ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • mwb19 August ojú ìwé 8
  • Àwọn Iṣẹ́ Rere Tá Ò Ní Gbàgbé

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Àwọn Iṣẹ́ Rere Tá Ò Ní Gbàgbé
  • Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2019
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Èyí Ha Lè Jẹ́ Iṣẹ́ Tó Dára Jù Lọ fún Ọ Bí?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2001
  • Ǹjẹ́ O Lè Yọ̀ǹda Ara Rẹ?
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2003
  • Fífi Ìmọrírì Wo “Ilé Ọlọrun”
    Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1994
  • Gbogbo Èèyàn La Pè!
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2010
Àwọn Míì
Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2019
mwb19 August ojú ìwé 8
Arábìnrin kan ń ṣiṣẹ́ nílé ìdáná tó wà ní Bẹ́tẹ́lì

MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI

Àwọn Iṣẹ́ Rere Tá Ò Ní Gbàgbé

Gbogbo àwa tá à ń sin Jèhófà la lè gbé nǹkan ńlá ṣe lẹ́nu iṣẹ́ ìsìn Jèhófà, nǹkan tá à ò ní gbàgbé láé. Àwọn òbí tó nífẹ̀ẹ́ àwọn ọmọ wọn kì í gbàgbé àwọn nǹkan rere tí àwọn ọmọ wọn ń ṣe, Jèhófà náà kì í gbàgbé àwọn iṣẹ́ rere wa àti ìfẹ́ tá a ní fún orúkọ rẹ̀. (Mt 6:20; Heb 6:10) Òótọ́ kan ni pé ohun tá a mọ̀ ọ́ ṣe àti ipò wa yàtọ̀ síra, àmọ́ tá a bá ṣe gbogbo nǹkan tá a lè ṣe lẹ́nu iṣẹ́ ìsìn Jèhófà, a máa láyọ̀. (Ga 6:4; Kol 3:23) Láti ọ̀pọ̀ ọdún wá, ẹgbẹẹgbẹ̀rún àwọn ará lọ́kùnrin lóbìnrin ló ti ṣiṣẹ́ sìn ní Bẹ́tẹ́lì. Ṣé ìwọ náà lè yọ̀ǹda ara rẹ láti ṣiṣẹ́ ní Bẹ́tẹ́lì? Tó ò bá lè ṣe bẹ́ẹ̀, ṣé o lè gba ẹlòmíì níyànjú láti ṣe bẹ́ẹ̀, àbí o lè ran ẹnì kan tó ń ṣiṣẹ́ sìn ní Bẹ́tẹ́lì lọ́wọ́ kó lè máa bá a lọ lẹ́nu àkànṣe iṣẹ́ ìsìn náà?

WO FÍDÍÒ NÁÀ OHUN TÓ O LÈ ṢE LÁTI ṢIṢẸ́ SÌN NÍ BẸ́TẸ́LÌ, KÓ O SÌ DÁHÙN ÀWỌN ÌBÉÈRÈ YÌÍ:

  • Kí ló yẹ kó sún wa láti fẹ́ sìn ní Bẹ́tẹ́lì?

  • Kí ni àwọn kan ti sọ nípa àwọn ìbùkún tá a máa rí tá a bá ṣiṣẹ́ sìn ní Bẹ́tẹ́lì?

  • Kí làwọn nǹkan tá à ń retí lọ́wọ́ ẹni tó bá fẹ́ sìn ní Bẹ́tẹ́lì?

  • Kí lo lè ṣe láti yọ̀ǹda ara rẹ fún iṣẹ́ ìsìn Bẹ́tẹ́lì?

Àwọn mẹ́ta tó ń ṣiṣẹ́ sìn ní Bẹ́tẹ́lì jọ ń ṣiṣẹ́ pa pọ̀ lórí kọ̀ǹpútà; arákùnrin kan ń kó ìwé sínú pààlì; arákùnrin kan ń ṣiṣẹ́ káfíńtà ní Bẹ́tẹ́lì

Àwọn nǹkan tá a retí lọ́wọ́ ẹni tó fẹ́ ṣiṣẹ́ sìn ní Bẹ́tẹ́lì

  • Ní ìfẹ́ tó jinlẹ̀ fún Jèhófà àti ètò rẹ̀

  • Máa pa àwọn ìlànà Jèhófà mọ́, kó o sì ní ẹ̀rí ọkàn tó mọ́

  • Jẹ́ kí aṣọ rẹ àti ìrísí rẹ fi hàn pé Kristẹni ni ẹ́

  • Eré ìnàjú to yẹ Kristẹni ni kó o máa ṣe

  • Ó yẹ kó o wà láàárín ẹni ọdún mọ́kàndínlógún (19) sí márùndínlógójì (35)

  • Ó yẹ kó o ní ìlera tó dáa

  • Ó yẹ kó o lè kàwé, kọ̀wé, kó o sì lè sọ èdè tí wọ́n ń lò ní ẹ̀ka ọ́fíìsì yín

  • Tí wọ́n bá pè ẹ́ wá sí Bẹ́tẹ́lì, ó yẹ kó o ṣe tán láti wà níbẹ̀ fún ọdún kan, ó kéré tán

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́