ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Ẹ́kísódù 25
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

Ohun Tó Wà Nínú Ìwé Ẹ́kísódù

      • Ọrẹ àgọ́ ìjọsìn (1-9)

      • Àpótí (10-22)

      • Tábìlì (23-30)

      • Ọ̀pá fìtílà (31-40)

Ẹ́kísódù 25:2

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 35:4-9; 1Kr 29:9; 2Kọ 9:7

Ẹ́kísódù 25:3

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 38:24
  • +Ẹk 38:25
  • +Ẹk 38:3, 29

Ẹ́kísódù 25:4

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “òwú tí wọ́n fi àwọ̀ pọ́pù tó dà pọ̀ mọ́ pupa pa láró.”

  • *

    Tàbí “òwú aláwọ̀ rírẹ̀dòdò ti kòkòrò kókọ́sì.”

  • *

    Tàbí “aṣọ àtàtà.”

Ẹ́kísódù 25:5

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 36:20

Ẹ́kísódù 25:6

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 27:20
  • +Ẹk 30:23-25
  • +Ẹk 30:34, 35

Ẹ́kísódù 25:7

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 28:6
  • +Ẹk 28:15

Ẹ́kísódù 25:8

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “pàgọ́ sáàárín.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 29:45; 1Ọb 6:13; Heb 9:11

Ẹ́kísódù 25:9

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “àwòrán.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Kr 28:12; Iṣe 7:44; Heb 8:5; 9:9

Ẹ́kísódù 25:10

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ìgbọ̀nwọ́ kan jẹ́ sẹ̀ǹtímítà 44.5 (ínǹṣì 17.5). Wo Àfikún B14.

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 37:1-5

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Àwọn Ìtẹ̀jáde Tá A Tọ́ka sí Nínú Ìwé Ìpàdé, 9/2020, ojú ìwé 2

Ẹ́kísódù 25:11

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “mọ wúrà sí etí rẹ̀.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Heb 9:4
  • +Ẹk 30:1, 3

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Àwọn Ìtẹ̀jáde Tá A Tọ́ka sí Nínú Ìwé Ìpàdé, 9/2020, ojú ìwé 2

Ẹ́kísódù 25:13

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 30:1, 5; 1Kr 15:15

Ẹ́kísódù 25:15

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Ọb 8:8

Ẹ́kísódù 25:16

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 31:18; 40:20; 1Ọb 8:9; Heb 9:4

Ẹ́kísódù 25:17

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 37:6-9

Ẹ́kísódù 25:18

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Sa 4:4; Heb 9:5

Ẹ́kísódù 25:20

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Ọb 8:7; 1Kr 28:18

Ẹ́kísódù 25:21

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 40:20; Heb 9:4, 5

Ẹ́kísódù 25:22

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 30:6; Le 16:2; Nọ 7:89; Ond 20:27; Sm 80:1

Ẹ́kísódù 25:23

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 40:22; Le 24:6; Nọ 3:30, 31; Heb 9:2
  • +Ẹk 37:10-15

Ẹ́kísódù 25:24

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “mọ wúrà sí etí rẹ̀.”

Ẹ́kísódù 25:25

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Nǹkan bíi sẹ̀ǹtímítà 7.4 (ínǹṣì 2.9). Wo Àfikún B14.

  • *

    Tàbí “mọ wúrà sí etí rẹ̀ yí ká.”

Ẹ́kísódù 25:29

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 37:16; Nọ 4:7; 1Ọb 7:48, 50

Ẹ́kísódù 25:30

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Le 24:5, 6; 1Sa 21:6; 1Kr 9:32; 2Kr 13:11; Mt 12:4

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Àwọn Ìtẹ̀jáde Tá A Tọ́ka sí Nínú Ìwé Ìpàdé, 9/2020, ojú ìwé 3

Ẹ́kísódù 25:31

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 40:24; 1Ọb 7:48, 49; Heb 9:2
  • +Ẹk 37:17-24

Ẹ́kísódù 25:36

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 8:4

Ẹ́kísódù 25:37

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 30:8; Le 24:2, 3; Nọ 8:2; 2Kr 13:11

Ẹ́kísódù 25:38

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ẹ̀mú.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 4:9

Ẹ́kísódù 25:39

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tálẹ́ńtì kan jẹ́ kìlógíráàmù 34.2. Wo Àfikún B14.

