ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • 2 Àwọn Ọba 23
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

Ohun Tó Wà Nínú Ìwé 2 Àwọn Ọba

      • Àwọn àtúnṣe tí Jòsáyà ṣe (1-20)

      • Wọ́n ṣe Ìrékọjá (21-23)

      • Àwọn àtúnṣe míì tí Jòsáyà ṣe (24-27)

      • Ikú Jòsáyà (28-30)

      • Jèhóáhásì di ọba Júdà (31-33)

      • Jèhóákímù di ọba Júdà (34-37)

2 Àwọn Ọba 23:1

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Kr 34:29, 30

2 Àwọn Ọba 23:2

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 31:26
  • +Ẹk 24:8
  • +2Ọb 22:8

2 Àwọn Ọba 23:3

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “tún májẹ̀mú dá.”

  • *

    Wo Àlàyé Ọ̀rọ̀.

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 11:17; 2Kr 15:10, 12
  • +Joṣ 24:24, 25; 2Kr 34:31, 32

2 Àwọn Ọba 23:4

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Wo Àlàyé Ọ̀rọ̀.

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 22:4
  • +2Ọb 21:1, 7; 2Kr 34:4
  • +1Ọb 12:28, 29

2 Àwọn Ọba 23:5

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 21:1, 3; Jer 8:1, 2

2 Àwọn Ọba 23:6

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Wo Àlàyé Ọ̀rọ̀.

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 21:1, 7
  • +Di 7:25
  • +2Kr 34:4

2 Àwọn Ọba 23:7

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Wo Àlàyé Ọ̀rọ̀.

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Le 18:22; Di 23:17, 18; 1Ọb 15:11, 12; 22:46

2 Àwọn Ọba 23:8

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 21:17, 19; 1Ọb 15:22
  • +Jẹ 21:31

2 Àwọn Ọba 23:9

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Isk 44:10; Mal 2:7, 8

2 Àwọn Ọba 23:10

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Wo Àlàyé Ọ̀rọ̀, “Gẹ̀hẹ́nà.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 7:31
  • +Joṣ 15:8
  • +2Ọb 16:2, 3; Jer 32:35

2 Àwọn Ọba 23:11

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “yàrá ìjẹun.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 4:19; Isk 8:16

2 Àwọn Ọba 23:12

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 19:13; Sef 1:4, 5
  • +2Ọb 21:1, 5

2 Àwọn Ọba 23:13

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “ọ̀tún.” Ìyẹn, gúúsù, tí èèyàn bá dojú kọ ìlà oòrùn.

  • *

    Ìyẹn, Òkè Ólífì, pàápàá ìkángun gúúsù tí wọ́n tún ń pè ní Òkè Ìpèníjà.

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sef 1:4, 5
  • +1Ọb 11:5, 7

2 Àwọn Ọba 23:14

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Wo Àlàyé Ọ̀rọ̀.

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 23:24; Di 7:5; 2Kr 34:1, 3

2 Àwọn Ọba 23:15

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Wo Àlàyé Ọ̀rọ̀.

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Ọb 12:28, 33
  • +2Kr 34:6, 7

2 Àwọn Ọba 23:16

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Ọb 13:2

2 Àwọn Ọba 23:17

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Ọb 13:1

2 Àwọn Ọba 23:18

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Ọb 13:30, 31

2 Àwọn Ọba 23:19

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Ọb 12:25, 31; 13:32; 2Ọb 17:9
  • +2Kr 34:6, 7

2 Àwọn Ọba 23:20

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Ọb 13:2

2 Àwọn Ọba 23:21

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Kr 35:1
  • +Ẹk 12:3-14

2 Àwọn Ọba 23:22

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Kr 35:18, 19

2 Àwọn Ọba 23:24

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “àwọn òrìṣà ìdílé; òrìṣà.”

  • *

    Ó ṣeé ṣe kí ọ̀rọ̀ Hébérù yìí ní í ṣe pẹ̀lú ọ̀rọ̀ tí wọ́n ń lò fún “ìgbẹ́,” wọ́n sì máa ń lò ó fún ohun tí wọ́n bá kórìíra.

