Hósíà
8 “Fi ìwo sí ẹnu rẹ!+
2 Wọ́n ké pè mí, wọ́n ní ‘Ọlọ́run wa, àwa Ísírẹ́lì ti mọ̀ ọ́!’+
3 Ísírẹ́lì ti kọ ohun rere sílẹ̀.+
Kí ọ̀tá máa lépa rẹ̀.
4 Wọ́n ti fi àwọn ọba jẹ, ṣùgbọ́n kì í ṣe láti ọ̀dọ̀ mi.
Wọ́n ti yan àwọn ìjòyè, ṣùgbọ́n èmi kò fọwọ́ sí i.
5 Mo ti kọ ọmọ màlúù rẹ sílẹ̀, ìwọ Samáríà.+
Mo bínú sí yín gidigidi.+
Ìgbà wo lẹ máa tó jáwọ́ nínú ìwà àìmọ́?
6 Torí láti Ísírẹ́lì ni èyí ti wá.
Ohun tí oníṣẹ́ ọnà ṣe ni, kì í ṣe Ọlọ́run;
Ọmọ màlúù Samáríà yóò di èérún.
Bí èyíkéyìí bá sì so, àwọn àjèjì* yóò gbé e mì.+
8 Ọ̀tá ló máa gbé Ísírẹ́lì mì.+
Wọ́n á wà láàárín àwọn orílẹ̀-èdè,+
Bí ohun èlò tí kò wúlò.
9 Nítorí wọ́n ti lọ sí Ásíríà,+ bíi kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ inú igbó tó dá wà.
Éfúrémù ti lọ gba àwọn aṣẹ́wó láti fi ṣe olólùfẹ́.+
10 Bó tilẹ̀ jẹ́ pé àárín àwọn orílẹ̀-èdè ni wọ́n ti gbà wọ́n,
Màá kó àwọn náà jọ;
Wọ́n á bẹ̀rẹ̀ sí í jìyà+ nítorí ẹrù tí ọba àti àwọn ìjòyè dì lé wọn.
11 Torí Éfúrémù ti mọ pẹpẹ púpọ̀ kó lè máa dẹ́ṣẹ̀.+
Àwọn pẹpẹ náà ló sì fi ń dẹ́ṣẹ̀.+
13 Wọ́n ń fi ẹran rúbọ sí mi, wọ́n sì jẹ ẹran náà,
Ṣùgbọ́n inú Jèhófà kò dùn sí ẹbọ wọn.+
Ó máa rántí ẹ̀ṣẹ̀ wọn, á sì fìyà jẹ wọ́n nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn.+
Àmọ́ màá sọ iná sí àwọn ìlú rẹ̀,
Á sì jó àwọn ilé gogoro ìlú kọ̀ọ̀kan run.”+