ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • mwb20 December ojú ìwé 3
  • Ìfẹ́ Ló Ń Mú Ká Fara Mọ́ Ìbáwí Jèhófà

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ìfẹ́ Ló Ń Mú Ká Fara Mọ́ Ìbáwí Jèhófà
  • Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2020
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ìfẹ́ Ló Ń Mú Kí Jèhófà Bá Wa Wí
    Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2021
  • Ìdí Tí Ìyọlẹ́gbẹ́ Fi Jẹ́ Ìpèsè Onífẹ̀ẹ́
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2015
  • O Lè Jẹ́ Olóòótọ́ Tí Èèyàn Ẹ Kan Bá Fi Jèhófà Sílẹ̀
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2021
  • Kíkojú Ìpènijà Ìdúróṣinṣin
    Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1996
Àwọn Míì
Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2020
mwb20 December ojú ìwé 3

MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI

Ìfẹ́ Ló Ń Mú Ká Fara Mọ́ Ìbáwí Jèhófà

Ìyọlẹ́gbẹ́ máa ń dáàbò bo ìjọ, ó tún jẹ́ ìbáwí fún ẹni tí kò ronú pìwà dà. (1Kọ 5:​6, 11) Tá a bá sì fara mọ́ ìbáwí yìí látọ̀dọ̀ Jèhófà, ṣe là ń fìfẹ́ hàn. Àmọ́ ṣé a gbà pé bẹ́ẹ̀ lọ̀rọ̀ rí lóòótọ́, torí kì í rọrùn tí wọ́n bá yọ èèyàn wa kan lẹ́gbẹ́. Ó máa ń fa ẹ̀dùn ọkàn fún gbogbo àwọn tọ́rọ̀ kàn, títí kan àwọn mọ̀lẹ́bí ẹni yẹn àtàwọn tó wà nínú ìgbìmọ̀ tó bójú tó ọ̀rọ̀ náà?

Ohun àkọ́kọ́ ni pé tá a bá fara mọ́ ìbáwí Jèhófà, ṣe là ń fi hàn pé a nífẹ̀ẹ́ rè, a sì bọ̀wọ̀ fún ìlànà rẹ̀ lórí ìwà mímọ́. (1Pe 1:​14-16) Ìyẹn á sì fi hàn pé a nífẹ̀ẹ́ ẹni tí wọ́n yọ lẹ́gbẹ́ náà. Ìbáwí kì í ṣe ohun ayọ̀, àmọ́ ó máa ń “so èso àlàáfíà ti òdodo.” (Heb 12:​5, 6, 11) Tá a bá ṣì ń ní nǹkan kan ṣe pẹ̀lú ẹni tí wọ́n ti yọ lẹ́gbẹ́ tàbí ẹni tó mú ara ẹ̀ kúrò lẹ́gbẹ́, a ò fi hàn pé a fara mọ́ ìbáwí Jèhófà. Ká má gbàgbé pé Jèhófà kì í bá àwa èèyàn rẹ̀ wí “kọjá ààlà.” (Jer 30:11) Tá a bá fara mọ́ ìbáwí Jèhófà, tá a sì gbájú mọ́ nǹkan tẹ̀mí, ìyẹn máa fi wá lọ́kàn balẹ̀ pé ẹni náà máa pa dà sọ́dọ̀ Jèhófà Baba wa aláàánú.​—Ais 1:​16-18; 55:7.

WO FÍDÍÒ NÁÀ JẸ́ ADÚRÓṢINṢIN BÓ O ṢE Ń FI ỌKÀN KAN SIN JÈHÓFÀ, KÓ O SÌ DÁHÙN ÀWỌN ÌBÉÈRÈ YÌÍ:

  • Àwòrán látinú fídíò ‘Jẹ́ Adúróṣinṣin Bó O Ṣe Ń Fi Ọkàn Kan Sin Jèhófà.’ Gabriella àti Ben ń sunkún nígbà tí wọ́n ka lẹ́tà tí ọmọ wọn tó filé sílẹ̀ kọ.

    Báwo ló ṣe máa ń rí lára àwọn òbí tí ọmọ wọn bá fi Jèhófà sílẹ̀?

  • Àwòrán látinú fídíò ‘Jẹ́ Adúróṣinṣin Bó O Ṣe Ń Fi Ọkàn Kan Sin Jèhófà.’ Àwọn ará ń kí Gabriella àti Ben, wọ́n sì ń tù wọ́n nínú lẹ́yìn típàdé parí.

    Báwo làwọn ará ìjọ ṣe lè ran àwọn tó wà nínú ìdílé náà lọ́wọ́?

  • Àwòrán látinú fídíò ‘Jẹ́ Adúróṣinṣin Bó O Ṣe Ń Fi Ọkàn Kan Sin Jèhófà.’ Gabriella ń fojú inú wo ohun tó ṣẹlẹ̀ nígbà tí Kórà ṣọ̀tẹ̀ sí Jèhófà.

    Àpẹẹrẹ wo la rí látinú Bíbélì tó jẹ́ ká mọ bó ṣe ṣe pàtàkì tó pé kí ìfẹ́ tá a ní sí Jèhófà pọ̀ ju ti àwọn mọ̀lẹ́bí wa lọ?

  • Àwòrán látinú fídíò ‘Jẹ́ Adúróṣinṣin Bó O Ṣe Ń Fi Ọkàn Kan Sin Jèhófà.’ Nígbà tí wọ́n délé lẹ́yìn ìpàdé, Gabriella ń fi ọ̀rọ̀ tí ọmọ wọn fi ránṣẹ́ sí i han Ben.

    Báwo la ṣe lè fi hàn pé Jèhófà la jẹ́ adúróṣinṣin sí dípò àwọn mọ̀lẹ́bí wa?

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́