ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • mwb20 March ojú ìwé 7
  • Mú Kí Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Rẹ Sunwọ̀n Sí I​—Máa Wàásù fún Àwọn Afọ́jú

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Mú Kí Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Rẹ Sunwọ̀n Sí I​—Máa Wàásù fún Àwọn Afọ́jú
  • Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2020
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ran Àwọn Afọ́jú Lọ́wọ́ Kí Wọ́n Lè Mọ Jèhófà
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2015
  • Ìwé Tó Ń Ṣe Àwọn Èèyàn Láǹfààní
    Bá A Ṣe Ń Ná Owó Tẹ́ Ẹ Fi Ń Ṣètọrẹ
  • Lílajú Sí Ìhìnrere
    Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1994
  • Wọ́n Fìfẹ́ Hàn sí Wọn Gan-an
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2023
Àwọn Míì
Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2020
mwb20 March ojú ìwé 7
Arábìnrin kan tó jẹ́ afọ́jú ń fi ọwọ́ ka ìtẹ̀jáde tó wà lédè àwọn afọ́jú.

MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI

Mú Kí Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Rẹ Sunwọ̀n Sí I​—Máa Wàásù fún Àwọn Afọ́jú

ÌDÍ TÓ FI ṢE PÀTÀKÌ: Ọ̀pọ̀ àwọn afọ́jú ni kì í fẹ́ bá àwọn tí wọn ò mọ̀ rí sọ̀rọ̀. Torí náà, ó máa ń gba ọgbọ́n ká tó lè wàásù fún wọn. Jèhófà ò fọ̀rọ̀ àwọn afọ́jú ṣeré rárá. (Le 19:14) Àwa náà lè tẹ̀ lé àpẹẹrẹ rẹ̀ tá a bá ń wá bá a ṣe máa ràn wọ́n lọ́wọ́ kí wọ́n lè mọ Ọlọ́run.

BÓ O ṢE LÈ ṢE É:

  • “Wá” àwọn afọ́jú lọ. (Mt 10:11) Ṣé o mọ ẹnì kan tí afọ́jú wà nínú ìdílé rẹ̀? Ṣé ilé ìwé àwọn afọ́jú wà ní ìpínlẹ̀ ìwàásù yín tàbí àwọn àjọ tó ń pèsè ìrànwọ́ fún àwọn afọ́jú tàbí ibi tí wọ́n ti ń tọ́jú àwọn afọ́jú? Ṣé ó ṣeé ṣe kí wọ́n nífẹ̀ẹ́ sí àwọn ìwé wa tó wà lédè àwọn afọ́jú?

  • Fi hàn pé o nífẹ̀ẹ́ wọn. Tó o bá ṣe ohun tó fi hàn pé ọ̀rọ̀ wọn jẹ ẹ́ lọ́kàn, tó o sì fi tẹ̀rín tọ̀yàyà bá wọn sọ̀rọ̀, ìyẹn á jẹ́ kára tù wọ́n. O lè fi ohun tí wọ́n máa nífẹ̀ẹ́ sí bẹ̀rẹ̀ ìjíròrò rẹ

  • Ràn wọ́n lọ́wọ́ kí wọ́n lè sún mọ́ Jèhófà. Ètò Ọlọ́run ti pèsè onírúurú ìtẹ̀jáde ká lè ṣèrànwọ́ fáwọn afọ́jú àtàwọn tí kò fi bẹ́ẹ̀ ríran dáadáa. O lè bi í pé èwo ló nífẹ̀ẹ́. Kí alábòójútó iṣẹ́ ìsìn rí i pé ìránṣẹ́ ìwé ìkẹ́kọ̀ọ́ béèrè fún irú èyí tí afọ́jú tó wà ládùúgbò yín bá nífẹ̀ẹ́ sí

Àwọn ìwé ìkẹ́kọ̀ọ́ fún àwọn tí kò ríran dáadáa àti àwọn afọ́jú wà ní ọ̀pọ̀ èdè. Oríṣiríṣi ọ̀nà tí àwọn ìwé náà wà nìyí:

  • Àwọn àtẹ́tísí lórí ìkànnì wa

  • Onílẹ́tà gàdàgbà

  • Braille (ìwé tó ṣe e kà fún àwọn afọ́jú)

  • Ìwé tó ṣeé lò lórí ẹ̀rọ táwọn afọ́jú fi ń kàwé

  • Ìwé tó ṣeé lò lórí ẹ̀rọ tó ń kàwé fáwọn afọ́jú

Àwòrán: 1. Arábìnrin kan ń ka ìtẹ̀jáde tó wà fáwọn afọ́jú. 2. Arábìnrin kan ń lo ẹ̀rọ táwọn afọ́jú fi ń kàwé.

Àwọn tó ń lo ìwé àwọn afọ́jú àti ẹ̀rọ táwọn afọ́jú fi ń kàwé

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́