ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 7/15 ojú ìwé 3-4
  • Ìkésíni Tààràtà

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ìkésíni Tààràtà
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2015
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ìwé Ìkésíni Pàtàkì
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2014
  • Ìpolongo Tó Méso Rere Jáde
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2013
  • A Máa Pín Ìwé Ìkésíni sí Àpéjọ Àgbègbè
    Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Àwa Kristẹni​—Ìwé Ìpàdé (2016)
  • A Máa Pín Ìwé Ìkésíni Síbi Ìrántí Ikú Kristi Bẹ̀rẹ̀ Láti April 2
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2011
Àwọn Míì
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2015
km 7/15 ojú ìwé 3-4

Ìkésíni Tààràtà

1. Ìgbà wo la máa bẹ̀rẹ̀ sí í pín ìwé ìkésíni sí àpéjọ àgbègbè?

1 Tó o bá náwó nára gan-an láti se àkànṣe àsè kan fún àwọn ẹbí àti ọ̀rẹ́ rẹ, ó dájú pé ó máa yá ọ lára láti pe àwọn èèyàn wá síbi àpèjẹ náà. Bákan náà, iṣẹ́ ti lọ gan-an lórí àsè tẹ̀mí tá a máa gbádùn ní àpéjọ àgbègbè wa tó ń bọ̀. Tí àpéjọ àgbègbè wa bá ti ku ọ̀sẹ̀ mẹ́ta, Jèhófà fún wa láǹfààní láti bẹ̀rẹ̀ sí í pe àwọn èèyàn wá sí àpéjọ náà. Kí ló máa mú kó yá wa lára láti pe àwọn èèyàn wá sí àpéjọ yìí?

2. Kí ló máa mú ká kópa kíkún nínú pípín ìwé ìkésíni sí àpéjọ àgbègbè yìí?

2 Tá a bá ronú nípa bí àwa fúnra wa ṣe máa ń jàǹfààní látinú àsè tẹ̀mí tó ń tuni lára tí Jèhófà ń pèsè fún wa láwọn àpéjọ wa, èyí á mú ká kópa kíkún nínú pínpín ìwé ìkésíni sí àpéjọ yìí. (Aísá. 65:13, 14) Ó yẹ ká rántí pé àwọn ìwé ìkésíni tí à ń pín lọ́dọọdún máa ń méso rere jáde. (Wo àpótí náà, “Ó Ń Méso Rere Jáde.”) Àwọn kan lára àwọn tá a fún ní ìwé ìkésíni máa wá sí àpéjọ náà, àwọn kan ò sì ní wá. Iye èèyàn yòówù kó wá sí àpéjọ náà, akitiyan tá a ṣe nígbà tí à ń pín ìwé ìkésíni yìí máa mú ìyìn bá orúkọ Jèhófà, á sì tún fi hàn pé a jẹ́ ọ̀làwọ́ bíi tirẹ̀.—Sm. 145:3, 7; Ìṣí. 22:17.

3. Báwo la ṣe máa pín ìwé ìkésíni náà?

3 Ìgbìmọ̀ àwọn alàgbà ìjọ kọ̀ọ̀kan ló máa pinnu bí ìjọ ṣe máa pín ìwé ìkésíni yìí tó fi máa délé-dóko láwọn ìpínlẹ̀ ìwàásù wọn. Àwọn ló sì máa sọ bóyá a lè fi ìwé ìkésíni sí ẹnu ọ̀nà àwọn tí kò bá sí nílé tàbí bóyá kí a pín in nígbà tá a bá ń wàásù láwọn ibi tí èrò pọ̀ sí ní ìpínlẹ̀ ìwàásù wa. Tá a bá ń pín ìwé ìkésíni lópin ọ̀sẹ̀, a lè fún àwọn èèyàn ní ìwé ìròyìn pẹ̀lú ìwé ìkésíni náà níbi tá a bá ti rí i pé ó yẹ bẹ́ẹ̀. Lẹ́yìn tá a bá ti pín ìwé ìkésíni náà tán, ẹ wo bí inú wa ṣe máa dùn tó láti mọ̀ pé àwa náà fi ìtara kópa nínú rẹ̀ tá a sì tún pe ọ̀pọ̀ èèyàn láti wá gbádùn àsè tẹ̀mí tí Jèhófà pèsè!

