ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Ẹ́kísódù 33
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

Ohun Tó Wà Nínú Ìwé Ẹ́kísódù

      • Ọlọ́run bá àwọn ọmọ Ísírẹ́lì wí (1-6)

      • Àgọ́ ìpàdé ní ẹ̀yìn ibùdó (7-11)

      • Mósè fẹ́ rí ògo Jèhófà (12-23)

Ẹ́kísódù 33:1

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “èso.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jẹ 12:7; 26:3

Ẹ́kísódù 33:2

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 23:20; 32:34
  • +Di 7:1, 22; Joṣ 24:11

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Àsọtẹ́lẹ̀ Dáníẹ́lì, ojú ìwé 204-205

Ẹ́kísódù 33:3

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “ọlọ́rùn líle.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 3:8; Di 8:7-9
  • +Ẹk 32:9; Di 9:6; Iṣe 7:51
  • +Ẹk 32:10; Nọ 16:21

Ẹ́kísódù 33:5

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “Ọlọ́rùn líle.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 34:9; Di 9:6; Iṣe 7:51
  • +Nọ 16:45

Ẹ́kísódù 33:6

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “ti wá bọ́.”

Ẹ́kísódù 33:7

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 18:25, 26; Nọ 27:1-5

Ẹ́kísódù 33:9

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “àwọsánmà tó rí bí òpó.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 13:21; Sm 99:7
  • +Nọ 11:16, 17; 12:5

Ẹ́kísódù 33:11

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 33:22, 23; Nọ 12:8; Di 34:10; Jo 1:18; 6:46; Iṣe 7:38
  • +Nọ 11:28; Di 1:38; Joṣ 1:1
  • +Ẹk 17:9; 24:13

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    3/15/2004, ojú ìwé 27

    12/1/2002, ojú ìwé 10-11

    10/1/1997, ojú ìwé 4-5

Ẹ́kísódù 33:12

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “Mo mọ̀ ọ́ lójúkojú.”

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Àwọn Ìtẹ̀jáde Tá A Tọ́ka sí Nínú Ìwé Ìpàdé, 10/2020, ojú ìwé 2

Ẹ́kísódù 33:13

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 25:4; 27:11; 86:11; 119:33; Ais 30:21
  • +Di 9:26

Ẹ́kísódù 33:14

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “Ojú mi.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 13:21; 40:34; Joṣ 1:5, 17; Ais 63:9
  • +Joṣ 21:44; 23:1

Ẹ́kísódù 33:15

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “Tí ojú rẹ.”

Ẹ́kísódù 33:16

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 14:13, 14
  • +Di 4:34; 2Sa 7:23; Sm 147:20

Ẹ́kísódù 33:19

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 3:13; 6:3; 34:6
  • +Ro 9:15

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́ (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́),

    3/2019, ojú ìwé 26

Ẹ́kísódù 33:20

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Sún Mọ́ Jèhófà, ojú ìwé 12-13

