ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Jóṣúà 11
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

Ohun Tó Wà Nínú Ìwé Jóṣúà

      • Wọ́n gba àwọn ìlú tó wà ní àríwá (1-15)

      • Àwọn ilẹ̀ tí Jóṣúà ṣẹ́gun (16-23)

Jóṣúà 11:1

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 12:7, 19
  • +Joṣ 12:7, 20

Jóṣúà 11:2

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “Árábà.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 17:11; Ond 1:27

Jóṣúà 11:3

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 13:29
  • +Jẹ 15:16
  • +Di 7:1; 20:17
  • +Di 4:48

Jóṣúà 11:6

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “já pátì.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 10:8
  • +Di 17:16; Owe 21:31

Jóṣúà 11:8

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 21:44
  • +Jẹ 10:19; Joṣ 19:28, 31
  • +Joṣ 13:1, 6
  • +Di 20:16

Jóṣúà 11:9

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 11:6

Jóṣúà 11:10

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 12:7, 19

Jóṣúà 11:11

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ọkàn.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Le 27:29
  • +Di 20:16; Joṣ 11:14

Jóṣúà 11:12

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 9:5
  • +Di 7:2, 16

Jóṣúà 11:14

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 8:2, 27
  • +Di 7:2
  • +Di 20:16

Jóṣúà 11:15

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 3:28; 7:1; 31:7
  • +Di 4:2, 5

Jóṣúà 11:16

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “òkè kéékèèké rẹ̀.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 13:17; Di 1:7
  • +Joṣ 10:40, 41
  • +Joṣ 12:7, 8

Jóṣúà 11:17

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 13:1, 5
  • +Di 4:48; Joṣ 13:8, 11

Jóṣúà 11:19

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 9:7, 15
  • +Di 20:17

Jóṣúà 11:20

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 2:30
  • +Ẹk 34:12; Di 7:2
  • +Di 20:16

Jóṣúà 11:21

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 13:22; Di 1:28; Joṣ 15:13, 14
  • +Le 27:29; Joṣ 11:12; 24:11

Jóṣúà 11:22

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 23:28-30
  • +Ond 1:18
  • +1Sa 17:4
  • +2Kr 26:1, 6

Jóṣúà 11:23

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 23:27; Di 11:23
  • +Nọ 26:53, 54; Joṣ 14:1
  • +Joṣ 14:15; 21:44; 23:1

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    12/1/2004, ojú ìwé 11-12

Àwọn míì

Jóṣ. 11:1Joṣ 12:7, 19
Jóṣ. 11:1Joṣ 12:7, 20
Jóṣ. 11:2Joṣ 17:11; Ond 1:27
Jóṣ. 11:3Nọ 13:29
Jóṣ. 11:3Jẹ 15:16
Jóṣ. 11:3Di 7:1; 20:17
Jóṣ. 11:3Di 4:48
Jóṣ. 11:6Joṣ 10:8
Jóṣ. 11:6Di 17:16; Owe 21:31
Jóṣ. 11:8Joṣ 21:44
Jóṣ. 11:8Jẹ 10:19; Joṣ 19:28, 31
Jóṣ. 11:8Joṣ 13:1, 6
Jóṣ. 11:8Di 20:16
Jóṣ. 11:9Joṣ 11:6
Jóṣ. 11:10Joṣ 12:7, 19
Jóṣ. 11:11Le 27:29
Jóṣ. 11:11Di 20:16; Joṣ 11:14
Jóṣ. 11:12Di 9:5
Jóṣ. 11:12Di 7:2, 16
Jóṣ. 11:14Joṣ 8:2, 27
Jóṣ. 11:14Di 7:2
Jóṣ. 11:14Di 20:16
Jóṣ. 11:15Di 3:28; 7:1; 31:7
Jóṣ. 11:15Di 4:2, 5
Jóṣ. 11:16Nọ 13:17; Di 1:7
Jóṣ. 11:16Joṣ 10:40, 41
Jóṣ. 11:16Joṣ 12:7, 8
Jóṣ. 11:17Joṣ 13:1, 5
Jóṣ. 11:17Di 4:48; Joṣ 13:8, 11
Jóṣ. 11:19Joṣ 9:7, 15
Jóṣ. 11:19Di 20:17
Jóṣ. 11:20Di 2:30
Jóṣ. 11:20Ẹk 34:12; Di 7:2
Jóṣ. 11:20Di 20:16
Jóṣ. 11:21Nọ 13:22; Di 1:28; Joṣ 15:13, 14
Jóṣ. 11:21Le 27:29; Joṣ 11:12; 24:11
Jóṣ. 11:22Ẹk 23:28-30
Jóṣ. 11:22Ond 1:18
Jóṣ. 11:221Sa 17:4
Jóṣ. 11:222Kr 26:1, 6
Jóṣ. 11:23Ẹk 23:27; Di 11:23
Jóṣ. 11:23Nọ 26:53, 54; Joṣ 14:1
Jóṣ. 11:23Joṣ 14:15; 21:44; 23:1
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
  • 1
  • 2
  • 3
  • 4
  • 5
  • 6
  • 7
  • 8
  • 9
  • 10
  • 11
  • 12
  • 13
  • 14
  • 15
  • 16
  • 17
  • 18
  • 19
  • 20
  • 21
  • 22
  • 23
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
Jóṣúà 11:1-23