Ẹ́kísódù 25:40

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “àwòrán.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 39:42; Nọ 8:4; Iṣe 7:44; Heb 8:5

Àwọn míì

Ẹ́kís. 25:2Ẹk 35:4-9; 1Kr 29:9; 2Kọ 9:7
Ẹ́kís. 25:3Ẹk 38:24
Ẹ́kís. 25:3Ẹk 38:25
Ẹ́kís. 25:3Ẹk 38:3, 29
Ẹ́kís. 25:5Ẹk 36:20
Ẹ́kís. 25:6Ẹk 27:20
Ẹ́kís. 25:6Ẹk 30:23-25
Ẹ́kís. 25:6Ẹk 30:34, 35
Ẹ́kís. 25:7Ẹk 28:6
Ẹ́kís. 25:7Ẹk 28:15
Ẹ́kís. 25:8Ẹk 29:45; 1Ọb 6:13; Heb 9:11
Ẹ́kís. 25:91Kr 28:12; Iṣe 7:44; Heb 8:5; 9:9
Ẹ́kís. 25:10Ẹk 37:1-5
Ẹ́kís. 25:11Heb 9:4
Ẹ́kís. 25:11Ẹk 30:1, 3
Ẹ́kís. 25:13Ẹk 30:1, 5; 1Kr 15:15
Ẹ́kís. 25:151Ọb 8:8
Ẹ́kís. 25:16Ẹk 31:18; 40:20; 1Ọb 8:9; Heb 9:4
Ẹ́kís. 25:17Ẹk 37:6-9
Ẹ́kís. 25:181Sa 4:4; Heb 9:5
Ẹ́kís. 25:201Ọb 8:7; 1Kr 28:18
Ẹ́kís. 25:21Ẹk 40:20; Heb 9:4, 5
Ẹ́kís. 25:22Ẹk 30:6; Le 16:2; Nọ 7:89; Ond 20:27; Sm 80:1
Ẹ́kís. 25:23Ẹk 40:22; Le 24:6; Nọ 3:30, 31; Heb 9:2
Ẹ́kís. 25:23Ẹk 37:10-15
Ẹ́kís. 25:29Ẹk 37:16; Nọ 4:7; 1Ọb 7:48, 50
Ẹ́kís. 25:30Le 24:5, 6; 1Sa 21:6; 1Kr 9:32; 2Kr 13:11; Mt 12:4
Ẹ́kís. 25:31Ẹk 40:24; 1Ọb 7:48, 49; Heb 9:2
Ẹ́kís. 25:31Ẹk 37:17-24
Ẹ́kís. 25:36Nọ 8:4
Ẹ́kís. 25:37Ẹk 30:8; Le 24:2, 3; Nọ 8:2; 2Kr 13:11
Ẹ́kís. 25:38Nọ 4:9
Ẹ́kís. 25:40Ẹk 39:42; Nọ 8:4; Iṣe 7:44; Heb 8:5
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
  • 1
  • 2
  • 3
  • 4
  • 5
  • 6
  • 7
  • 8
  • 9
  • 10
  • 11
  • 12
  • 13
  • 14
  • 15
  • 16
  • 17
  • 18
  • 19
  • 20
  • 21
  • 22
  • 23
  • 24
  • 25
  • 26
  • 27
  • 28
  • 29
  • 30
  • 31
  • 32
  • 33
  • 34
  • 35
  • 36
  • 37
  • 38
  • 39
  • 40
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
Ẹ́kísódù 25:1-40

Ẹ́kísódù

25 Jèhófà wá sọ fún Mósè pé: 2 “Sọ fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì pé kí wọ́n mú ọrẹ wá fún mi. Kí ẹ gba ọrẹ fún mi lọ́wọ́ gbogbo ẹni tí ọkàn rẹ̀ bá sún láti mú un wá.+ 3 Ọrẹ tí ẹ máa gbà lọ́wọ́ wọn nìyí: wúrà,+ fàdákà,+ bàbà,+ 4 fọ́nrán òwú aláwọ̀ búlúù, òwú aláwọ̀ pọ́pù,* òwú aláwọ̀ rírẹ̀dòdò,* aṣọ ọ̀gbọ̀* tó dáa, irun ewúrẹ́, 5 awọ àgbò tí wọ́n pa láró pupa, awọ séálì, igi bọn-ọ̀n-ní,+ 6 òróró fìtílà,+ òróró básámù tí wọ́n á fi ṣe òróró àfiyanni+ àti tùràrí onílọ́fínńdà,+ 7 àwọn òkúta ónísì àti àwọn òkúta míì tí wọ́n máa tò sára éfódì+ àti aṣọ ìgbàyà.+ 8 Kí wọ́n ṣe ibi mímọ́ fún mi, èmi yóò sì máa gbé láàárín* wọn.+ 9 Kí ẹ ṣe àgọ́ ìjọsìn àti gbogbo ohun tó máa wà níbẹ̀, kó rí bí ohun* tí màá fi hàn ọ́ gẹ́lẹ́.+

