ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 3/15 ojú ìwé 1
  • Ṣé Ò Ń Múra Sílẹ̀ fún Ìrántí Ikú Kristi?

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ṣé Ò Ń Múra Sílẹ̀ fún Ìrántí Ikú Kristi?
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2015
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ṣé Ò Ń Múra Sílẹ̀ fún Ìrántí Ikú Kristi?
    Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2021
  • Fi Ayọ̀ Múra Sílẹ̀ De Ìrántí Ikú Kristi
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2013
  • Àwọn Ohun Tí Kò Yẹ Ká Gbàgbé Nípa Ìṣe Ìrántí
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2001
  • Àwọn Ìránnilétí Ìṣe Ìrántí
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—1998
Àwọn Míì
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2015
km 3/15 ojú ìwé 1

Ṣé Ò Ń Múra Sílẹ̀ fún Ìrántí Ikú Kristi?

Ohun kan ṣẹlẹ̀ ní Nísàn 13 ọdún 33 Sànmánì Kristẹni. Jésù mọ̀ pé alẹ́ kan ṣoṣo ló kù tí òun á fi wà pẹ̀lú àwọn ọ̀rẹ́ òun tímọ́tímọ́ kí wọ́n tó pa òun. Ó máa ṣe Ayẹyẹ Ìrékọjá tó kẹ́yìn pẹ̀lú wọn, ó sì máa dá ohun kan tí wọ́n á máa rántí sílẹ̀, ìyẹn Oúnjẹ Alẹ́ Olúwa. Ó dájú pé wọ́n ní láti múra sílẹ̀ dáadáa fún ìṣẹ̀lẹ̀ pàtàkì yìí. Torí náà, ó rán Pétérù àti Jòhánù pé kí wọ́n lọ ṣètò àwọn nǹkan tí wọ́n máa lò sílẹ̀. (Lúùkù 22:7-13) Látìgbà yẹn ló ti jẹ́ pé ọdọọdún làwọn Kristẹni tó fẹ́ ṣe Ìrántí Ikú Kristi ti kà á sí ohun pàtàkì pé kí wọ́n máa múra sílẹ̀ fún ìṣẹ̀lẹ̀ yìí. (Lúùkù 22:19) Àwọn nǹkan pàtó wo la lè ṣe láti múra sílẹ̀ fún Ìrántí Ikú Kristi tá a máa ṣe ní April 3?

Ìmúrasílẹ̀ Táwọn Alàgbà Máa Ṣe:

  • Ẹ ṣètò Gbọ̀ngàn Ìjọba tàbí ibòmíì tẹ́ ẹ máa lò. Ẹ rí i pé ìjókòó tó pọ̀ tó wà níbẹ̀, kí iná ibẹ̀ mọ́lẹ̀ dáadáa, kó sì jẹ́ ibi tí atẹ́gùn á ti máa wọlé dáadáa. Ẹ ṣètò bẹ́ ẹ ṣe máa ṣe ìmọ́tótó ibẹ̀ dáadáa ṣáájú àkókò.

  • Ẹ yan arákùnrin tó tóótun tó máa sọ àsọyé, ẹ yan alága àtàwọn arákùnrin tó máa gbàdúrà sórí àwọn ohun ìṣàpẹẹrẹ.

  • Tí ìjọ tó máa lo ibi tí ẹ ti fẹ́ ṣe Ìrántí Ikú Kristi bá ju ọ̀kan lọ, ẹ ṣètò àkókò ìpàdé náà dáadáa kẹ́ ẹ sì ṣètò bí àwọn ará á ṣe wọlé àti bí wọ́n á ṣe jáde níbẹ̀ àti bí wọ́n á ṣe lo ibi ìgbọ́kọ̀sí.

  • Ẹ yan àwọn tó ń bójú tó èrò àtàwọn tó máa gbé àwọn ohun ìṣàpẹẹrẹ, kẹ́ ẹ sì ṣètò wọn.

  • Ẹ ṣètò bẹ́ ẹ ṣe máa rí àwọn ohun ìṣàpẹẹrẹ tó yẹ, títí kan àwọn àwo, ife wáìnì, tábìlì tó bójú mu àti aṣọ tẹ́ ẹ máa fi bo tábìlì.

Ìmúrasílẹ̀ Tí Gbogbo Wa Máa Ṣe:

  • Ṣètò láti kópa dáadáa nínú pípín ìwé ìkésíni sí Ìrántí Ikú Kristi.

  • Ṣàkọsílẹ̀ orúkọ àwọn akẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì rẹ, àwọn ìbátan rẹ, àwọn ọmọ iléèwé rẹ, àwọn ará ibiṣẹ́ rẹ àtàwọn míì tó o bá mọ̀, kó o sì pè wọ́n wá.

  • Ka àwọn ẹsẹ Ìwé Mímọ́ tá a máa ń kà lákòókò Ìrántí Ikú Kristi, kó o sì ṣàṣàrò lé wọn lórí.

  • Wá síbi Ìrántí Ikú Kristi kó o sì kí àwọn àlejò káàbọ̀.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́