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Le 19:31; Di 18:10, 11; 2Ọb 21:1, 6; Ais 8:19
  • +Jẹ 31:19
  • +Nọ 33:52; Di 12:2
  • +2Ọb 22:8

2 Àwọn Ọba 23:25

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Wo Àlàyé Ọ̀rọ̀.

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 4:29

2 Àwọn Ọba 23:26

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 21:11, 12; 24:3, 4; Jer 15:4

2 Àwọn Ọba 23:27

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 29:28; 2Ọb 25:11; Isk 23:33
  • +2Ọb 18:11; 21:13
  • +Di 12:5; 1Ọb 8:29; 9:3

2 Àwọn Ọba 23:29

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Ọb 9:15; 2Kr 35:20-25; Sek 12:11

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    9/15/2000, ojú ìwé 30

2 Àwọn Ọba 23:30

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Kr 36:1, 2

2 Àwọn Ọba 23:31

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 22:11
  • +2Ọb 24:18

2 Àwọn Ọba 23:32

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 21:1, 2, 19-21

2 Àwọn Ọba 23:33

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tálẹ́ńtì kan jẹ́ kìlógíráàmù 34.2. Wo Àfikún B14.

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 23:29
  • +Jer 39:5; 52:10
  • +2Kr 36:3

2 Àwọn Ọba 23:34

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Kr 36:4, 5
  • +Jer 22:11, 12

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Jeremáyà, ojú ìwé 158-159

2 Àwọn Ọba 23:36

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 1:3; 22:18, 19
  • +2Kr 36:5

2 Àwọn Ọba 23:37

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 26:21; 36:22-24
  • +2Kr 28:24, 25; 33:1, 4

Àwọn míì

2 Ọba 23:12Kr 34:29, 30
2 Ọba 23:2Di 31:26
2 Ọba 23:2Ẹk 24:8
2 Ọba 23:22Ọb 22:8
2 Ọba 23:32Ọb 11:17; 2Kr 15:10, 12
2 Ọba 23:3Joṣ 24:24, 25; 2Kr 34:31, 32
2 Ọba 23:42Ọb 22:4
2 Ọba 23:42Ọb 21:1, 7; 2Kr 34:4
2 Ọba 23:41Ọb 12:28, 29
2 Ọba 23:52Ọb 21:1, 3; Jer 8:1, 2
2 Ọba 23:62Ọb 21:1, 7
2 Ọba 23:6Di 7:25
2 Ọba 23:62Kr 34:4
2 Ọba 23:7Le 18:22; Di 23:17, 18; 1Ọb 15:11, 12; 22:46
2 Ọba 23:8Joṣ 21:17, 19; 1Ọb 15:22
2 Ọba 23:8Jẹ 21:31
2 Ọba 23:9Isk 44:10; Mal 2:7, 8
2 Ọba 23:10Jer 7:31
2 Ọba 23:10Joṣ 15:8
2 Ọba 23:102Ọb 16:2, 3; Jer 32:35
2 Ọba 23:11Di 4:19; Isk 8:16
2 Ọba 23:12Jer 19:13; Sef 1:4, 5
2 Ọba 23:122Ọb 21:1, 5
2 Ọba 23:13Sef 1:4, 5
2 Ọba 23:131Ọb 11:5, 7
2 Ọba 23:14Ẹk 23:24; Di 7:5; 2Kr 34:1, 3
2 Ọba 23:151Ọb 12:28, 33
2 Ọba 23:152Kr 34:6, 7
2 Ọba 23:161Ọb 13:2
2 Ọba 23:171Ọb 13:1
2 Ọba 23:181Ọb 13:30, 31
2 Ọba 23:191Ọb 12:25, 31; 13:32; 2Ọb 17:9
2 Ọba 23:192Kr 34:6, 7
2 Ọba 23:201Ọb 13:2
2 Ọba 23:212Kr 35:1
2 Ọba 23:21Ẹk 12:3-14
2 Ọba 23:222Kr 35:18, 19
2 Ọba 23:24Le 19:31; Di 18:10, 11; 2Ọb 21:1, 6; Ais 8:19
2 Ọba 23:24Jẹ 31:19
2 Ọba 23:24Nọ 33:52; Di 12:2
2 Ọba 23:242Ọb 22:8
2 Ọba 23:25Di 4:29
2 Ọba 23:262Ọb 21:11, 12; 24:3, 4; Jer 15:4
2 Ọba 23:27Di 29:28; 2Ọb 25:11; Isk 23:33
2 Ọba 23:272Ọb 18:11; 21:13
2 Ọba 23:27Di 12:5; 1Ọb 8:29; 9:3
2 Ọba 23:291Ọb 9:15; 2Kr 35:20-25; Sek 12:11
2 Ọba 23:302Kr 36:1, 2
2 Ọba 23:31Jer 22:11
2 Ọba 23:312Ọb 24:18
2 Ọba 23:322Ọb 21:1, 2, 19-21
2 Ọba 23:332Ọb 23:29
2 Ọba 23:33Jer 39:5; 52:10
2 Ọba 23:332Kr 36:3
2 Ọba 23:342Kr 36:4, 5
2 Ọba 23:34Jer 22:11, 12
2 Ọba 23:36Jer 1:3; 22:18, 19
2 Ọba 23:362Kr 36:5
2 Ọba 23:37Jer 26:21; 36:22-24
2 Ọba 23:372Kr 28:24, 25; 33:1, 4
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
  • 1
  • 2
  • 3
  • 4
  • 5
  • 6
  • 7
  • 8
  • 9
  • 10
  • 11
  • 12
  • 13
  • 14
  • 15
  • 16
  • 17
  • 18
  • 19
  • 20
  • 21
  • 22
  • 23
  • 24
  • 25
  • 26
  • 27
  • 28
  • 29
  • 30
  • 31
  • 32
  • 33
  • 34
  • 35
  • 36
  • 37
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
2 Àwọn Ọba 23:1-37

