ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • sn orin 127
  • Ibi Tá A Ń Fi Orúkọ Rẹ Pè

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ibi Tá A Ń Fi Orúkọ Rẹ Pè
  • Kọrin sí Jèhófà
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ibi Tá À Ń Fi Orúkọ Rẹ Pè
    “Fi Ayọ̀ Kọrin” sí Jèhófà
  • Jèhófà Ni Ìyìn àti Ògo Yẹ!
    “Fi Ayọ̀ Kọrin” sí Jèhófà
  • Jọ̀ọ́, Gbọ́ Àdúrà Mi
    “Fi Ayọ̀ Kọrin” sí Jèhófà
  • Jọ̀wọ́ Gbọ́ Àdúrà Mi
    Kọrin sí Jèhófà
Àwọn Míì
Kọrin sí Jèhófà
sn orin 127

Orin 127

Ibi Tá A Ń Fi Orúkọ Rẹ Pè

Bíi Ti Orí Ìwé

(1 Kíróníkà 29:16)

1. Ọlá ńlá lo dá wa Jèhófà,

Láti kọ́lé fórúkọ rẹ!

Inú wa dùn láti fi fún ọ

Kí ògo rẹ lè máa pọ̀ síi.

Ohunkóhun yòówù ká fún ọ,

Tìrẹ ni wọ́n tẹ́lẹ̀tẹ́lẹ̀.

Ohun gbogbo táa mọ̀ táa sì ní,

Tayọ̀tayọ̀ la yọ̀ǹda wọn.

(ÈGBÈ)

A fẹ́ fi ibí yìí fún ọ

Kórúkọ rẹ wà níbẹ̀.

A yà á sí mímọ́ fún ọ;

Jọ̀wọ́ gbà á tìrẹ ni.

2. Ọlá ńlá la bù fún ọ Baba,

Bí ìyìn rẹ ṣe gbabí kan.

Jẹ́ káwọn tó ńmọ̀ ọ́ máa pọ̀ síi

Ògo rẹ yóò lè máa pọ̀ síi.

Torí ìwọ laó máa sìn níbí,

A ó máa tọjú rẹ̀ dáadáa.

Kó máa jẹ́ ẹ̀rí fáwọn èèyàn,

Kó lè fi kún ìwàásù wa.

(ÈGBÈ)

A fẹ́ fi ibí yìí fún ọ

Kórúkọ rẹ wà níbẹ̀.

A yà á sí mímọ́ fún ọ;

Jọ̀wọ́ gbà á tìrẹ ni.

(Tún wo 1 Ọba 8:18, 27; 1 Kíró. 29:11-14; Ìṣe 20:24.)

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́