Jóṣúà

11 Gbàrà tí Jábínì ọba Hásórì gbọ́ nípa rẹ̀, ó ránṣẹ́ sí Jóbábù ọba Mádónì,+ sí ọba Ṣímúrónì, ọba Ákíṣáfù,+ 2 àwọn ọba agbègbè olókè tó wà ní apá àríwá, àwọn tó wà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀* apá gúúsù Kínérétì, àwọn tó wà ní Ṣẹ́fẹ́là àti ní gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ Dórì+ ní ìwọ̀ oòrùn, 3 àwọn ọmọ Kénáánì+ lápá ìlà oòrùn àti ìwọ̀ oòrùn, àwọn Ámórì,+ àwọn ọmọ Hétì, àwọn Pérísì, àwọn ará Jébúsì ní agbègbè olókè àti àwọn Hífì+ ní ìsàlẹ̀ Hámónì+ ní ilẹ̀ Mísípà. 4 Wọ́n kó gbogbo ọmọ ogun wọn jáde, wọ́n pọ̀ bí iyanrìn etí òkun, pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹṣin àti kẹ̀kẹ́ ogun. 5 Gbogbo àwọn ọba yìí ṣe àdéhùn láti pàdé, wọ́n wá, wọ́n sì jọ pàgọ́ síbi omi Mérómù láti bá Ísírẹ́lì jà.

6 Torí náà, Jèhófà sọ fún Jóṣúà pé: “Má ṣe jẹ́ kí ẹ̀rù wọn bà ọ́,+ torí ní ìwòyí ọ̀la, màá fi gbogbo wọn lé Ísírẹ́lì lọ́wọ́ láti pa wọ́n. Kí o já iṣan ẹsẹ̀*+ àwọn ẹṣin wọn, kí o sì dáná sun àwọn kẹ̀kẹ́ ogun wọn.” 7 Jóṣúà àti gbogbo ọkùnrin ogun wá gbéjà kò wọ́n lójijì lẹ́gbẹ̀ẹ́ omi Mérómù. 8 Jèhófà fi wọ́n lé Ísírẹ́lì lọ́wọ́,+ wọ́n ṣẹ́gun wọn, wọ́n lé wọn títí dé Sídónì Ńlá+ àti Misirefoti-máímù+ àti Àfonífojì Mísípè lápá ìlà oòrùn, wọ́n sì pa wọ́n láìku ẹnì kankan.+ 9 Jóṣúà wá ṣe ohun tí Jèhófà sọ fún un sí wọn; ó já iṣan ẹsẹ̀ àwọn ẹṣin wọn, ó sì dáná sun àwọn kẹ̀kẹ́ ogun wọn.+

