Sáàmù 93:2 Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun 2 Tipẹ́tipẹ́ ni ìtẹ́ rẹ ti fìdí múlẹ̀ gbọn-in;+O ti wà láti ayébáyé.+ Àìsáyà 40:28 Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun 28 Ṣé o ò mọ̀ ni? Ṣé o ò tíì gbọ́ ni? Jèhófà, Ẹlẹ́dàá àwọn ìkángun ayé, jẹ́ Ọlọ́run títí ayé.+ Kì í rẹ̀ ẹ́, okun rẹ̀ kì í sì í tán.+ Àwámáridìí ni òye rẹ̀.*+ Hábákúkù 1:12 Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun 12 Jèhófà, ṣebí láti ayérayé ni ìwọ ti wà?+ Ọlọ́run mi, Ẹni Mímọ́ mi, ìwọ kì í kú.*+ Jèhófà, ìwọ lo yàn wọ́n láti ṣèdájọ́;Àpáta mi,+ o lò wọ́n láti fìyà jẹni.*+ 1 Tímótì 1:17 Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun 17 Nítorí náà, kí ọlá àti ògo máa jẹ́ ti Ọba ayérayé,+ ẹni tí kò lè díbàjẹ́,+ tí a kò lè rí,+ Ọlọ́run kan ṣoṣo,+ títí láé àti láéláé. Àmín. Ìfihàn 1:8 Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun 8 Jèhófà* Ọlọ́run sọ pé, “Èmi ni Ááfà àti Ómégà,*+ Ẹni tó ti wà tipẹ́, tó wà báyìí, tó sì ń bọ̀, Olódùmarè.”+ Ìfihàn 15:3 Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun 3 Wọ́n ń kọ orin Mósè+ ẹrú Ọlọ́run àti orin Ọ̀dọ́ Àgùntàn+ náà, pé: “Jèhófà* Ọlọ́run, Olódùmarè,+ àwọn iṣẹ́ rẹ tóbi, ó sì kàmàmà.+ Òdodo àti òótọ́ ni àwọn ọ̀nà rẹ,+ Ọba ayérayé.+
28 Ṣé o ò mọ̀ ni? Ṣé o ò tíì gbọ́ ni? Jèhófà, Ẹlẹ́dàá àwọn ìkángun ayé, jẹ́ Ọlọ́run títí ayé.+ Kì í rẹ̀ ẹ́, okun rẹ̀ kì í sì í tán.+ Àwámáridìí ni òye rẹ̀.*+
12 Jèhófà, ṣebí láti ayérayé ni ìwọ ti wà?+ Ọlọ́run mi, Ẹni Mímọ́ mi, ìwọ kì í kú.*+ Jèhófà, ìwọ lo yàn wọ́n láti ṣèdájọ́;Àpáta mi,+ o lò wọ́n láti fìyà jẹni.*+
17 Nítorí náà, kí ọlá àti ògo máa jẹ́ ti Ọba ayérayé,+ ẹni tí kò lè díbàjẹ́,+ tí a kò lè rí,+ Ọlọ́run kan ṣoṣo,+ títí láé àti láéláé. Àmín.
8 Jèhófà* Ọlọ́run sọ pé, “Èmi ni Ááfà àti Ómégà,*+ Ẹni tó ti wà tipẹ́, tó wà báyìí, tó sì ń bọ̀, Olódùmarè.”+
3 Wọ́n ń kọ orin Mósè+ ẹrú Ọlọ́run àti orin Ọ̀dọ́ Àgùntàn+ náà, pé: “Jèhófà* Ọlọ́run, Olódùmarè,+ àwọn iṣẹ́ rẹ tóbi, ó sì kàmàmà.+ Òdodo àti òótọ́ ni àwọn ọ̀nà rẹ,+ Ọba ayérayé.+