ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 8/14 ojú ìwé 4
  • Ìwé Ìkésíni Pàtàkì

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ìwé Ìkésíni Pàtàkì
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2014
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ìkésíni Tààràtà
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2015
  • A Máa Bẹ̀rẹ̀ Sí Í Pín Ìwé Ìkésíni Síbi Ìrántí Ikú Kristi Ní March 1
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2013
  • A Máa Pín Ìwé Ìkésíni sí Àpéjọ Àgbègbè
    Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Àwa Kristẹni​—Ìwé Ìpàdé (2016)
  • A Máa Bẹ̀rẹ̀ Sí Í Pín Ìwé Ìkésíni Síbi Ìrántí Ikú Kristi Ní March 22
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2014
Àwọn Míì
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2014
km 8/14 ojú ìwé 4

Ìwé Ìkésíni Pàtàkì

1. Ìgbà wo la máa bẹ̀rẹ̀ sí í pín ìwé ìkésíni sí àpéjọ ti ọdún 2014?

1 Tó o bá náwó nára gan-an láti se àkànṣe àsè kan fún àwọn ẹbí àti ọ̀rẹ́ rẹ, ó dájú pé yóò yá ọ lára láti pe àwọn èèyàn wá síbi àpèjẹ náà. Bákan náà, iṣẹ́ ti lọ gan-an lórí àsè tẹ̀mí tá a máa gbádùn láwọn àpéjọ àgbáyé àti àpéjọ àgbègbè ti ọdún 2014. A ó láǹfààní láti fi ìwé ìkésíni pe àwọn èèyàn wá sí àpéjọ àgbègbè tó bá ku ọ̀sẹ̀ mẹ́ta tá a máa ṣe é. Kí ló máa mú kó yá wa lára láti pé àwọn èèyàn wá sí àwọn àpéjọ yìí?

2. Kí ló máa mú ká kópa lẹ́kùn-ún rẹ́rẹ́ nínú pípín ìwé ìkésíni sí àpéjọ yìí?

2 Tá a bá ronú nípa bí àwa fúnra wa ṣe jàǹfààní látinú àsè tẹ̀mí tí Jèhófà ń pèsè fún wa láwọn àpéjọ wa, èyí á mú ká kópa lẹ́kùn-ún rẹ́rẹ́ nínú pínpín ìwé ìkésíni sí àwọn àpéjọ yìí. (Aísá. 65:13, 14) Ó yẹ ká rántí pé àwọn ìwé ìkésíni tí à ń pín lọ́dọọdún máa ń méso rere jáde. Àwọn kan lára àwọn tá a fún ní ìwé ìkésíni máa wá sí àpéjọ náà. Láìka bí àwọn tó wá ṣe pọ̀ tó, akitiyan tá a ṣe nígbà tí à ń pín ìwé ìkésíni yìí máa mú ìyìn bá orúkọ Jèhófà, á sì tún fi hàn pé a jẹ́ ọ̀làwọ́ bíi ti Jèhófà.—Sm. 145:3, 7; Ìṣí. 22:17.

3. Báwo lá ṣe máa pín ìwé ìkésíni yìí?

3 Ìgbìmọ̀ àwọn alàgbà ìjọ kọ̀ọ̀kan ló máa pinnu bí ìjọ ṣe máa pín ìwé ìkésíni yìí, wọ́n á sì sọ fún yín bóyá kí ẹ fi ìwé ìkésíni sí ẹnu ọ̀nà àwọn tí kò bá sí nílé tàbí bóyá kí ẹ pín in nígbà tẹ́ ẹ bá ń wàásù láwọn ibi tí èrò pọ̀ sí ní ìpínlẹ̀ ìwàásù yín. Tí ẹ bá ń pín ìwé ìkésíni lópin ọ̀sẹ̀, ẹ lè fún àwọn èèyàn ní ìwé ìròyìn níbi tẹ́ ẹ bá ti rí i pé ó yẹ bẹ́ẹ̀. Tí ọjọ́ tẹ́ ẹ máa bẹ̀rẹ̀ sí í pín ìwé ìkésíni bá bọ́ sí Sátidé àkọ́kọ́ lóṣù, ẹ gbájú mọ́ bí ẹ ṣe máa pín ìwé ìkésíni dípò kí ẹ bẹ̀rẹ̀ ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì. Lẹ́yìn tá a bá parí pínpín ìwé ìkésíni náà, ẹ wo bí inú wa ṣe máa dùn tó láti mọ̀ pé àwa náà fi ìtara kópa nínú rẹ̀ tá a sì tún pe ọ̀pọ̀ èèyàn láti wá gbádùn àsè tẹ̀mí tí Jèhófà pèsè!

Kí Lo Máa Sọ?

Lẹ́yìn tó o bá ti kí onílé dáadáa, o lè sọ pé: “À ń pín ìwé ìkésíni yìí kárí ayé láti pe àwọn èèyàn síbi ìṣẹ̀lẹ̀ pàtàkì kan. Ọjọ́ tá a máa ṣe é, aago tá a máa bẹ̀rẹ̀ àti àdírẹ́sì ibi tá a ti máa ṣe é wà nínú ìwé ìkésíni yìí.”

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́