Kíróníkà Kìíní
9 Orúkọ gbogbo àwọn ọmọ Ísírẹ́lì wà nínú àkọsílẹ̀ ìdílé wọn, a sì kọ wọ́n sínú Ìwé Àwọn Ọba Ísírẹ́lì. Àwọn ọmọ Júdà ni a sì kó lọ sí ìgbèkùn ní Bábílónì nítorí ìwà àìṣòótọ́+ wọn. 2 Àwọn tó kọ́kọ́ pa dà sídìí ohun ìní wọn, ní àwọn ìlú wọn, ni àwọn kan lára àwọn ọmọ Ísírẹ́lì, àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Léfì àti àwọn ìránṣẹ́ tẹ́ńpìlì.*+ 3 Lára àwọn ọmọ Júdà+ àti lára àwọn ọmọ Bẹ́ńjámínì+ àti lára àwọn ọmọ Éfúrémù pẹ̀lú àwọn kan lára àwọn ọmọ Mánásè ń gbé Jerúsálẹ́mù, àwọn ni: 4 Útáì ọmọ Ámíhúdù ọmọ Ómírì ọmọ Ímúrì ọmọ Bánì, tó jẹ́ àtọmọdọ́mọ Pérésì+ ọmọ Júdà. 5 Látinú àwọn ọmọ Ṣílò, Ásáyà àkọ́bí àti àwọn ọmọ rẹ̀. 6 Látinú àwọn ọmọ Síírà,+ Júẹ́lì àti ọgọ́rùn-ún méje ó dín mẹ́wàá (690) lára àwọn arákùnrin wọn.
7 Látinú àwọn ọmọ Bẹ́ńjámínì, Sáálù ọmọ Méṣúlámù ọmọ Hodafáyà ọmọ Hásénúà, 8 Ibineáyà ọmọ Jéróhámù, Élà ọmọ Úsáì ọmọ Míkírì àti Méṣúlámù ọmọ Ṣẹfatáyà ọmọ Réúẹ́lì ọmọ Ibiníjà. 9 Àwọn arákùnrin wọn láti ìran wọn jẹ́ ọgọ́rùn-ún mẹ́sàn-án ó lé àádọ́ta àti mẹ́fà (956). Gbogbo wọn jẹ́ olórí ní agbo ilé bàbá wọn.*
10 Látinú àwọn àlùfáà, Jedáyà, Jèhóáríbù, Jákínì,+ 11 Asaráyà ọmọ Hilikáyà ọmọ Méṣúlámù ọmọ Sádókù ọmọ Méráótì ọmọ Áhítúbù, aṣáájú ní ilé* Ọlọ́run tòótọ́, 12 Ádáyà ọmọ Jéróhámù ọmọ Páṣúrì ọmọ Málíkíjà, Máásáì ọmọ Ádíélì ọmọ Jásérà ọmọ Méṣúlámù ọmọ Méṣílẹ́mítì ọmọ Ímérì 13 àti àwọn arákùnrin wọn, àwọn ni olórí agbo ilé bàbá wọn, ẹgbẹ̀rún kan ó lé ọgọ́rùn-ún méje àti ọgọ́ta (1,760) ọkùnrin tó dáńgájíá tí wọ́n wà fún iṣẹ́ ilé Ọlọ́run tòótọ́.
14 Látinú àwọn ọmọ Léfì, Ṣemáyà+ ọmọ Háṣúbù ọmọ Ásíríkámù ọmọ Haṣabáyà látinú àwọn àtọmọdọ́mọ Mérárì 15 àti Bakibákárì, Héréṣì, Gálálì, Matanáyà ọmọ Máíkà ọmọ Síkírì ọmọ Ásáfù, 16 Ọbadáyà ọmọ Ṣemáyà ọmọ Gálálì ọmọ Jédútúnì àti Berekáyà ọmọ Ásà ọmọ Ẹlikénà, ẹni tó ń gbé ní ibi tí àwọn ará Nétófà+ tẹ̀ dó sí.
17 Àwọn aṣọ́bodè+ ni Ṣálúmù, Ákúbù, Tálímónì, Áhímánì àti Ṣálúmù arákùnrin wọn tó jẹ́ olórí, 18 títí di ìgbà náà, ẹnubodè ọba lápá ìlà oòrùn+ ni ó wà. Àwọn ni aṣọ́bodè ibùdó àwọn ọmọ Léfì. 19 Ṣálúmù ọmọ Kórè ọmọ Ébíásáfù ọmọ Kórà àti àwọn arákùnrin rẹ̀ láti agbo ilé bàbá rẹ̀, ìyẹn àwọn ọmọ Kórà, ló ń bójú tó iṣẹ́ náà, àwọn aṣọ́nà àgọ́, àwọn bàbá wọn ló sì ń bójú tó ibùdó Jèhófà torí àwọn ló ń ṣọ́ ọ̀nà àbáwọlé. 20 Fíníhásì+ ọmọ Élíásárì+ ni aṣáájú wọn tẹ́lẹ̀; Jèhófà sì wà pẹ̀lú rẹ̀. 21 Sekaráyà+ ọmọ Meṣelemáyà ni aṣọ́bodè ẹnu ọ̀nà àgọ́ ìpàdé.