    Ilé Ìṣọ́,

    6/15/1999, ojú ìwé 19-20

Ẹ́kísódù 33:23

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jo 1:18

Àwọn míì

Ẹ́kís. 33:1Jẹ 12:7; 26:3
Ẹ́kís. 33:2Ẹk 23:20; 32:34
Ẹ́kís. 33:2Di 7:1, 22; Joṣ 24:11
Ẹ́kís. 33:3Ẹk 3:8; Di 8:7-9
Ẹ́kís. 33:3Ẹk 32:9; Di 9:6; Iṣe 7:51
Ẹ́kís. 33:3Ẹk 32:10; Nọ 16:21
Ẹ́kís. 33:5Ẹk 34:9; Di 9:6; Iṣe 7:51
Ẹ́kís. 33:5Nọ 16:45
Ẹ́kís. 33:7Ẹk 18:25, 26; Nọ 27:1-5
Ẹ́kís. 33:9Ẹk 13:21; Sm 99:7
Ẹ́kís. 33:9Nọ 11:16, 17; 12:5
Ẹ́kís. 33:11Ẹk 33:22, 23; Nọ 12:8; Di 34:10; Jo 1:18; 6:46; Iṣe 7:38
Ẹ́kís. 33:11Nọ 11:28; Di 1:38; Joṣ 1:1
Ẹ́kís. 33:11Ẹk 17:9; 24:13
Ẹ́kís. 33:13Sm 25:4; 27:11; 86:11; 119:33; Ais 30:21
Ẹ́kís. 33:13Di 9:26
Ẹ́kís. 33:14Ẹk 13:21; 40:34; Joṣ 1:5, 17; Ais 63:9
Ẹ́kís. 33:14Joṣ 21:44; 23:1
Ẹ́kís. 33:16Nọ 14:13, 14
Ẹ́kís. 33:16Di 4:34; 2Sa 7:23; Sm 147:20
Ẹ́kís. 33:19Ẹk 3:13; 6:3; 34:6
Ẹ́kís. 33:19Ro 9:15
Ẹ́kís. 33:23Jo 1:18
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
  • 1
  • 2
  • 3
  • 4
  • 5
  • 6
  • 7
  • 8
  • 9
  • 10
  • 11
  • 12
  • 13
  • 14
  • 15
  • 16
  • 17
  • 18
  • 19
  • 20
  • 21
  • 22
  • 23
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
Ẹ́kísódù 33:1-23

Ẹ́kísódù

33 Jèhófà ń bá ọ̀rọ̀ tó ń sọ fún Mósè lọ pé: “Kúrò níbí pẹ̀lú àwọn èèyàn tí o mú kúrò ní ilẹ̀ Íjíbítì. Kí ẹ lọ sí ilẹ̀ tí mo búra nípa rẹ̀ fún Ábúráhámù, Ísákì àti Jékọ́bù pé, ‘Ìwọ àti àtọmọdọ́mọ* rẹ ni màá fún.’+ 2 Màá rán áńgẹ́lì kan ṣáájú yín,+ màá sì lé àwọn ọmọ Kénáánì kúrò, pẹ̀lú àwọn Ámórì, àwọn ọmọ Hétì, àwọn Pérísì, àwọn Hífì àti àwọn ará Jébúsì.+ 3 Ẹ máa lọ sí ilẹ̀ tí wàrà àti oyin ti ń ṣàn.+ Àmọ́ mi ò ní bá yín lọ, torí alágídí* ni yín,+ mo sì lè pa yín run lójú ọ̀nà.”+

4 Nígbà tí àwọn èèyàn náà gbọ́ ọ̀rọ̀ líle yìí, wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí í ṣọ̀fọ̀, ìkankan nínú wọn ò sì lo ohun ọ̀ṣọ́ rẹ̀. 5 Jèhófà sọ fún Mósè pé: “Sọ fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì pé, ‘Alágídí* ni yín.+ Ní ìṣẹ́jú kan, mo lè la àárín yín kọjá, kí n sì pa yín run.+ Torí náà, ẹ yọ àwọn ohun ọ̀ṣọ́ yín kúrò títí màá fi mọ ohun tí màá ṣe sí yín.’” 6 Láti Òkè Hórébù lọ ni àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ò ti lo* ohun ọ̀ṣọ́ wọn.

