ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Jeremáyà 40
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

Ohun Tó Wà Nínú Ìwé Jeremáyà

      • Nebusarádánì jẹ́ kí Jeremáyà lọ ní òmìnira (1-6)

      • A yan Gẹdaláyà ṣe olórí ilẹ̀ náà (7-12)

      • Wọ́n dìtẹ̀ Gẹdaláyà (13-16)

Jeremáyà 40:1

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 39:9; 52:12, 13
  • +Joṣ 18:21, 25

Jeremáyà 40:3

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 50:7

Jeremáyà 40:4

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 39:11, 12

Jeremáyà 40:5

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 25:22; Jer 39:13, 14; 41:2
  • +2Ọb 22:12, 13; Jer 26:24
  • +2Ọb 22:8

Jeremáyà 40:6

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ond 20:1; 1Ọb 15:22

Jeremáyà 40:7

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 25:22; Jer 39:10

Jeremáyà 40:8

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 25:23
  • +2Ọb 25:25
  • +Jer 41:11, 16; 43:2
  • +Jer 42:1, 2

Jeremáyà 40:9

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 25:24; Jer 27:11

Jeremáyà 40:10

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “láti dúró níwájú.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 39:10

Jeremáyà 40:14

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “láti pa ọkàn rẹ?”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 41:10
  • +Jer 41:2

Jeremáyà 40:15

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “pa ọkàn rẹ.”

Jeremáyà 40:16

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 25:22

Àwọn míì

Jer. 40:1Jer 39:9; 52:12, 13
Jer. 40:1Joṣ 18:21, 25
Jer. 40:3Jer 50:7
Jer. 40:4Jer 39:11, 12
Jer. 40:52Ọb 25:22; Jer 39:13, 14; 41:2
Jer. 40:52Ọb 22:12, 13; Jer 26:24
Jer. 40:52Ọb 22:8
Jer. 40:6Ond 20:1; 1Ọb 15:22
Jer. 40:72Ọb 25:22; Jer 39:10
Jer. 40:82Ọb 25:23
Jer. 40:82Ọb 25:25
Jer. 40:8Jer 41:11, 16; 43:2
Jer. 40:8Jer 42:1, 2
Jer. 40:92Ọb 25:24; Jer 27:11
Jer. 40:10Jer 39:10
Jer. 40:14Jer 41:10
Jer. 40:14Jer 41:2
Jer. 40:162Ọb 25:22
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
  • 1
  • 2
  • 3
  • 4
  • 5
  • 6
  • 7
  • 8
  • 9
  • 10
  • 11
  • 12
  • 13
  • 14
  • 15
  • 16
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
Jeremáyà 40:1-16

Jeremáyà

40 Ọ̀rọ̀ tí Jèhófà bá Jeremáyà sọ lẹ́yìn tí Nebusarádánì+ olórí ẹ̀ṣọ́ jẹ́ kó lọ ní òmìnira láti Rámà.+ Ṣẹkẹ́ṣẹkẹ̀ wà lọ́wọ́ rẹ̀ nígbà tó mú un dé ibẹ̀, ó sì wà pẹ̀lú gbogbo àwọn tí wọ́n kó nígbèkùn láti Jerúsálẹ́mù àti Júdà, ìyẹn àwọn tí wọ́n ń kó lọ sí Bábílónì. 2 Ìgbà náà ni olórí ẹ̀ṣọ́ mú Jeremáyà, ó sì sọ fún un pé: “Jèhófà Ọlọ́run rẹ ló sọ pé àjálù yìí máa bá ibí yìí, 3 Jèhófà sì ti mú kó ṣẹlẹ̀ bó ṣe sọ, nítorí pé ẹ̀yin èèyàn yìí ti ṣẹ Jèhófà, ẹ kò sì ṣègbọràn sí ohùn rẹ̀. Ìdí nìyẹn tí èyí fi ṣẹlẹ̀ sí yín.+ 4 Ní báyìí, màá tú ṣẹkẹ́ṣẹkẹ̀ tó wà ní ọwọ́ rẹ kúrò lónìí. Tí o bá fẹ́ bá mi lọ sí Bábílónì, jẹ́ ká lọ, màá sì tọ́jú rẹ. Ṣùgbọ́n bí o kò bá fẹ́ tẹ̀ lé mi lọ sí Bábílónì, dúró ẹ. Wò ó! Gbogbo ilẹ̀ náà pátá wà níwájú rẹ. Ibikíbi tí o bá fẹ́ ni kí o lọ.”+

5 Kí Jeremáyà tó pẹ̀yìn dà, Nebusarádánì sọ pé: “Pa dà sọ́dọ̀ Gẹdaláyà+ ọmọ Áhíkámù+ ọmọ Ṣáfánì,+ ẹni tí ọba Bábílónì yàn ṣe olórí àwọn ìlú Júdà, sì máa gbé pẹ̀lú rẹ̀ ní àárín àwọn èèyàn náà tàbí kí o lọ sí ibikíbi tí o bá fẹ́.”

