ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • 1 Àwọn Ọba 8:25
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 25 Ní báyìí, Jèhófà Ọlọ́run Ísírẹ́lì, mú ìlérí tí o ṣe fún ìránṣẹ́ rẹ Dáfídì bàbá mi ṣẹ, nígbà tí o sọ pé: ‘Kò ní ṣàìsí ọkùnrin kan láti ìlà ìdílé rẹ níwájú mi tí yóò máa jókòó sórí ìtẹ́ Ísírẹ́lì, bí àwọn ọmọ rẹ bá ṣáà ti ń fiyè sí ọ̀nà wọn, tí wọ́n sì ń rìn níwájú mi bí ìwọ náà ṣe rìn níwájú mi.’+

  • Sáàmù 89:3, 4
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    •  3 “Mo ti bá àyànfẹ́ mi dá májẹ̀mú;+

      Mo ti búra fún Dáfídì ìránṣẹ́ mi pé:+

       4 ‘Màá fìdí ọmọ* rẹ+ múlẹ̀ títí láé,

      Màá gbé ìtẹ́ rẹ ró, á sì wà láti ìran dé ìran.’”+ (Sélà)

  • Sáàmù 89:20
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 20 Mo ti rí Dáfídì ìránṣẹ́ mi;+

      Mo ti fi òróró mímọ́ mi yàn án.+

  • Sáàmù 89:36
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 36 Àwọn ọmọ* rẹ̀ yóò wà títí láé;+

      Ìtẹ́ rẹ̀ yóò wà títí lọ bí oòrùn níwájú mi.+

  • Àìsáyà 9:7
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    •  7 Àkóso* rẹ̀ á máa gbilẹ̀ títí lọ,

      Àlàáfíà kò sì ní lópin,+

      Lórí ìtẹ́ Dáfídì+ àti lórí ìjọba rẹ̀,

      Kó lè fìdí rẹ̀ múlẹ̀ gbọn-in,+ kó sì gbé e ró,

      Nípasẹ̀ ìdájọ́+ tí ó tọ́ àti òdodo,+

      Láti ìsinsìnyí lọ àti títí láé.

      Ìtara Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun máa ṣe èyí.

  • Jeremáyà 33:20, 21
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 20 “Ohun tí Jèhófà sọ nìyí, ‘Bí ẹ bá lè ba májẹ̀mú mi nípa ọ̀sán àti májẹ̀mú mi nípa òru jẹ́, pé kí ọ̀sán àti òru má ṣe wà ní àkókò wọn+ 21 nìkan ni májẹ̀mú tí mo bá Dáfídì ìránṣẹ́ mi dá tó lè bà jẹ́,+ tí kò fi ní máa ní ọmọ tó ń jọba lórí ìtẹ́ rẹ̀,+ bẹ́ẹ̀ náà ni májẹ̀mú tí mo bá àwọn àlùfáà tó jẹ́ ọmọ Léfì dá, àwọn òjíṣẹ́ mi.+

  • Mátíù 9:27
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 27 Bí Jésù ṣe kúrò níbẹ̀, àwọn ọkùnrin afọ́jú méjì + tẹ̀ lé e, wọ́n ń kígbe pé: “Ṣàánú wa, Ọmọ Dáfídì.”

  • Lúùkù 1:69
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 69 Ó ti gbé ìwo ìgbàlà*+ kan dìde fún wa ní ilé Dáfídì ìránṣẹ́ rẹ̀,+

  • Ìṣe 2:30, 31
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 30 Nítorí pé wòlíì ni, ó sì mọ̀ pé Ọlọ́run ti búra fún òun pé òun máa gbé ọ̀kan lára àwọn ọmọ rẹ̀* gorí ìtẹ́ rẹ̀,+ 31 ó ti rí i tẹ́lẹ̀, ó sì sọ nípa àjíǹde Kristi, pé a kò fi í sílẹ̀ nínú Isà Òkú,* bẹ́ẹ̀ ni ara rẹ̀ kò rí ìdíbàjẹ́.*+

  • Ìṣe 13:22, 23
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 22 Lẹ́yìn tó mú un kúrò, ó gbé Dáfídì dìde láti jẹ́ ọba wọn,+ ẹni tó jẹ́rìí nípa rẹ̀, tó sì sọ pé: ‘Mo ti rí Dáfídì ọmọ Jésè,+ ẹni tí ọkàn mi fẹ́;+ yóò ṣe gbogbo ohun tí mo fẹ́.’ 23 Gẹ́gẹ́ bí ìlérí tó ṣe, látọ̀dọ̀ ọmọ* ọkùnrin yìí ni Ọlọ́run ti mú olùgbàlà wá fún Ísírẹ́lì, ìyẹn Jésù.+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́