ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 11/00 ojú ìwé 1
  • “Ọ̀rọ̀ Tí A Sọ Ní Àkókò Tí Ó Tọ́”

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • “Ọ̀rọ̀ Tí A Sọ Ní Àkókò Tí Ó Tọ́”
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2000
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Máa Bẹ̀rẹ̀ Ọ̀rọ̀ Ẹ Wẹ́rẹ́
    Nífẹ̀ẹ́ Àwọn Èèyàn—Máa Sọ Wọ́n Dọmọ Ẹ̀yìn
  • Lílo Ìbéèrè Lọ́nà Tó Múná Dóko
    Jàǹfààní Nínú Ilé Ẹ̀kọ́ Ìjọba Ọlọ́run
  • Bí A Ṣe Lè Mú Ọ̀nà Tí A Gbà Ń Fọ̀rọ̀ Wérọ̀ Sunwọ̀n Sí I
    Jàǹfààní Nínú Ilé Ẹ̀kọ́ Ìjọba Ọlọ́run
  • Fílípì Batisí Ìjòyè Òṣìṣẹ́ Ará Etiópíà kan
    Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1996
Àwọn Míì
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2000
km 11/00 ojú ìwé 1

“Ọ̀rọ̀ Tí A Sọ Ní Àkókò Tí Ó Tọ́”

1 Ṣé sísọ ọ̀rọ̀ ìyè fún àwọn ẹlòmíràn máa ń kà ọ́ láyà? Ṣé o máa ń ronú pé o gbọ́dọ̀ fi òye sọ̀rọ̀ kí ó lè wọ àwọn olùgbọ́ rẹ lọ́kàn? Nígbà tí Jésù rán àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ jáde, ó sọ fún wọn pé: “Bí ẹ ti ń lọ, ẹ máa wàásù, pé, ‘Ìjọba ọ̀run ti sún mọ́lé.’” (Mát. 10:7) Iṣẹ́ náà ò ṣòro láti lóye, bẹ́ẹ̀ ló sì rọrùn láti nípìn-ín nínú rẹ̀. Kò sí ìyàtọ̀ kankan nínú rẹ̀ lóde òní.

2 Ọ̀pọ̀ ìgbà ló jẹ́ pé a kò ní láti sọ̀rọ̀ jù ká tó bẹ̀rẹ̀ ìjíròrò. Nígbà tí Fílípì pàdé ìwẹ̀fà ará Etiópíà, ó béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé: “Ní ti gidi, ìwọ ha mọ ohun tí o ń kà bí?” (Ìṣe 8:30) Ẹ sì wo ìjíròrò tí ń mérè wá tó ń jẹ yọ látinú “ọ̀rọ̀ tí a sọ ní àkókò tí ó tọ́” yẹn!—Òwe 25:11.

3 Ìwọ náà lè bẹ̀rẹ̀ ìjíròrò lọ́nà tó jọ ìyẹn nínú iṣẹ́ ìsìn rẹ. Báwo? Nípa jíjẹ́ alákìíyèsí kí o sì lo àwọn ọ̀rọ̀ tó bá ipò kọ̀ọ̀kan mu. Béèrè ìbéèrè, kí o sì fara balẹ̀ gbọ́ ìdáhùn.

4 Àwọn Ìbéèrè Tó Ṣe Kókó: O lè lo ọ̀kan lára àwọn ìbéèrè wọ̀nyí láti bẹ̀rẹ̀ ìjíròrò:

◼ “Ǹjẹ́ o tiẹ̀ máa ń ka Àdúrà Olúwa (tàbí, Baba Wa Tí Ń Bẹ Lọ́run) nínú ìjọsìn rẹ?” (Mát. 6:9, 10) Ka apá kan àdúrà náà, lẹ́yìn náà kí o wá sọ pé: “Àwọn èèyàn kan máa ń béèrè pé, ‘Kí ni orúkọ Ọlọ́run tí Jésù ní kó di sísọ di mímọ́ (tàbí, kí á bọ̀wọ̀ fún)?’ Bẹ́ẹ̀ làwọn míì sì ń béèrè pé, ‘Ìjọba wo ni Jésù sọ pé ká gbàdúrà fún?’ Ṣé o ti rí ìdáhùn tó tẹ́rùn sí àwọn ìbéèrè wọ̀nyí?”

◼ “Ǹjẹ́ o ti f ìgbà kan rí ṣe kàyéfì pé: ‘Kí ni ìgbésí ayé túmọ̀ sí?’” Fi hàn án pé ó ní í ṣe pẹ̀lú ìmọ̀ Ọlọ́run.—Oníw. 12:13; Jòh. 17:3.

◼ “Ǹjẹ́ o tiẹ̀ rò pé ikú lè di ohun tí kò ní sí mọ́ títí láé?” Fi ìwé Aísáyà 25:8 àti Ìṣípayá 21:4 pèsè ìdáhùn tó ṣeé gbíyè lé.

◼ “Ojútùú kan ha wà sí pákáǹleke tó wà nínú ayé bí?” Fi hàn án pé Ọlọ́run kọ́ wa pé kí a ‘nífẹ̀ẹ́ aládùúgbò wa.’—Mát. 22:39.

◼ “Iná láti ọ̀run yóò ha pa ilẹ̀ ayé wa run lọ́jọ́ kan bí?” Sọ ìlérí tí Bíbélì ṣe pé ayé yóò wà títí láé fún un.—Sm. 104:5.

5 Gbé ìhìn rere náà kalẹ̀ ní ọ̀nà tó rọrùn, tó ṣe tààrà, kí o sì fi inú rere bá àwọn èèyàn sọ̀rọ̀. Jèhófà yóò f ìbùkún sí ìsapá tí o ń ṣe láti bá àwọn ẹlòmíràn sọ “ọ̀rọ̀” òtítọ́.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́