10 Lẹ́yìn náà, Jóṣúà pa dà, ó sì gba Hásórì, o fi idà pa ọba rẹ̀,+ torí pé Hásórì ni olórí gbogbo àwọn ìlú yìí tẹ́lẹ̀. 11 Wọ́n fi idà pa gbogbo àwọn* tó ń gbé ibẹ̀ run pátápátá.+ Wọn ò dá ohun eléèémí kankan sí.+ Lẹ́yìn náà, ó dáná sun Hásórì. 12 Jóṣúà gba gbogbo ìlú àwọn ọba yìí, ó sì fi idà ṣẹ́gun gbogbo ọba wọn.+ Ó pa wọ́n run,+ bí Mósè ìránṣẹ́ Jèhófà ṣe pa á láṣẹ. 13 Àmọ́ Ísírẹ́lì ò dáná sun ìkankan nínú àwọn ìlú tó wà lórí òkìtì, àfi Hásórì; òun nìkan ni Jóṣúà dáná sun. 14 Gbogbo ẹrù àwọn ìlú yìí àti ẹran ọ̀sìn wọn ni àwọn ọmọ Ísírẹ́lì kó fún ara wọn.+ Àmọ́ wọ́n fi idà pa gbogbo èèyàn títí wọ́n fi pa gbogbo wọn run.+ Wọn ò dá ẹnikẹ́ni tó ń mí sí.+ 15 Bí Jèhófà ṣe pàṣẹ fún Mósè ìránṣẹ́ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni Mósè ṣe pa á láṣẹ fún Jóṣúà,+ Jóṣúà sì ṣe bẹ́ẹ̀ gẹ́lẹ́. Gbogbo ohun tí Jèhófà pa láṣẹ fún Mósè ni Jóṣúà ṣe láìṣẹ́ ìkankan kù.+

16 Jóṣúà ṣẹ́gun gbogbo ilẹ̀ yìí, agbègbè olókè, gbogbo Négébù,+ gbogbo ilẹ̀ Góṣénì, Ṣẹ́fẹ́là,+ Árábà+ àti agbègbè olókè Ísírẹ́lì àti Ṣẹ́fẹ́là rẹ̀,* 17 láti Òkè Hálákì, tó lọ dé Séírì àti títí lọ dé Baali-gádì,+ ní Àfonífojì Lẹ́bánónì, ní ìsàlẹ̀ Òkè Hámónì,+ ó mú gbogbo ọba wọn, ó ṣẹ́gun wọn, ó sì pa wọ́n. 18 Ó ṣe díẹ̀ tí Jóṣúà fi bá gbogbo àwọn ọba yìí jagun. 19 Kò sí ìlú kankan tó bá àwọn ọmọ Ísírẹ́lì rẹ́ àfi àwọn Hífì tó ń gbé ní Gíbíónì.+ Gbogbo àwọn yòókù ni wọ́n bá jà tí wọ́n sì ṣẹ́gun wọn.+ 20 Jèhófà fàyè gbà á kí ọkàn wọn le,+ tí wọ́n fi bá Ísírẹ́lì jagun, kó lè pa wọ́n run láì ṣojú àánú sí wọn rárá.+ Ìparun tọ́ sí wọn, bí Jèhófà ṣe pa á láṣẹ fún Mósè.+

21 Ìgbà yẹn ni Jóṣúà pa àwọn Ánákímù+ run kúrò ní agbègbè olókè, ní Hébúrónì, Débírì, Ánábù àti gbogbo agbègbè olókè Júdà àti gbogbo agbègbè olókè Ísírẹ́lì. Jóṣúà pa àwọn àtàwọn ìlú wọn run.+ 22 Ánákímù kankan ò ṣẹ́ kù ní ilẹ̀ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì;+ Gásà,+ Gátì+ àti Áṣídódì+ nìkan ni wọ́n ṣẹ́ kù sí. 23 Jóṣúà wá gba gbogbo ilẹ̀ náà, bí Jèhófà ṣe ṣèlérí fún Mósè,+ Jóṣúà sì fi ṣe ogún fún Ísírẹ́lì, bí ìpín wọn, pé kí wọ́n pín in láàárín àwọn ẹ̀yà wọn.+ Ogun sì dáwọ́ dúró ní ilẹ̀ náà.+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́