ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Ẹ́kísódù 22
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

Ohun Tó Wà Nínú Ìwé Ẹ́kísódù

      • Ìdájọ́ tí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì máa tẹ̀ lé (1-31)

        • Tí ẹnì kan bá jalè (1-4)

        • Tí ẹnì kan bá ba irè oko ẹlòmíì jẹ́ (5, 6)

        • Nípa àsanfidípò àti ohun ìní (7-15)

        • Nípa fífa ojú wúńdíá mọ́ra (16, 17)

        • Nípa ìjọsìn àti ohun tó tọ́ láwùjọ (18-31)

Ẹ́kísódù 22:1

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Sa 12:6; Lk 19:8

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé-Ìṣọ́nà,

    6/15/1992, ojú ìwé 30

Ẹ́kísódù 22:2

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 20:15

Ẹ́kísódù 22:7

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 22:4

Ẹ́kísódù 22:8

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 16:18; 19:17

Ẹ́kísódù 22:9

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 16:18; 25:1
  • +Ẹk 22:4

Ẹ́kísódù 22:11

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Le 6:2-5

Ẹ́kísódù 22:16

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 22:28, 29

Ẹ́kísódù 22:18

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Le 19:26; 20:6; Di 18:10-12; 1Sa 28:3; Ga 5:20; Ifi 22:15

Ẹ́kísódù 22:19

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Le 18:23; 20:15; Di 27:21

Ẹ́kísódù 22:20

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 25:3; 1Ọb 18:40; 1Kọ 10:20

Ẹ́kísódù 22:21

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Le 25:35
  • +Le 19:33, 34; Di 10:19

Ẹ́kísódù 22:22

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “aláìlóbìí.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 27:19; Jem 1:27

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́ (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́),

    2/2019, ojú ìwé 24-25

    Ilé Ìṣọ́,

    4/1/2009, ojú ìwé 31

Ẹ́kísódù 22:23

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 10:18; Jem 5:4

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    4/1/2009, ojú ìwé 31

Ẹ́kísódù 22:24

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    4/1/2009, ojú ìwé 31

Ẹ́kísódù 22:25

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “tí ìyà ń jẹ.”

  • *

    Tàbí “ayánilówó èlé gọbọi.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Le 25:35, 36; Di 23:19; Lk 6:34, 35

Ẹ́kísódù 22:26

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ìdógò.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 24:6

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́ (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́),

    9/2017, ojú ìwé 9

Ẹ́kísódù 22:27

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “awọ ara.”

  • *

    Tàbí “olóore ọ̀fẹ́.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 24:13
  • +Di 10:18; Sm 34:6

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́ (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́),

    9/2017, ojú ìwé 9

Ẹ́kísódù 22:28

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “kẹ́gàn.”

  • *

    Tàbí “olórí.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Le 24:11, 14
  • +Onw 10:20; Iṣe 23:5; Jud 8

Ẹ́kísódù 22:29

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ìyẹn, àwọn ibi tí wọ́n ti ń fún òróró àti wáìnì.

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Owe 3:9; 2Kọ 9:7
  • +Ẹk 13:2

Ẹ́kísódù 22:30

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 15:19
  • +Le 22:27

Ẹ́kísódù 22:31

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Le 19:2; Nọ 15:40; 1Pe 1:15
  • +Le 22:3, 8

Àwọn míì

Ẹ́kís. 22:12Sa 12:6; Lk 19:8
Ẹ́kís. 22:2Ẹk 20:15
Ẹ́kís. 22:7Ẹk 22:4
Ẹ́kís. 22:8Di 16:18; 19:17
Ẹ́kís. 22:9Di 16:18; 25:1
Ẹ́kís. 22:9Ẹk 22:4
Ẹ́kís. 22:11Le 6:2-5
Ẹ́kís. 22:16Di 22:28, 29
Ẹ́kís. 22:18Le 19:26; 20:6; Di 18:10-12; 1Sa 28:3; Ga 5:20; Ifi 22:15
Ẹ́kís. 22:19Le 18:23; 20:15; Di 27:21
Ẹ́kís. 22:20Nọ 25:3; 1Ọb 18:40; 1Kọ 10:20
Ẹ́kís. 22:21Le 25:35
Ẹ́kís. 22:21Le 19:33, 34; Di 10:19
Ẹ́kís. 22:22Di 27:19; Jem 1:27
Ẹ́kís. 22:23Sm 10:18; Jem 5:4
Ẹ́kís. 22:25Le 25:35, 36; Di 23:19; Lk 6:34, 35
Ẹ́kís. 22:26Di 24:6
Ẹ́kís. 22:27Di 24:13
Ẹ́kís. 22:27Di 10:18; Sm 34:6
Ẹ́kís. 22:28Le 24:11, 14
Ẹ́kís. 22:28Onw 10:20; Iṣe 23:5; Jud 8
Ẹ́kís. 22:29Owe 3:9; 2Kọ 9:7
Ẹ́kís. 22:29Ẹk 13:2
Ẹ́kís. 22:30Di 15:19
Ẹ́kís. 22:30Le 22:27
Ẹ́kís. 22:31Le 19:2; Nọ 15:40; 1Pe 1:15
Ẹ́kís. 22:31Le 22:3, 8
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
  • 1
  • 2
  • 3
  • 4
  • 5
  • 6
  • 7
  • 8
  • 9
  • 10
  • 11
  • 12
  • 13
  • 14
  • 15
  • 16
  • 17
  • 18
  • 19
  • 20
  • 21
  • 22
  • 23
  • 24
  • 25
  • 26
  • 27
  • 28
  • 29
  • 30
  • 31
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
Ẹ́kísódù 22:1-31