10 “Kí wọ́n fi igi bọn-ọ̀n-ní ṣe àpótí, kí gígùn rẹ̀ jẹ́ ìgbọ̀nwọ́* méjì ààbọ̀, kí fífẹ̀ rẹ̀ jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ kan ààbọ̀, kí gíga rẹ̀ sì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ kan ààbọ̀.+ 11 Kí o wá fi ògidì wúrà bò ó.+ Kí o fi bò ó nínú àti níta, kí o sì ṣe ìgbátí wúrà sí i* yí ká.+ 12 Kí o fi wúrà rọ òrùka mẹ́rin fún un, kí o sì fi wọ́n síbi òkè ẹsẹ̀ rẹ̀ mẹ́rẹ̀ẹ̀rin, òrùka méjì ní ẹ̀gbẹ́ kan àti òrùka méjì ní ẹ̀gbẹ́ kejì. 13 Kí o fi igi bọn-ọ̀n-ní ṣe àwọn ọ̀pá, kí o sì fi wúrà bò wọ́n.+ 14 O máa ki àwọn ọ̀pá náà bọ inú àwọn òrùka tó wà ní ẹ̀gbẹ́ méjèèjì Àpótí náà, kí ẹ lè máa fi gbé Àpótí náà. 15 Inú àwọn òrùka Àpótí náà ni kí àwọn ọ̀pá náà máa wà; ẹ má ṣe yọ wọ́n kúrò níbẹ̀.+ 16 Kí o gbé Ẹ̀rí tí èmi yóò fún ọ sínú Àpótí náà.+

17 “Kí o fi ògidì wúrà ṣe ìbòrí, kí gígùn rẹ̀ jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ méjì ààbọ̀, kí fífẹ̀ rẹ̀ sì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ kan ààbọ̀.+ 18 Kí o fi wúrà ṣe kérúbù méjì; kó jẹ́ iṣẹ́ ọnà tí o fi òòlù ṣe sí ìkángun méjèèjì ìbòrí náà.+ 19 Kí o ṣe àwọn kérúbù náà sí ìkángun méjèèjì, kérúbù kan ní ìkángun kọ̀ọ̀kan ìbòrí náà. 20 Kí àwọn kérúbù náà na ìyẹ́ wọn méjèèjì sókè, kí wọ́n fi bo ìbòrí náà,+ kí wọ́n sì dojú kọra. Kí àwọn kérúbù náà sì máa wo ìbòrí náà. 21 Kí o gbé ìbòrí náà+ sórí Àpótí náà, kí o sì fi Ẹ̀rí tí màá fún ọ sínú Àpótí náà. 22 Màá pàdé rẹ níbẹ̀, màá sì bá ọ sọ̀rọ̀ látorí ìbòrí náà.+ Láti àárín àwọn kérúbù méjì tó wà lórí àpótí Ẹ̀rí náà ni màá ti jẹ́ kí o mọ gbogbo ohun tí màá pa láṣẹ fún ọ pé kí o sọ fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì.

23 “Kí o tún fi igi bọn-ọ̀n-ní ṣe tábìlì,+ kí gígùn rẹ̀ jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ méjì, kí fífẹ̀ rẹ̀ jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ kan, kí gíga rẹ̀ sì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ kan ààbọ̀.+ 24 Kí o fi ògidì wúrà bò ó, kí o sì ṣe ìgbátí wúrà sí i* yí ká. 25 Kí o ṣe etí tó fẹ̀ tó ìbú ọwọ́* kan sí i yí ká, kí o sì ṣe ìgbátí wúrà sí etí náà yí ká.* 26 Kí o ṣe òrùka wúrà mẹ́rin fún tábìlì náà, kí o sì fi àwọn òrùka náà sí igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin, níbi tí ẹsẹ̀ mẹ́rẹ̀ẹ̀rin wà. 27 Kí àwọn òrùka náà sún mọ́ etí Àpótí náà, torí òun ló máa gba àwọn ọ̀pá tí wọ́n á máa fi gbé tábìlì náà dúró. 28 Igi bọn-ọ̀n-ní ni kí o fi ṣe àwọn ọ̀pá náà, kí o sì fi wúrà bò wọ́n, kí wọ́n máa fi wọ́n gbé tábìlì náà.

