ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • mwb21 November ojú ìwé 9
  • Báwo Làwọn Arábìnrin Ṣe Lè Ṣe Púpọ̀ Sí I Lẹ́nu Iṣẹ́ Ìsìn Jèhófà?

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Báwo Làwọn Arábìnrin Ṣe Lè Ṣe Púpọ̀ Sí I Lẹ́nu Iṣẹ́ Ìsìn Jèhófà?
  • Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2021
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ẹ Máa Fún Àwọn Arábìnrin Níṣìírí
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2020
  • Ṣé Ojú Tí Jèhófà Fi Ń Wo Àwọn Obìnrin Lo Fi Ń Wò Wọ́n?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2024
  • “Àwọn Obìnrin Tí Ń Ṣiṣẹ́ Kára Nínú Olúwa”
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2000
  • Àwọn Ọ̀nà Tó O Lè Gbà Mú Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Rẹ Gbòòrò Sí I
    A Ṣètò Wa Láti Ṣe Ìfẹ́ Jèhófà
Àwọn Míì
Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2021
mwb21 November ojú ìwé 9
Àwòrán: Iṣẹ́ ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ làwọn arábìnrin yìí ń ṣe, wọ́n sì ń fayọ̀ ṣe é. 1. Arábìnrin kan wà lóde ìwàásù. 2. Arábìnrin kan wà níbi iṣẹ́ ìkọ́lé. 3. Arábìnrin kan ń tún Gbọ̀ngàn Ìjọba ṣe. 4. Arábìnrin kan ń kọ́ arábìnrin àgbàlagbà kan bó ṣe lè lo fóònù. 5. Arábìnrin kan ń ran ọmọbìnrin rẹ̀ lọ́wọ́ kó lè dáhùn nípàdé. 6. Àwọn arábìnrin méjì ń wàásù nígbà òtútù.

MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI

Báwo Làwọn Arábìnrin Ṣe Lè Ṣe Púpọ̀ Sí I Lẹ́nu Iṣẹ́ Ìsìn Jèhófà?

Iṣẹ́ kékeré kọ́ làwọn arábìnrin wa ń ṣe lẹ́nu iṣẹ́ ìsìn Jèhófà. (Sm 68:11) Bí àpẹẹrẹ, àwọn ló ń darí ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì tó pọ̀ jù, àwọn ló pọ̀ jù lára àwọn aṣáájú-ọ̀nà déédéé. Ọ̀pọ̀ lára wọn ló sì ń ṣiṣẹ́ kára lẹ́nu iṣẹ́ ìsìn Bẹ́tẹ́lì, míṣọ́nnárì, iṣẹ́ ìkọ́lé àti iṣẹ́ ìtúmọ̀ èdè. Yàtọ̀ síyẹn, àwọn arábìnrin tí wọ́n jẹ́ ẹni tẹ̀mí máa ń gbé ìdílé wọn ró, wọ́n sì ń fún ìjọ lókun. (Owe 14:1) Òótọ́ ni pé àwọn arábìnrin ò láǹfààní láti di alàgbà tàbí ìránṣẹ́ iṣẹ́ òjíṣẹ́, síbẹ̀ ọ̀pọ̀ nǹkan ni wọ́n lè ṣe láti ran ìjọ lọ́wọ́. Tó o bá jẹ́ arábìnrin, báwo lo ṣe lè ṣe púpọ̀ sí i lẹ́nu iṣẹ́ ìsìn Jèhófà?

  • Gbìyànjú láti ní àwọn ànímọ́ Kristẹni.​—1Ti 3:11; 1Pe 3:3-6

  • Máa ṣèrànwọ́ fáwọn arábìnrin tí ò fi bẹ́ẹ̀ nírìírí.​—Tit 2:3-5

  • Máa lo àkókò tó pọ̀ sí i lẹ́nu iṣẹ́ ìwàásù, kó o sì mú kí ọ̀nà tó ò ń gbà kọ́ni lẹ́kọ̀ọ́ sunwọ̀n sí i

  • Kọ́ èdè míì

  • Lọ sìn níbi tá a ti nílò àwọn oníwàásù púpọ̀ sí i

  • Sapá láti sìn ní Bẹ́tẹ́lì tàbí láti yọ̀nda ara rẹ níbi tá a ti ń kọ́ àwọn ilé tá à ń lò fún ìjọsìn

  • Sapá kó o lè lọ sí Ilé Ẹ̀kọ́ Àwọn Ajíhìnrere

Ẹ WO FÍDÍÒ NÁÀ “ÀWỌN OBÌNRIN TÓ Ń ṢIṢẸ́ KÁRA NÍNÚ OLÚWA,” KẸ́ Ẹ SÌ DÁHÙN ÌBÉÈRÈ YÌÍ:

  • Kí lo rí kọ́ látinú ohun táwọn arábìnrin yìí sọ?

Àwọn arábìnrin mẹ́tẹ̀ẹ̀ta tó wà nínú fídíò “Àwọn Obìnrin Tó Ń Ṣiṣẹ́ Kára Nínú Olúwa.”
    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́