7 Mósè wá ká àgọ́ rẹ̀, ó sì lọ pa àgọ́ náà sí ẹ̀yìn ibùdó níbi tó jìnnà sí àwọn yòókù, ó sì pè é ní àgọ́ ìpàdé. Gbogbo ẹni tó bá fẹ́ wádìí ọ̀rọ̀ lọ́dọ̀ Jèhófà+ yóò jáde lọ sí àgọ́ ìpàdé náà, tó wà ní ẹ̀yìn ibùdó. 8 Gbàrà tí Mósè bá ti ń lọ síbi àgọ́ náà, gbogbo àwọn èèyàn náà á dìde, wọ́n á sì dúró sí ẹnu ọ̀nà àgọ́ wọn, wọ́n á sì máa wo Mósè títí yóò fi wọnú àgọ́. 9 Gbàrà tí Mósè bá ti wọnú àgọ́, ọwọ̀n ìkùukùu*+ máa sọ̀ kalẹ̀, á sì dúró sí ẹnu ọ̀nà àgọ́ nígbà tí Ọlọ́run bá ń bá Mósè sọ̀rọ̀.+ 10 Nígbà tí gbogbo èèyàn rí ọwọ̀n ìkùukùu tó dúró ní ẹnu ọ̀nà àgọ́ náà, kálukú wọn dìde, wọ́n sì tẹrí ba ní ẹnu ọ̀nà àgọ́ wọn. 11 Jèhófà bá Mósè sọ̀rọ̀ ní ojúkojú,+ bí ìgbà téèyàn méjì ń bá ara wọn sọ̀rọ̀. Nígbà tó pa dà sọ́dọ̀ àwọn èèyàn náà, Jóṣúà+ ọmọ Núnì, òjíṣẹ́ rẹ̀ àti ìránṣẹ́ rẹ̀+ ò kúrò níbi àgọ́ náà.

12 Mósè wá sọ fún Jèhófà pé: “Wò ó, ò ń sọ fún mi pé, ‘Darí àwọn èèyàn yìí lọ,’ àmọ́ o ò jẹ́ kí n mọ ẹni tí o máa rán pẹ̀lú mi. O tún sọ pé, ‘Mo fi orúkọ mọ̀ ọ́,* o sì tún rí ojúure mi.’ 13 Jọ̀ọ́, tí mo bá rí ojúure rẹ, jẹ́ kí n mọ àwọn ọ̀nà rẹ,+ kí n lè mọ̀ ọ́, kí n sì túbọ̀ máa rí ojú rere rẹ. Tún ro ti orílẹ̀-èdè yìí, tí wọ́n jẹ́ èèyàn rẹ.”+ 14 Ó sọ pé: “Èmi fúnra mi* yóò bá ọ lọ,+ màá sì fún ọ ní ìsinmi.”+ 15 Mósè wá sọ fún un pé: “Tí ìwọ fúnra rẹ* ò bá ní bá wa lọ, má ṣe mú wa kúrò níbí. 16 Báwo ni àwọn èèyàn yóò ṣe mọ̀ pé èmi àti àwọn èèyàn rẹ ti rí ojúure rẹ? Ṣebí tí o bá bá wa lọ ni,+ kí èmi àti àwọn èèyàn rẹ lè yàtọ̀ sí gbogbo èèyàn yòókù tó wà ní ayé?”+

17 Lẹ́yìn náà, Jèhófà sọ fún Mósè pé: “Màá tún ṣe ohun tí o ní kí n ṣe yìí, torí o ti rí ojúure mi, mo sì fi orúkọ mọ̀ ọ́.” 18 Mósè bá sọ pé: “Jọ̀ọ́, fi ògo rẹ hàn mí.” 19 Àmọ́ Ọlọ́run dáhùn pé: “Màá mú kí gbogbo oore mi kọjá níwájú rẹ, màá sì kéde orúkọ Jèhófà níwájú rẹ;+ èmi yóò ṣojúure sí ẹni tí èmi yóò ṣojúure sí, èmi yóò sì ṣàánú ẹni tí èmi yóò ṣàánú.”+ 20 Àmọ́ ó tún sọ pé: “O ò lè rí ojú mi, torí kò sí èèyàn tó lè rí mi, kó sì wà láàyè.”

21 Jèhófà wá ń bá ọ̀rọ̀ rẹ̀ lọ pé: “Ibì kan nìyí nítòsí mi. Dúró sórí àpáta. 22 Tí ògo mi bá ń kọjá, màá fi ọ́ pa mọ́ sínú ihò àpáta, màá sì fi ọwọ́ mi bò ọ́ títí màá fi kọjá. 23 Lẹ́yìn náà, màá gbé ọwọ́ mi kúrò, ìwọ yóò sì rí ẹ̀yìn mi. Àmọ́ o ò ní rí ojú mi.”+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́