ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 1/12 ojú ìwé 2
  • Wàásù fún “Ènìyàn Gbogbo”

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Wàásù fún “Ènìyàn Gbogbo”
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2012
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • “Ẹ Lè Fún Un Ní Àwọn Ìwé Ìròyìn Tí Ọjọ́ Wọn Ti Pẹ́ Tàbí Ìwé Pẹlẹbẹ Èyíkéyìí Tó Sọ̀rọ̀ Nípa Ohun Tí Onílé Nífẹ̀ẹ́ Sí”
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2011
  • Ó Yẹ Kí Àwọn Aládùúgbò Wa Gbọ́ Ìhìn Rere
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—1998
  • Ran Àwọn Èèyàn Lọ́wọ́ Kí Wọ́n Lè Tẹ́tí sí Ọlọ́run
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2012
  • Àwọn Ohun Tá A Fi Ń Kọ́ni Lẹ́kọ̀ọ́
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2015
Àwọn Míì
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2012
km 1/12 ojú ìwé 2

Wàásù fún “Ènìyàn Gbogbo”

1. Báwo ni àwọn oníwàásù ìhìn rere tó dáńgájíá ṣe dà bí ọ̀jáfáfá oníṣẹ́ ọnà?

1 Ọ̀jáfáfá oníṣẹ́ ọnà máa ń ní ọ̀pọ̀ irin iṣẹ́, ó sì máa ń mọ ìgbà tó yẹ kó lò wọ́n àti ọ̀nà tó yẹ kó gbà lò wọ́n. Bákan náà, a ní oríṣiríṣi irin iṣẹ́ tó lè ràn wá lọ́wọ́ kí a lè ṣàṣeyọrí lẹ́nu iṣẹ́ wa gẹ́gẹ́ bí ajíhìnrere. Bí àpẹẹrẹ, a ti ṣe àwọn ìwé pẹlẹbẹ tó sọ̀rọ̀ lórí oríṣiríṣi nǹkan, èyí tó ń ràn wá lọ́wọ́ ká lè wàásù fún “ènìyàn gbogbo.” (1 Kọ́r. 9:22) A to orúkọ àwọn ìwé pẹlẹbẹ kan sínú àfikún tó wà nínú Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa yìí, a sọ àwọn tá a torí wọn ṣe é àti àwọn àbá nípa bá a ṣe lè lo àwọn ìwé pẹlẹbẹ náà lóde ẹ̀rí.

2. Àwọn ìgbà wo la lè lo ìwé pẹlẹbẹ lẹ́nu iṣẹ́ òjíṣẹ́ wa?

2 Àwọn Ìgbà Tá A Lè Lo Ìwé Pẹlẹbẹ: Ọ̀jáfáfá oníṣẹ́ ọnà máa ń lo irin iṣẹ́ kan nígbàkigbà tí irin iṣẹ́ náà bá máa ṣàǹfààní. Bákan náà, a lè lo ìwé pẹlẹbẹ nígbàkigbà tá a bá rí i pé ó máa ṣe ẹnì kan láǹfààní, kì í wulẹ̀ ṣe ní àwọn oṣù tá a bá sọ pé ìwé pẹlẹbẹ ni kí á lò lóde ẹ̀rí. Bí àpẹẹrẹ, tó bá jẹ́ pé ìwé Bíbélì Fi Kọ́ni là ń lò ní oṣù kan, tó sì jẹ́ pé àwọn tí kì í ṣe Kristẹni ló wà ní ìpínlẹ̀ ìwàásù tá a ti fẹ́ ṣiṣẹ́, tí wọn kò sì fi bẹ́ẹ̀ nífẹ̀ẹ́ sí ẹ̀kọ́ Bíbélì, ó lè ṣàǹfààní tá a bá lo ìwé pẹlẹbẹ kan tó ṣeé ṣe kí ẹni tá à ń wàásù fún nífẹ̀ẹ́ sí, kí a ṣẹ̀ṣẹ̀ wá fi ìwé Bíbélì Fi Kọ́ni hàn án, lẹ́yìn tá a ti sọ̀rọ̀ lọ́nà tó máa mú kí ó nífẹ̀ẹ́ sí òtítọ́.

3. Kí nìdí tó fi yẹ kí a jẹ́ ọ̀jáfáfá nínú lílo àwọn irin iṣẹ́ tá a fi ń wàásù?

3 Bíbélì gbóríyìn fún àwọn tó bá jẹ́ ọ̀jáfáfá lẹ́nu iṣẹ́ wọn. (Òwe 22:29) Ó dájú pé, kò sí iṣẹ́ mìíràn tó ṣe pàtàkì ju “iṣẹ́ mímọ́ ti ìhìn rere.” (Róòmù. 15:16) Tá a bá fẹ́ jẹ́ “aṣiṣẹ́ tí kò ní ohun kankan láti tì í lójú,” àfi ká máa sapá gidigidi ká lè túbọ̀ di ọ̀jáfáfá nínú lílo àwọn irin iṣẹ́ wa.—2 Tím. 2:15.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́