Kí Lo Máa Sọ?

Lẹ́yìn tó o bá ti kí onílé dáadáa, o lè sọ pé: “À ń pín ìwé ìkésíni yìí kárí ayé láti pe àwọn èèyàn sí àpéjọ pàtàkì kan. Ọjọ́ tá a máa ṣe é, aago tá a máa bẹ̀rẹ̀ àti àdírẹ́sì ibi tá a ti máa ṣe é wà nínú ìwé ìkésíni yìí.”

Ó Ń Méso Rere Jáde

  • Lọ́dún bíi mélòó kan sẹ́yìn nígbà tí arábìnrin kan ń pín ìwé ìkésíni sí àpéjọ àgbègbè, ó ń ṣe é bí ẹni pé akitiyan tó ń ṣe yẹn ò lè méso rere jáde. Ó ronú pé, ‘Ṣé àwọn tá a fún ní ìwé ìkésíni á wá sí àpéjọ àgbègbè yìí lóòótọ́?’ Lọ́jọ́ Sátidé àpéjọ náà, ó rí ọkùnrin ẹlẹ́sìn Sikh kan tó jókòó nítòsí rẹ̀, ó wá kí i, ó sì sọ orúkọ ara rẹ̀ fún un. Ó hàn kedere pé àwọn ará wa ló fi ìwé ìkésíni pè é wá sí àpéjọ náà. Arábìnrin náà dáhùn gbogbo ìbéèrè tó ní. Ó sọ pé òun gbádùn àwọn nǹkan tí òun gbọ́ ní àpéjọ náà gan-an àti pé ìmúra àti ìwà àwọn ará wú òun lórí. Lọ́jọ́ yẹn kan náà, arábìnrin yìí tún bẹ̀rẹ̀ ìjíròrò pẹ̀lú tọkọtaya kan tí wọ́n jókòó sítòsí rẹ̀. Ìwé ìkésíni tí àwọn náà rí gbà ló jẹ́ kí wọ́n wá, ọkọ̀ èrò ni wọ́n sì wọ̀ wá. Wọ́n gbádùn àpéjọ náà, wọ́n sì tún ṣètò láti wá lọ́jọ́ Sunday. Arábìnrin yìí wá rí bó ti ṣe pàtàkì tó pé ká máa pín ìwé ìkésíni náà lọ́dọọdún.

  • Ní àpéjọ àgbègbè kan lẹ́nu àìpẹ́ yìí, tọkọtaya aṣáájú-ọ̀nà kan kí tọkọtaya àgbàlagbà kan, wọ́n sì sọ orúkọ ara wọn. Tọkọtaya àgbàlagbà náà sọ pé ìgbà àkọ́kọ́ táwọn máa wá nìyẹn. Àwọn aṣáájú-ọ̀nà náà wá bi wọ́n pé: “Ta ló pè yín wá?” Wọ́n wá dáhùn pé: “Nígbà tá a délé lọ́jọ́ kan, a rí ìwé ìkésíni náà lábẹ́ ilẹ̀kùn wa.” Wọ́n ka ìwé ìkésíni náà, wọ́n sì kọ̀wé sínú fọ́ọ̀mù tó wà lẹ́yìn rẹ̀. Àwọn ará fún wọn lóúnjẹ. Wọ́n gbádùn ìtòlẹ́sẹẹsẹ náà débi pé wọ́n ṣètò láti wá lọ́jọ́ kejì. Àwọn ará sì ṣètò láti lọ bẹ̀rẹ̀ ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì pẹ̀lú wọn.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́