Àwọn Ọba Kejì

23 Nígbà náà, ọba ránṣẹ́, wọ́n sì pe gbogbo àwọn àgbààgbà Júdà àti Jerúsálẹ́mù jọ.+ 2 Lẹ́yìn náà, ọba lọ sí ilé Jèhófà pẹ̀lú gbogbo èèyàn Júdà, gbogbo àwọn tó ń gbé Jerúsálẹ́mù, àwọn àlùfáà àti àwọn wòlíì, ìyẹn gbogbo àwọn èèyàn náà, látorí ẹni kékeré dórí ẹni ńlá. Ó ka gbogbo ọ̀rọ̀ inú ìwé+ májẹ̀mú+ tí wọ́n rí ní ilé Jèhófà sí wọn létí.+ 3 Ọba dúró lẹ́gbẹ̀ẹ́ òpó, ó sì dá májẹ̀mú* níwájú Jèhófà+ pé gbogbo ọkàn àti gbogbo ara* ni òun á máa fi tẹ̀ lé Jèhófà, òun á sì máa pa àwọn àṣẹ rẹ̀ mọ́ àti àwọn ìránnilétí rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìlànà rẹ̀, láti máa ṣe ohun tí májẹ̀mú tí a kọ sínú ìwé yìí sọ. Gbogbo àwọn èèyàn náà sì fara mọ́ májẹ̀mú náà.+

4 Ọba wá pàṣẹ fún Hilikáyà+ àlùfáà àgbà àti àwọn àlùfáà yòókù àti àwọn aṣọ́nà pé kí wọ́n kó gbogbo nǹkan èlò tí àwọn èèyàn ṣe fún Báálì àti fún òpó òrìṣà*+ àti fún gbogbo ọmọ ogun ọ̀run jáde nínú tẹ́ńpìlì Jèhófà. Lẹ́yìn náà, ó dáná sun wọ́n ní ìta Jerúsálẹ́mù lórí ilẹ̀ onípele tó wà ní Kídírónì, ó sì kó eérú wọn lọ sí Bẹ́tẹ́lì.+ 5 Ó lé àwọn àlùfáà ọlọ́run ilẹ̀ àjèjì kúrò lẹ́nu iṣẹ́, àwọn tí ọba Júdà yàn láti máa mú ẹbọ rú èéfín lórí àwọn ibi gíga ní àwọn ìlú Júdà àti ní àyíká Jerúsálẹ́mù títí kan àwọn tó ń mú ẹbọ rú èéfín sí Báálì, sí oòrùn àti sí òṣùpá àti sí àwọn àgbájọ ìràwọ̀ sódíákì àti sí gbogbo ọmọ ogun ọ̀run.+ 6 Ó gbé òpó òrìṣà*+ jáde kúrò ní ilé Jèhófà lọ sí ẹ̀yìn Jerúsálẹ́mù, sí Àfonífojì Kídírónì, ó dáná sun ún+ ní Àfonífojì Kídírónì, ó lọ̀ ọ́ kúnná, ó sì fọ́n eruku rẹ̀ sórí sàréè àwọn èèyàn ìlú náà.+ 7 Ó tún wó àwọn ilé aṣẹ́wó ọkùnrin+ tó wà ní tẹ́ńpìlì, èyí tó wà nínú ilé Jèhófà àti ibi tí àwọn obìnrin ti ń hun aṣọ àgọ́ fún ojúbọ òpó òrìṣà.*

