ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • sn orin 131
  • Jèhófà Ń Ṣe Ọ̀nà Àsálà

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Jèhófà Ń Ṣe Ọ̀nà Àsálà
  • Kọrin sí Jèhófà
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Jèhófà Ń Ṣe Ọ̀nà Àsálà
    “Fi Ayọ̀ Kọrin” sí Jèhófà
  • Jẹ́ Kí N Ní Ìgboyà
    “Fi Ayọ̀ Kọrin” sí Jèhófà
  • Àkànṣe Ìní
    “Fi Ayọ̀ Kọrin” sí Jèhófà
  • Àkànṣe Dúkìá
    Kọrin sí Jèhófà—Àwọn Orin Tuntun
Àwọn Míì
Kọrin sí Jèhófà
sn orin 131

Orin 131

Jèhófà Ń Ṣe Ọ̀nà Àsálà

Bíi Ti Orí Ìwé

(2 Sámúẹ́lì 22:1-8)

1. Jèhófà, ìwọ ni Ọlọ́run alààyè;

Iṣẹ́ rẹ̀ pọ̀ láyé,

ní òkun òun sánmà.

Kò sọ́lọ́run tó lè bá ọ dọ́gba, kò

sí rárá.

Àwọn ọ̀tá wa gbé.

(ÈGBÈ)

Jèhófà ńṣọ̀nà àsálà fólóòótọ́.

Èèyàn rẹ̀ yóò rí bágbára rẹ̀ ti pọ̀ tó.

Pẹ̀lú ìgboyà àtìgbàgbọ́,

a ńkókìkí,

A sì ńyin Jèhófà,

Olùṣọ̀nà àsálà.

2. Ìjárá ikú lè yí mi ká, nó pè ọ́,

“Jèhófà jọ̀ọ́, fún mi

lókun àtìgboyà.”

Gbọ́ ohùn mi láti orí ìtẹ́ rẹ,

“Gbà mí là;

Ọlọ́run, kó mi yọ.”

(ÈGBÈ)

Jèhófà ńṣọ̀nà àsálà fólóòótọ́.

Èèyàn rẹ̀ yóò rí bágbára rẹ̀ ti pọ̀ tó.

Pẹ̀lú ìgboyà àtìgbàgbọ́,

a ńkókìkí,

A sì ńyin Jèhófà,

Olùṣọ̀nà àsálà.

3. Ohùn rẹ yóò dún bí

ààrá látọ̀run wá.

Ọ̀tá rẹ yóò páyà;

ìránṣẹ́ rẹ yóò yọ̀.

Alèwílèṣe ni ọ́ Baba;

Àwa yóò sì rí

Bí wàá ṣe gbà wá là.

(ÈGBÈ)

Jèhófà ńṣọ̀nà àsálà fólóòótọ́.

Èèyàn rẹ̀ yóò rí bágbára rẹ̀ ti pọ̀ tó.

Pẹ̀lú ìgboyà àtìgbàgbọ́,

a ńkókìkí,

A sì ńyin Jèhófà,

Olùṣọ̀nà àsálà.

(Tún wo Sm. 18:1, 2; 144:1, 2.)

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́