Olórí ẹ̀ṣọ́ wá fún un ní oúnjẹ díẹ̀ àti ẹ̀bùn, ó sì jẹ́ kó máa lọ. 6 Torí náà, Jeremáyà lọ sọ́dọ̀ Gẹdaláyà ọmọ Áhíkámù ní Mísípà,+ ó sì ń gbé lọ́dọ̀ rẹ̀ ní àárín àwọn èèyàn tó ṣẹ́ kù ní ilẹ̀ náà.

7 Nígbà tó yá, gbogbo olórí àwọn ọmọ ogun tó wà ní pápá pẹ̀lú àwọn ọkùnrin wọn gbọ́ pé ọba Bábílónì ti yan Gẹdaláyà ọmọ Áhíkámù ṣe olórí ilẹ̀ náà àti pé ó ti yàn án sórí àwọn ọkùnrin àti àwọn obìnrin àti àwọn ọmọ kéékèèké tí wọ́n jẹ́ aláìní, tó ṣẹ́ kù sí ilẹ̀ náà, tí wọn ò kó lọ sí Bábílónì.+ 8 Nítorí náà, wọ́n wá sọ́dọ̀ Gẹdaláyà ní Mísípà.+ Àwọn ni Íṣímáẹ́lì+ ọmọ Netanáyà, Jóhánánì+ àti Jónátánì, àwọn ọmọ Káréà, Seráyà ọmọ Táńhúmétì, àwọn ọmọ Éfáì ará Nétófà àti Jesanáyà+ ọmọ ará Máákátì, pẹ̀lú àwọn ọkùnrin wọn. 9 Gẹdaláyà ọmọ Áhíkámù ọmọ Ṣáfánì sì búra fún wọn àti fún àwọn ọkùnrin wọn pé: “Ẹ má bẹ̀rù láti sin àwọn ará Kálídíà. Ẹ máa gbé ní ilẹ̀ yìí, kí ẹ máa sin ọba Bábílónì, nǹkan á sì máa lọ dáadáa fún yín.+ 10 Ní tèmi, màá dúró ní Mísípà láti ṣojú yín lọ́dọ̀* àwọn ará Kálídíà tó ń wá sọ́dọ̀ wa. Àmọ́, ẹ kó wáìnì jọ àti èso ìgbà ẹ̀ẹ̀rùn àti òróró, ẹ kó wọn sínú àwọn ohun tí ẹ̀ ń kó nǹkan sí, kí ẹ sì máa gbé nínú àwọn ìlú tí ẹ gbà.”+

11 Gbogbo àwọn Júù tó wà ní Móábù, ní Ámónì àti ní Édómù títí kan àwọn tó wà ní gbogbo àwọn ilẹ̀ yòókù náà gbọ́ pé ọba Bábílónì ti fi àwọn kan sílẹ̀ kí wọ́n máa gbé ní Júdà àti pé ó ti yan Gẹdaláyà ọmọ Áhíkámù ọmọ Ṣáfánì ṣe olórí wọn. 12 Torí náà gbogbo àwọn Júù bẹ̀rẹ̀ sí í pa dà wá láti gbogbo ibi tí wọ́n fọ́n wọn ká sí, wọ́n sì wá sí ilẹ̀ Júdà, sọ́dọ̀ Gẹdaláyà ní Mísípà. Wọ́n sì kó wáìnì àti èso ìgbà ẹ̀ẹ̀rùn jọ lọ́pọ̀lọpọ̀.

13 Jóhánánì ọmọ Káréà àti gbogbo olórí àwọn ọmọ ogun tó wà ní pápá wá sọ́dọ̀ Gẹdaláyà ní Mísípà. 14 Wọ́n sọ fún un pé: “Ṣé o kò mọ̀ pé Báálísì, ọba àwọn ọmọ Ámónì,+ ti rán Íṣímáẹ́lì ọmọ Netanáyà láti wá pa ọ́?”*+ Ṣùgbọ́n Gẹdaláyà ọmọ Áhíkámù kò gbà wọ́n gbọ́.

15 Ìgbà náà ni Jóhánánì ọmọ Káréà yọ́ ọ̀rọ̀ sọ fún Gẹdaláyà ní Mísípà pé: “Mo fẹ́ lọ pa Íṣímáẹ́lì ọmọ Netanáyà, ẹnikẹ́ni kò sì ní mọ̀. Kí ló dé tó fi máa pa ọ́,* tí gbogbo àwọn èèyàn Júdà tí wọ́n kóra jọ sọ́dọ̀ rẹ á fi tú ká, tí àwọn tó ṣẹ́ kù ní Júdà á sì pa run?” 16 Ṣùgbọ́n Gẹdaláyà+ ọmọ Áhíkámù sọ fún Jóhánánì ọmọ Káréà pé: “Má ṣe bẹ́ẹ̀, nítorí ohun tí ò ń sọ nípa Íṣímáẹ́lì kì í ṣe òótọ́.”

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́