú ìwé 4
  • Ohun Tó O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ohun Tó O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2007
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ohun Tó O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2007
  • Ohun Tí O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2004
  • Ohun Tó O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2009
  • Ohun Tó O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2007
Àwọn Míì
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2007
km 6/07 ojú ìwé 4

Ohun Tó O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn

Ile Iṣọ June 15

“Ǹjẹ́ o ti kíyè sí i pé lásìkò tá a wà yìí, ńṣe lọ̀pọ̀ èèyàn ń fúnra wọn pinnu ohun tó dáa àtèyí tí ò dáa? [Jẹ́ kó fèsì.] Àpẹẹrẹ kan rèé nípa ìtọ́ni tó bá àkókò mu látinú Bíbélì. [Ka ẹsẹ Ìwé Mímọ́ kan látinú àpótí tó wà lójú ìwé 6 àti 7.] Ìwé ìròyìn yìí ṣàlàyé àǹfààní tá a máa rí bá a bá ń fi àwọn ìwà rere tí Bíbélì mẹ́nu bà ṣèwà hù.”

Ile Iṣọ July 1

“Ǹjẹ́ o ti fìgbà kan rí ṣe kàyéfì nípa báwọn èèyàn ṣe máa ń fojú ẹ̀dá bíi tiwọn gbolẹ̀ torí pé ẹ̀yà tiwọn yàtọ̀ tàbí torí pé ọ̀tọ̀ lórílẹ̀-èdè tí wọ́n ti wá tàbí torí pé wọ́n ń sọ èdè tó yàtọ̀? [Jẹ́ kó fèsì.] Gbọ́ bí Bíbélì ṣe sọ ohun tó fà á. [Ka 1 Jòhánù 4:20.] Ìwé ìròyìn yìí dáhùn ìbéèrè náà, Ǹjẹ́ ó ṣeé ṣe kí gbogbo ẹ̀yà wà níṣọ̀kan?

Jí! Apr.–June

“Ǹjẹ́ o rò pé agbára àìrí kan wà tó ń fa àwọn ìṣòro tó ń da ayé yìí láàmú? [Jẹ́ kó fèsì.] Jésù mú kó di mímọ̀ pé Sátánì ni eku ẹdá tó ń dá gbogbo ìṣòro tó wà nínú ayé lónìí sílẹ̀. Ohun tó ti pinnu láti máa ṣe rèé. [Ka Ìṣípayá 12:9.] Ó ṣe pàtàkì ká gbà pé Sátánì wà, ká sì yáa fi ara wa pa mọ́ sọ́dọ̀ Ọlọ́run.” Fi àpilẹ̀kọ tó bẹ̀rẹ̀ lójú ewé 24 hàn án.

“Ọ̀pọ̀ àwọn tó ń wù pé káwọn ní ẹ̀rí ọkàn tó mọ́, káwọn má sì fi ara àwọn wọ́lẹ̀ ti wá ń kojú ìṣòro báyìí. Ìṣòro ọ̀hún ò sì ṣẹ̀yìn pípè tí wọ́n ń pè wọ́n láti ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú ẹni tí kì í ṣe ọkọ tàbí aya wọn. Ǹjẹ́ ohun kan wà tó burú nínú ìyẹn? [Jẹ́ kó fèsì, kó o wá ṣàlàyé 1 Kọ́ríńtì 6:9 fún un.] Béèyàn bá máa ṣègbọràn sí òfin Ọlọ́run lórí ọ̀ràn yìí, àfi kéèyàn yáa kọ̀ jálẹ̀ kó máà lọ́wọ́ sí ìṣekúṣe.” Fi àpilẹ̀kọ tó wà lójú ewé 14 hàn án.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́