ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 3/12 ojú ìwé 7
  • Ìṣẹ̀dá Ń Gbé Ògo Ọlọ́run Yọ

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ìṣẹ̀dá Ń Gbé Ògo Ọlọ́run Yọ
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2012
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Túbọ̀ Máa Kẹ́kọ̀ọ́ Nípa Jèhófà Lára Àwọn Nǹkan Tó Dá
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2023
  • Ṣé O Máa Ń Rí Àwọn Ànímọ́ Ọlọ́run Tí A Kò Lè Rí?
    Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2019
  • Máa Fi Àwọn Nǹkan Tí Jèhófà Dá Kọ́ Ọmọ Rẹ
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2023
  • Àwọn Ohun Tí Jèhófà Dá Fi Hàn Pé Ó Nífẹ̀ẹ́ Wa
    Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2021
Àwọn Míì
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2012
km 3/12 ojú ìwé 7

Ìṣẹ̀dá Ń Gbé Ògo Ọlọ́run Yọ

Ọ̀pọ̀ èèyàn ló fẹ́ràn kí wọ́n máa wo àwọn nǹkan tí Ọlọ́run dá. Àmọ́ ìwọ̀nba èèyàn ló mọ̀ pé bí àwọn ṣe ń ṣe bẹ́ẹ̀, ńṣe nìyẹn ń jẹ́ kí wọ́n mọ ohun tó wà lọ́kàn Atóbilọ́lá Ẹlẹ́dàá wa àti irú ẹni tó jẹ́ gan-an. (Róòmù 1:20) Nígbà ayé Dáfídì, ó kẹ́kọ̀ọ́ nípa Jèhófà látinú ọ̀rọ̀ tí Ọlọ́run mí sí. Bákan náà, ó tún “rí” àwọn iṣẹ́ ọwọ́ Jèhófà, èyí sì mú kó túbọ̀ sún mọ́ ọn. (Sm. 8:3, 4) Apá Kẹta nínú ìwé pẹlẹbẹ náà, Ọlọrun Ha Bikita Nipa Wa Niti Gidi Bi?, máa jẹ́ kí àwa, àwọn ọmọ wa àti àwọn tí à ń kọ́ lẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì fara balẹ̀ kẹ́kọ̀ọ́ nípa díẹ̀ lára àwọn ohun tí Jèhófà dá, ó máa jẹ́ ká rí àwọn ànímọ́ rẹ̀, ó sì máa jẹ́ ká mọ irú ẹni tí Atóbilọ́lá Ẹlẹ́dàá wa jẹ́, èyí táá mú kí á lè túbọ̀ sún mọ́ ọn.

“Máa Fi Tọkàntara Ṣàkíyèsí” Iṣẹ́ Ọwọ́ Jèhófà: Jésù rọ̀ wá pé kí á “fi tọkàntara ṣàkíyèsí àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run” kí á sì “kọ́ ẹ̀kọ́ àríkọ́gbọ́n lára àwọn òdòdó lílì pápá.” (Mát. 6:26, 28) Tá a bá ń ṣe bẹ́ẹ̀, ìgbàgbọ́ àti ìgbẹ́kẹ̀lé tá a ní nínú Ẹlẹ́dàá wa máa lágbára sí i, a máa túbọ̀ mọyì ọgbọ́n Jèhófà, a máa túbọ̀ mọyì bó ṣe ní agbára láti gbà wá, a ó sì rí i pé ó nífẹ̀ẹ́ wa lóòótọ́. Dípò tó o fi máa jẹ́ kí àwọn ohun tí ẹ̀dá èèyàn ṣe gbà ọ́ lọ́kàn, wá àyè láti máa kíyè sí àwọn ohun tí Jèhófà dá, kó o sì máa ronú nípa ohun tí àwọn nǹkan yìí ń jẹ́ ká mọ̀ nípa Ọlọ́run wa.—Sm. 19:1.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́