22 Gbogbo àwọn tí wọ́n yàn ṣe aṣọ́bodè ní àwọn ibi àbáwọlé jẹ́ igba ó lé méjìlá (212). Wọ́n wà ní ibi tí wọ́n tẹ̀ dó sí bí orúkọ wọn ṣe wà nínú àkọsílẹ̀ ìdílé wọn.+ Dáfídì àti Sámúẹ́lì aríran+ ló yàn wọ́n sí ipò ẹni tó ṣeé fọkàn tán tí wọ́n wà. 23 Àwọn àti àwọn ọmọ wọn ló ń ṣọ́ àwọn ẹnubodè ilé Jèhófà,+ ìyẹn ilé àgọ́. 24 Àwọn aṣọ́bodè wà ní ẹ̀gbẹ́ mẹ́rẹ̀ẹ̀rin, ìyẹn ní ìlà oòrùn, ìwọ̀ oòrùn, àríwá àti gúúsù.+ 25 Látìgbàdégbà, àwọn arákùnrin wọn máa ń wá láti àwọn ibi tí wọ́n tẹ̀ dó sí láti bá wọn ṣiṣẹ́ fún ọjọ́ méje. 26 Àwọn olórí* aṣọ́bodè mẹ́rin ló wà ní ipò ẹni tó ṣeé fọkàn tán. Ọmọ Léfì ni wọ́n, àwọn ló sì ń bójú tó àwọn yàrá* àti àwọn ibi ìṣúra tó wà nínú ilé Ọlọ́run tòótọ́.+ 27 Wọ́n máa ń wà níbi tí wọ́n ti ń ṣiṣẹ́ káàkiri ilé Ọlọ́run tòótọ́ láti òru mọ́jú, nítorí àwọn ló ń ṣe iṣẹ́ olùṣọ́, ọwọ́ wọn ni kọ́kọ́rọ́ máa ń wà, àwọn ló sì ń ṣí ilé náà láràárọ̀.
28 Àwọn kan lára wọn ń bójú tó àwọn ohun èlò+ tó wà fún ìjọsìn; wọ́n máa ń kà wọ́n tí wọ́n bá ń kó wọn wọlé àti nígbà tí wọ́n bá ń kó wọn jáde. 29 Wọ́n yan àwọn kan lára wọn láti máa bójú tó àwọn ohun èlò, gbogbo àwọn ohun èlò mímọ́,+ ìyẹ̀fun kíkúnná,+ wáìnì,+ òróró,+ oje igi tùràrí+ àti òróró básámù.+ 30 Àwọn kan lára àwọn ọmọ àlùfáà máa ń po ìpara tí ó ní òróró básámù. 31 Matitáyà tó wá látinú àwọn ọmọ Léfì, òun ni àkọ́bí Ṣálúmù ọmọ Kórà, òun ló wà ní ipò ẹni tó ṣeé fọkàn tán tó ń bójú tó yíyan àwọn nǹkan nínú páànù.+ 32 Àwọn kan lára àwọn arákùnrin àwọn ọmọ Kóhátì ló ń bójú tó búrẹ́dì onípele,*+ láti ṣe é sílẹ̀ ní sábáàtì+ kọ̀ọ̀kan.
33 Àwọn yìí ni àwọn akọrin, àwọn olórí agbo ilé àwọn ọmọ Léfì nínú àwọn yàrá,* àwọn tí a kò yan iṣẹ́ míì fún; nítorí pé ojúṣe wọn ni láti máa wà lẹ́nu iṣẹ́ tọ̀sántòru. 34 Àwọn ni olórí agbo ilé àwọn ọmọ Léfì ní ìran wọn, wọ́n jẹ́ aṣáájú. Jerúsálẹ́mù ni wọ́n sì ń gbé.
35 Jéélì gbé ní Gíbíónì,+ òun ló sì tẹ ìlú náà dó. Orúkọ ìyàwó rẹ̀ ni Máákà. 36 Àkọ́bí rẹ̀ ọkùnrin ni Ábídónì, àwọn tó tẹ̀ lé e ni Súúrì, Kíṣì, Báálì, Nérì, Nádábù, 37 Gédórì, Áhíò, Sekaráyà àti Míkílótì. 38 Míkílótì bí Ṣíméámù. Gbogbo wọn gbé nítòsí àwọn arákùnrin wọn ní Jerúsálẹ́mù pẹ̀lú àwọn arákùnrin wọn míì. 39 Nérì+ bí Kíṣì; Kíṣì bí Sọ́ọ̀lù;+ Sọ́ọ̀lù bí Jónátánì,+ Maliki-ṣúà,+ Ábínádábù+ àti Eṣibáálì. 40 Ọmọ Jónátánì ni Meribu-báálì.+ Meribu-báálì bí Míkà.+ 41 Àwọn ọmọ Míkà ni Pítónì, Mélékì, Tááréà àti Áhásì. 42 Áhásì bí Járà; Járà bí Álémétì, Ásímáfẹ́tì àti Símírì. Símírì bí Mósà. 43 Mósà bí Bínéà àti Refáyà, ọmọ* rẹ̀ ni Éléásà, ọmọ rẹ̀ sì ni Ásélì. 44 Ásélì ní ọmọkùnrin mẹ́fà, orúkọ wọn ni Ásíríkámù, Bókérù, Íṣímáẹ́lì, Ṣearáyà, Ọbadáyà àti Hánánì. Gbogbo wọn ni ọmọ Ásélì.