8 Lẹ́yìn náà, ó kó gbogbo àwọn àlùfáà jáde kúrò ní àwọn ìlú Júdà, ó sì sọ àwọn ibi gíga tí àwọn àlùfáà ti ń mú ẹbọ rú èéfín di ibi tí kò ṣeé lò fún ìjọsìn, láti Gébà+ títí dé Bíá-ṣébà.+ Ó tún wó àwọn ibi gíga ẹnubodè tó wà ní ibi àtiwọ ẹnubodè Jóṣúà olórí ìlú náà, èyí tó wà lápá òsì tí èèyàn bá wọ ẹnubodè ìlú náà. 9 Àwọn àlùfáà ibi gíga kò ṣiṣẹ́ níbi pẹpẹ Jèhófà tó wà ní Jerúsálẹ́mù,+ àmọ́ wọ́n máa ń jẹ búrẹ́dì aláìwú pẹ̀lú àwọn arákùnrin wọn. 10 Ó tún sọ Tófétì+ tó wà ní Àfonífojì Àwọn Ọmọ Hínómù*+ di ibi tí kò ṣeé lò fún ìjọsìn, kí ẹnikẹ́ni má bàa sun ọmọkùnrin rẹ̀ tàbí ọmọbìnrin rẹ̀ nínú iná sí Mólékì.+ 11 Kò fàyè gba àwọn ẹṣin tí àwọn ọba Júdà yà sọ́tọ̀ fún oòrùn láti máa gba yàrá* Natani-mélékì òṣìṣẹ́ ààfin wọnú ilé Jèhófà, yàrá náà wà níbi àwọn ọ̀nà olórùlé; ó sì dáná sun àwọn kẹ̀kẹ́ ẹṣin oòrùn.+ 12 Ọba tún wó àwọn pẹpẹ tí àwọn ọba Júdà mọ sórí òrùlé+ yàrá òkè Áhásì, títí kan àwọn pẹpẹ tí Mánásè mọ sínú àgbàlá méjì ní ilé Jèhófà.+ Ó fọ́ wọn túútúú, ó sì fọ́n eruku wọn sí Àfonífojì Kídírónì. 13 Ọba sọ àwọn ibi gíga tó wà níwájú Jerúsálẹ́mù di ibi tí kò ṣeé lò fún ìjọsìn, èyí tó wà ní gúúsù* Òkè Ìparun,* tí Sólómọ́nì ọba Ísírẹ́lì mọ fún Áṣítórétì abo ọlọ́run ìríra àwọn ọmọ Sídónì; fún Kémóṣì ọlọ́run ìríra Móábù àti fún Mílíkómù+ ọlọ́run ẹ̀gbin àwọn ọmọ Ámónì.+ 14 Ó fọ́ àwọn ọwọ̀n òrìṣà, ó gé àwọn òpó òrìṣà*+ lulẹ̀, ó sì kó egungun àwọn èèyàn sí àyè wọn. 15 Ó tún wó pẹpẹ tó wà ní Bẹ́tẹ́lì, ìyẹn ibi gíga tí Jèróbóámù ọmọ Nébátì kọ́, tó mú kí Ísírẹ́lì ṣẹ̀.+ Lẹ́yìn tó wó pẹpẹ yẹn àti ibi gíga náà, ó dáná sun ibi gíga náà, ó lọ̀ ọ́ kúnná, ó sì sun òpó òrìṣà*+ náà.