Ẹ́kísódù

22 “Tí ẹnì kan bá jí akọ màlúù tàbí àgùntàn, tó sì pa á tàbí tó tà á, kó fi akọ màlúù márùn-ún dípò akọ màlúù náà, kó sì fi àgùntàn mẹ́rin dípò àgùntàn náà.+

2 (“Tí ẹ bá rí olè kan+ níbi tó ti ń fọ́lé, tí ẹ lù ú, tó sì kú, ẹnikẹ́ni ò ní jẹ̀bi ẹ̀jẹ̀ rẹ̀. 3 Àmọ́ tó bá jẹ́ pé ojúmọmọ ló ṣẹlẹ̀, ẹ ó jẹ̀bi ẹ̀jẹ̀ rẹ̀.)

“Ó gbọ́dọ̀ fi nǹkan dípò. Tí kò bá ní nǹkan kan, kí ẹ ta òun fúnra rẹ̀ láti fi dí ohun tó jí. 4 Tí ohun tó jí bá ṣì wà láàyè, tó sì wà lọ́dọ̀ rẹ̀, bóyá akọ màlúù, kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tàbí àgùntàn, kó san án pa dà ní ìlọ́po méjì.

5 “Tí ẹnikẹ́ni bá da àwọn ẹran rẹ̀ lọ jẹko nínú pápá tàbí ọgbà àjàrà kan, tó sì jẹ́ kí wọ́n jẹko nínú pápá ẹlòmíì, kí ẹni náà fi ohun tó dáa jù nínú pápá rẹ̀ tàbí ohun tó dáa jù nínú ọgbà àjàrà rẹ̀ dí i.

6 “Tí ẹnì kan bá dá iná, tó wá ràn mọ́ àwọn igi ẹlẹ́gùn-ún, tó sì jó àwọn ìtí ọkà, tó jó ọkà tó wà ní ìdúró tàbí oko run, ẹni tó dá iná náà gbọ́dọ̀ san nǹkan kan láti fi dípò ohun tó jóná.

7 “Tí ẹnì kan bá fi owó tàbí àwọn ohun kan pa mọ́ sọ́wọ́ ọmọnìkejì rẹ̀, tí olè wá jí àwọn nǹkan náà kó nílé onítọ̀hún, tí ẹ bá mú olè náà, kó fi nǹkan dípò ní ìlọ́po méjì.+ 8 Tí ẹ ò bá rí olè náà, kí ẹ mú ẹni tó ni ilé náà wá síwájú Ọlọ́run tòótọ́+ láti mọ̀ bóyá òun ló mú nǹkan ẹnì kejì rẹ̀. 9 Ní ti gbogbo ẹjọ́ tó bá ní í ṣe pẹ̀lú ẹrù tí wọ́n jí, bóyá akọ màlúù, kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àgùntàn, aṣọ tàbí ohunkóhun tó sọ nù, tí ẹnì kan wá sọ pé, ‘Èmi ni mo ni ín!’ kí àwọn méjèèjì tí ọ̀rọ̀ náà kàn gbé ẹjọ́ wọn wá síwájú Ọlọ́run tòótọ́.+ Ẹni tí Ọlọ́run bá sọ pé ó jẹ̀bi ni yóò fi nǹkan dípò ní ìlọ́po méjì fún ọmọnìkejì rẹ̀.+

10 “Tí ẹnì kan bá fi kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tàbí akọ màlúù tàbí àgùntàn tàbí ẹran ọ̀sìn èyíkéyìí pa mọ́ sọ́dọ̀ ọmọnìkejì rẹ̀, tí ẹran náà wá kú tàbí tó di aláàbọ̀ ara tàbí tí ẹnì kan mú un lọ nígbà tí ẹnikẹ́ni ò rí i, 11 kí àwọn méjèèjì wá síwájú Jèhófà, kó lè búra pé òun ò fọwọ́ kan ẹrù ọmọnìkejì òun; kí ẹni tó ni ẹrù náà sì fara mọ́ ọn. Kí ẹnì kejì má san nǹkan kan dípò.+ 12 Àmọ́ tí wọ́n bá jí ẹran náà lọ́dọ̀ rẹ̀, kó fi nǹkan kan dípò fún ẹni tó ni ín. 13 Tó bá jẹ́ pé ẹranko búburú ló pa á, kó mú un wá bí ẹ̀rí. Kó má fi ohunkóhun dípò ẹran tí ẹranko búburú pa.