29 “Kí o tún ṣe àwọn abọ́ ìjẹun rẹ̀, àwọn ife rẹ̀, àwọn ṣágo àti àwọn abọ́ rẹ̀ tí wọ́n á máa da ọrẹ ohun mímu látinú rẹ̀. Kí o fi ògidì wúrà ṣe wọ́n.+ 30 Kí o sì máa gbé búrẹ́dì àfihàn sórí tábìlì níwájú mi ní gbogbo ìgbà.+

31 “Kí o fi ògidì wúrà ṣe ọ̀pá fìtílà.+ Kí ọ̀pá fìtílà náà jẹ́ iṣẹ́ ọnà tí o fi òòlù ṣe. Kí ìsàlẹ̀ rẹ̀, ọ̀pá rẹ̀, àwọn ẹ̀ka rẹ̀, àwọn iṣẹ́ ọnà rẹ̀, àwọn kókó rubutu rẹ̀ àti àwọn ìtànná rẹ̀ jẹ́ ọ̀kan ṣoṣo.+ 32 Ẹ̀ka mẹ́fà ló máa yọ jáde ní ẹ̀gbẹ́ méjèèjì ọ̀pá fìtílà náà, ẹ̀ka mẹ́ta láti ẹ̀gbẹ́ kan àti ẹ̀ka mẹ́ta láti ẹ̀gbẹ́ kejì. 33 Iṣẹ́ ọnà mẹ́ta tó rí bí òdòdó álímọ́ńdì ni kó wà lára àwọn ẹ̀ka tó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ kan, kí kókó rubutu àti ìtànná kọ̀ọ̀kan tẹ̀ léra, kí iṣẹ́ ọnà mẹ́ta tó rí bí òdòdó álímọ́ńdì sì wà lára àwọn ẹ̀ka tó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ kejì, kí kókó rubutu àti ìtànná kọ̀ọ̀kan sì tẹ̀ léra. Bí ẹ̀ka mẹ́fẹ̀ẹ̀fà ṣe máa yọ jáde lára ọ̀pá fìtílà náà nìyí. 34 Kí iṣẹ́ ọnà mẹ́rin tó rí bí òdòdó álímọ́ńdì wà lára ọ̀pá náà, kí kókó rubutu rẹ̀ àti ìtànná rẹ̀ sì tẹ̀ léra. 35 Kí kókó rubutu kan wà lábẹ́ ẹ̀ka méjì àkọ́kọ́ tó yọ jáde lára ọ̀pá náà, kí kókó rubutu kan tún wà lábẹ́ ẹ̀ka méjì tó tẹ̀ lé e, kí kókó rubutu míì sì wà lábẹ́ ẹ̀ka méjì tó tẹ̀ lé ìyẹn, bó ṣe máa wà lábẹ́ ẹ̀ka mẹ́fẹ̀ẹ̀fà tó yọ jáde lára ọ̀pá fìtílà náà nìyẹn. 36 Kí àwọn kókó rubutu, àwọn ẹ̀ka àti ọ̀pá fìtílà náà lódindi jẹ́ iṣẹ́ ọnà tí o fi òòlù ṣe, kí gbogbo rẹ̀ jẹ́ ọ̀kan, kó sì jẹ́ ògidì wúrà.+ 37 Fìtílà méje ni kí o ṣe sórí ọ̀pá náà, tí wọ́n bá sì tan àwọn fìtílà náà, iná wọn á mọ́lẹ̀ síwájú ọ̀pá náà.+ 38 Kí o fi ògidì wúrà ṣe àwọn ìpaná* rẹ̀ àti àwọn ìkóná rẹ̀.+ 39 Ògidì wúrà tálẹ́ńtì* kan ni kí o fi ṣe é, pẹ̀lú àwọn ohun èlò yìí. 40 Rí i pé o ṣe wọ́n bí ohun* tí mo fi hàn ọ́ lórí òkè.+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́