16 Nígbà tí Jòsáyà yíjú pa dà, tó sì rí àwọn sàréè tó wà lórí òkè, ó ní kí wọ́n kó àwọn egungun kúrò nínú àwọn sàréè náà, kí wọ́n sì sun wọ́n lórí pẹpẹ náà, kí ó lè sọ ọ́ di ibi tí kò ṣeé lò fún ìjọsìn, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Jèhófà tí èèyàn Ọlọ́run tòótọ́ kéde, nígbà tó sọ tẹ́lẹ̀ pé àwọn nǹkan yìí máa ṣẹlẹ̀.+ 17 Lẹ́yìn náà, ó sọ pé: “Èwo ni òkúta sàréè tí mò ń wò níbẹ̀ yẹn?” Àwọn èèyàn ìlú náà bá sọ fún un pé: “Sàréè èèyàn Ọlọ́run tòótọ́ tó wá láti Júdà+ ni, ẹni tó sọ àsọtẹ́lẹ̀ àwọn ohun tí o ṣe sí pẹpẹ tó wà ní Bẹ́tẹ́lì.” 18 Nítorí náà, ó sọ pé: “Kí ẹnikẹ́ni má fọwọ́ kan egungun rẹ̀, ẹ fi sílẹ̀ bó ṣe wà.” Torí náà, wọn ò fọwọ́ kan egungun rẹ̀, bẹ́ẹ̀ sì ni wọ́n ò fọwọ́ kan egungun wòlíì tó wá láti Samáríà.+

19 Jòsáyà tún mú gbogbo àwọn ilé ìjọsìn tó wà lórí àwọn ibi gíga kúrò ní àwọn ìlú Samáríà,+ èyí tí àwọn ọba Ísírẹ́lì kọ́ láti mú Ọlọ́run bínú, ohun tó ṣe ní Bẹ́tẹ́lì ló ṣe sí àwọn náà.+ 20 Torí náà, ó fi gbogbo àlùfáà àwọn ibi gíga tó wà níbẹ̀ rúbọ lórí àwọn pẹpẹ náà, ó sì sun egungun àwọn èèyàn lórí wọn.+ Lẹ́yìn náà, ó pa dà sí Jerúsálẹ́mù.

21 Ọba wá pàṣẹ fún gbogbo àwọn èèyàn náà pé: “Ẹ ṣe Ìrékọjá+ sí Jèhófà Ọlọ́run yín gẹ́gẹ́ bó ṣe wà lákọsílẹ̀ nínú ìwé májẹ̀mú yìí.”+ 22 Kò sí Ìrékọjá tí wọ́n ṣe tó dà bí èyí láti ìgbà tí àwọn onídàájọ́ ti ń ṣe ìdájọ́ Ísírẹ́lì tàbí ní gbogbo ìgbà tí àwọn ọba Ísírẹ́lì àti àwọn ọba Júdà ti ń jọba.+ 23 Àmọ́ ní ọdún kejìdínlógún Ọba Jòsáyà, wọ́n ṣe Ìrékọjá yìí fún Jèhófà ní Jerúsálẹ́mù.

24 Jòsáyà tún gbá àwọn abẹ́mìílò dà nù àti àwọn woṣẹ́woṣẹ́,+ àwọn ère tẹ́ráfímù,*+ àwọn òrìṣà ẹ̀gbin* pẹ̀lú gbogbo ohun ìríra tó fara hàn ní ilẹ̀ Júdà àti ní Jerúsálẹ́mù, kí ó lè mú àwọn ọ̀rọ̀ Òfin+ tó wà lákọsílẹ̀ nínú ìwé tí àlùfáà Hilikáyà rí ní ilé Jèhófà ṣẹ.+ 25 Ṣáájú rẹ̀, kò sí ọba kankan tó dà bíi rẹ̀, tó fi gbogbo ọkàn rẹ̀, gbogbo ara*+ rẹ̀ àti gbogbo okun rẹ̀ pa dà sọ́dọ̀ Jèhófà, bí gbogbo Òfin Mósè ṣe sọ; bẹ́ẹ̀ ni kò sí ẹni tó jọba lẹ́yìn rẹ̀ tó dà bíi rẹ̀.