14 “Àmọ́ tí ẹnikẹ́ni bá yá ẹran lọ́wọ́ ọmọnìkejì rẹ̀, tí ẹran náà wá di aláàbọ̀ ara tàbí tó kú nígbà tí ẹni tó ni ín kò sí níbẹ̀, ẹni tó yá a yóò san nǹkan kan dípò rẹ̀. 15 Tí ẹni tó ni ín bá wà níbẹ̀, ẹni tó yá a kò ní san nǹkan kan dípò. Tó bá jẹ́ pé ṣe ló fi owó yá a, owó tó san yẹn ni yóò fi dí i.

16 “Tí ọkùnrin kan bá fa ojú wúńdíá kan tí kò ní àfẹ́sọ́nà mọ́ra, tó sì bá a sùn, ó gbọ́dọ̀ san owó orí rẹ̀ kó lè di ìyàwó rẹ̀.+ 17 Tí bàbá obìnrin náà bá kọ̀ jálẹ̀ láti fún un ní ọmọbìnrin náà, kí ọkùnrin náà san iye tí wọ́n máa ń gbà fún owó orí.

18 “O ò gbọ́dọ̀ dá àjẹ́ sí.+

19 “Ṣe ni kí ẹ pa ẹnikẹ́ni tó bá bá ẹranko sùn.+

20 “Kí ẹ pa ẹnikẹ́ni tó bá rúbọ sí ọlọ́run èyíkéyìí yàtọ̀ sí Jèhófà.+

21 “Ẹ ò gbọ́dọ̀ fìyà jẹ àjèjì tàbí kí ẹ ni ín lára,+ torí àjèjì lẹ jẹ́ ní ilẹ̀ Íjíbítì.+

22 “Ẹ ò gbọ́dọ̀ fìyà jẹ opó tàbí ọmọ aláìníbaba* kankan.+ 23 Tí ẹ bá fìyà jẹ ẹ́ pẹ́nrẹ́n, tó sì ké pè mí, ó dájú pé màá gbọ́ igbe rẹ̀;+ 24 màá bínú gidigidi, màá sì fi idà pa yín, àwọn ìyàwó yín yóò di opó, àwọn ọmọ yín yóò sì di aláìníbaba.

25 “Tí ẹ bá yá ìkankan nínú àwọn èèyàn mi tó jẹ́ aláìní* lówó, ẹni tó ń bá yín gbé, ẹ ò gbọ́dọ̀ hùwà sí i bí àwọn tó ń yáni lówó èlé.* Ẹ ò gbọ́dọ̀ gba èlé lọ́wọ́ rẹ̀.+

26 “Tí o bá gba aṣọ ọmọnìkejì rẹ láti fi ṣe ìdúró,*+ kí o dá a pa dà fún un nígbà tí oòrùn bá wọ̀. 27 Ohun kan ṣoṣo tó bò ó lára nìyẹn, aṣọ tó fi bo ara* rẹ̀; kí wá ni kó fi bora sùn?+ Tó bá ké pè mí, ó dájú pé màá gbọ́, torí mo jẹ́ aláàánú.*+

28 “O ò gbọ́dọ̀ sọ̀rọ̀ òdì sí* Ọlọ́run+ tàbí kí o sọ̀rọ̀ òdì sí ìjòyè* nínú àwọn èèyàn rẹ.+

29 “O ò gbọ́dọ̀ lọ́ra láti mú nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ irè oko rẹ àti ohun tó kún àkúnwọ́sílẹ̀ nínú àwọn ibi ìfúntí* rẹ láti fi ṣe ọrẹ.+ Kí o fún mi ní àkọ́bí nínú àwọn ọmọkùnrin rẹ.+ 30 Ohun tí wàá ṣe sí akọ màlúù àti àgùntàn rẹ nìyí:+ Kí ó wà pẹ̀lú ìyá rẹ̀ fún ọjọ́ méje. Tó bá di ọjọ́ kẹjọ, kí o mú un wá fún mi.+

31 “Kí ẹ fi hàn pé èèyàn mi tó jẹ́ mímọ́ ni yín,+ ẹ ò sì gbọ́dọ̀ jẹ ẹranko èyíkéyìí tí ẹranko búburú ti pa.+ Kí ẹ jù ú sí àwọn ajá.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́