-
1 Pétérù 2:4-7Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
4 Bí ẹ ṣe wá sọ́dọ̀ rẹ̀, ẹni tó jẹ́ òkúta ààyè tí àwọn èèyàn kọ̀ sílẹ̀,+ àmọ́ tó jẹ́ àyànfẹ́, tó sì ṣeyebíye lójú Ọlọ́run,+ 5 bí àwọn òkúta ààyè, à ń fi ẹ̀yin pẹ̀lú kọ́ ilé tẹ̀mí+ kí ẹ lè di ẹgbẹ́ àlùfáà mímọ́, kí ẹ lè máa rú àwọn ẹbọ ẹ̀mí+ tí Ọlọ́run tẹ́wọ́ gbà nípasẹ̀ Jésù Kristi.+ 6 Torí Ìwé Mímọ́ sọ pé: “Wò ó! Màá fi òkúta àyànfẹ́ kan lélẹ̀ ní Síónì, òkúta ìpìlẹ̀ igun ilé tó ṣeyebíye, kò sì sí ẹni tó ní ìgbàgbọ́ nínú rẹ̀ tí a máa já kulẹ̀.”*+
7 Nítorí náà, ẹ̀yin ló ṣe iyebíye fún, torí ẹ jẹ́ onígbàgbọ́; àmọ́ fún àwọn tí kò gbà gbọ́, “òkúta tí àwọn kọ́lékọ́lé kọ̀ sílẹ̀,+ òun ló wá di olórí òkúta igun ilé”*+
-