26 Síbẹ̀, Jèhófà kò dẹwọ́ ìbínú rẹ̀ tó ń jó bí iná lórí Júdà nítorí gbogbo ohun búburú tí Mánásè ti ṣe láti mú un bínú.+ 27 Jèhófà sọ pé: “Màá mú Júdà kúrò níwájú mi,+ bí mo ṣe mú Ísírẹ́lì kúrò;+ màá kọ Jerúsálẹ́mù sílẹ̀, ìlú tí mo yàn àti ilé tí mo sọ nípa rẹ̀ pé, ‘Orúkọ mi yóò máa wà níbẹ̀.’”+

28 Ní ti ìyókù ìtàn Jòsáyà, gbogbo ohun tí ó ṣe, ǹjẹ́ kò wà lákọsílẹ̀ nínú ìwé ìtàn ìgbà àwọn ọba Júdà? 29 Nígbà ayé rẹ̀, Fáráò Nẹ́kò ọba Íjíbítì wá bá ọba Ásíríà lẹ́gbẹ̀ẹ́ odò Yúfírétì, Ọba Jòsáyà sì jáde lọ kò ó lójú; àmọ́ nígbà tí Nẹ́kò rí i, ó pa á ní Mẹ́gídò.+ 30 Nítorí náà, àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ fi kẹ̀kẹ́ ẹṣin gbé òkú rẹ̀ láti Mẹ́gídò wá sí Jerúsálẹ́mù, wọ́n sì sin ín sí sàréè rẹ̀. Lẹ́yìn náà, àwọn èèyàn ilẹ̀ náà mú Jèhóáhásì ọmọ Jòsáyà, wọ́n fòróró yàn án, wọ́n sì fi í jọba ní ipò bàbá rẹ̀.+

31 Ẹni ọdún mẹ́tàlélógún (23) ni Jèhóáhásì+ nígbà tó jọba, oṣù mẹ́ta ló sì fi ṣàkóso ní Jerúsálẹ́mù. Orúkọ ìyá rẹ̀ ni Hámútálì+ ọmọ Jeremáyà láti Líbínà. 32 Ó bẹ̀rẹ̀ sí í ṣe ohun tó burú ní ojú Jèhófà, gbogbo ohun tí àwọn baba ńlá rẹ̀ ṣe ni òun náà ṣe.+ 33 Fáráò Nẹ́kò+ fi í sínú ẹ̀wọ̀n ní Ríbúlà+ nílẹ̀ Hámátì, kó má bàa jọba lórí Jerúsálẹ́mù mọ́, ó wá bu owó ìtanràn lé ilẹ̀ náà, ọgọ́rùn-ún (100) tálẹ́ńtì* fàdákà àti tálẹ́ńtì wúrà kan.+ 34 Yàtọ̀ síyẹn, Fáráò Nẹ́kò fi Élíákímù ọmọ Jòsáyà jọba ní ipò Jòsáyà bàbá rẹ̀, ó sì yí orúkọ rẹ̀ pa dà sí Jèhóákímù; àmọ́ ó mú Jèhóáhásì wá sí Íjíbítì,+ ibẹ̀ ló sì kú sí nígbẹ̀yìn.+ 35 Jèhóákímù fún Fáráò ní fàdákà àti wúrà náà, àmọ́ ṣe ló bu owó orí lé ilẹ̀ náà, kó lè fún Fáráò ní fàdákà tó béèrè. Ó gba iye fàdákà àti wúrà tí ọ̀kọ̀ọ̀kan àwọn èèyàn ilẹ̀ náà máa san, kó lè fún Fáráò Nẹ́kò.

36 Ẹni ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n (25) ni Jèhóákímù+ nígbà tó jọba, ọdún mọ́kànlá (11) ló sì fi ṣàkóso ní Jerúsálẹ́mù.+ Orúkọ ìyá rẹ̀ ni Sébídà ọmọ Pedáyà láti Rúmà. 37 Ó ń ṣe ohun tó burú ní ojú Jèhófà,+ gbogbo ohun tí àwọn bàbá ńlá rẹ̀ ṣe ni òun náà ṣe.+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́