ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • wp21 No. 3 ojú ìwé 15
  • Ohun Tó O Bá Ṣe Láá Pinnu Bọ́jọ́ Ọ̀la Ẹ Ṣe Máa Rí

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ohun Tó O Bá Ṣe Láá Pinnu Bọ́jọ́ Ọ̀la Ẹ Ṣe Máa Rí
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tá À Ń Fi Sóde)—2021
  • Ìsọ̀rí
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • BÁWO LA ṢE LÈ NÍFẸ̀Ẹ́ JÈHÓFÀ KÁ SÌ MÁA FETÍ SÍ OHÙN RẸ̀?
  • Ìwọ Lo Máa Pinnu Bí Ọjọ́ Ọ̀la Rẹ Ṣe Máa Rí!
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tá À Ń Fi Sóde)—2018
  • O Lè Sún Mọ́ Ọlọ́run
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tá À Ń Fi Sóde)—2019
  • “Àwọn Ọlọ́kàn Tútù Ni Yóò Ni Ilẹ̀ Ayé”
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tá À Ń Fi Sóde)—2018
  • Ọ̀rọ̀ Ìbẹ̀rẹ̀
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tá À Ń Fi Sóde)—2021
Àwọn Míì
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tá À Ń Fi Sóde)—2021
wp21 No. 3 ojú ìwé 15
Ọkùnrin kan ń fi nǹkan han ọ̀rẹ́ ẹ̀ lórí fóònù nínú ilé oúnjẹ kan.

Ohun Tó O Bá Ṣe Láá Pinnu Bọ́jọ́ Ọ̀la Ẹ Ṣe Máa Rí

Ní nǹkan bí ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ààbọ̀ (3,500) ọdún sẹ́yìn, Jèhófà Ọlọ́run sọ ohun táwọn tó ń jọ́sìn rẹ̀ máa ṣe tí wọ́n bá fẹ́ kí ọjọ́ ọ̀la wọn dáa. Ó ní: “Mo ti fi ìyè àti ikú sí iwájú rẹ, ìbùkún àti ègún; yan ìyè, kí o lè máa wà láàyè, ìwọ àti àwọn àtọmọdọ́mọ rẹ.”​—Diutarónómì 30:19.

Àwọn èèyàn yẹn gbọ́dọ̀ pinnu láti ṣe ohun tó tọ́ tí wọ́n bá fẹ́ kí ọjọ́ ọ̀la wọn dáa. Àwa náà ní láti ṣe ohun kan náà lónìí. Bíbélì sọ ohun tá a lè ṣe tá a bá fẹ́ kí ọjọ́ ọ̀la wa dáa. Ó sọ pé ká ‘nífẹ̀ẹ́ Jèhófà Ọlọ́run wa, ká sì máa fetí sí ohùn rẹ̀.’​—Diutarónómì 30:20.

BÁWO LA ṢE LÈ NÍFẸ̀Ẹ́ JÈHÓFÀ KÁ SÌ MÁA FETÍ SÍ OHÙN RẸ̀?

MÁA KẸ́KỌ̀Ọ́ BÍBÉLÌ: Kó o tó lè nífẹ̀ẹ́ Jèhófà, o ní láti kẹ́kọ̀ọ́ nípa rẹ̀ látinú Bíbélì. Bó o bá ṣe túbọ̀ ń kẹ́kọ̀ọ́ nípa Jèhófà, bẹ́ẹ̀ ni wàá máa rí i pé ó nífẹ̀ẹ́ rẹ, wàá sì gbà pé ohun tó dáa jù lọ ló fẹ́ fún ẹ. Ó fẹ́ kó o máa gbàdúrà sí òun ‘torí ó ń bójú tó ẹ.’ (1 Pétérù 5:7) Kódà, Bíbélì jẹ́ ká rí i pé tó o bá gbìyànjú láti sún mọ́ ọn, ó máa ‘sún mọ́ ẹ.’​—Jémíìsì 4:8.

MÁA FI OHUN TÓ Ò Ń KỌ́ SÍLÒ: O máa fi hàn pé ò ń fetí sí Ọlọ́run tó o bá ń tẹ̀ lé àwọn ìmọ̀ràn ọlọgbọ́n rẹ̀ tó wà nínú Bíbélì. Tó o bá ń ṣe bẹ́ẹ̀, “ọ̀nà rẹ máa yọrí sí rere, . . . wàá sì máa hùwà ọgbọ́n.”​—Jóṣúà 1:8.

Tó o bá fẹ́ mọ̀ sí i, lọ sórí ìkànnì wa, jw.org. Wàá rí Bíbélì kà níbẹ̀, wàá rí apá tó o ti lè kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì láyè ara rẹ,a o sì lè ní kí ẹnì kan wá máa kọ́ ẹ lẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì.

Jẹ́ kí Bíbélì tọ́ ẹ sọ́nà kí ọjọ́ ọ̀la rẹ lè dáa!

a Ní báyìí, ó wà ní èdè méje. Lára àwọn èdè náà ni Gẹ̀ẹ́sì, Mandarin Chinese àti Cantonese Chinese.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́