Wíwá Àwọn Ẹni Yíyẹ Rí
1 Àwọn ìtọ́ni tí Jésù fún wa nípa bí a óò ṣe ṣe iṣẹ́ ìwàásù náà ń mú ìpèníjà wá. Ó sọ pé: “Ìlú ńlá tàbí abúlé èyíkéyìí tí ẹ bá wọ̀, ẹ wá ẹni yíyẹ inú rẹ̀ kàn.” (Mát. 10:11) Ní àkókò yìí tí àwọn èèyàn kì í fi bẹ́ẹ̀ sí nílé mọ́, ọ̀nà gbígbéṣẹ́ wo la lè gbà wá àwọn ẹni yíyẹ rí?
2 Gbé Ìpínlẹ̀ Rẹ Yẹ̀ Wò Dáadáa: Lákọ̀ọ́kọ́ ná, gbé ìpínlẹ̀ rẹ yẹ̀ wò dáadáa. Ìgbà wo ló ṣeé ṣe jù lọ pé kí àwọn èèyàn wà nílé? Ibo la ti lè rí wọn lójú mọmọ? Ǹjẹ́ ọjọ́ kan wà láàárín ọ̀sẹ̀ tàbí àkókò kan wà lóòjọ́ tí wọ́n á lè tẹ́tí gbọ́ wa dáadáa tá a bá kàn sí wọn? Mímú iṣẹ́ òjíṣẹ́ rẹ bá ìgbòkègbodò àti ipò àwọn èèyàn tó wà ní ìpínlẹ̀ rẹ mu lè ràn ọ́ lọ́wọ́ láti ṣe àṣeyọrí púpọ̀.—1 Kọ́r. 9:23, 26.
3 Ọ̀pọ̀ àwọn akéde ti rí i pé àwọ́n máa ń bá àwọn èèyàn nílé lọ́wọ́ ìrọ̀lẹ́. Lásìkò yẹn, ara àwọn onílé kan máa ń balẹ̀ dáadáa, wọ́n sì máa ń fẹ́ láti tẹ́tí sílẹ̀. Ṣíṣiṣẹ́ láwọn àgbègbè okòwò àti láwọn ibi táwọn èèyàn máa ń pọ̀ sí tún jẹ́ ọ̀nà mìíràn tá a lè gbà jẹ́ kí àwọn èèyàn gbọ́ nípa ìhìn rere náà.
4 Nínú oṣù kan tó jẹ́ oṣù àkànṣe ìgbòkègbodò, ìjọ kan ṣètò ìjẹ́rìí ọwọ́ ìrọ̀lẹ́ láwọn ọjọ́ Sátidé àti Sunday wọ́n sì tún ṣètò ìjẹ́rìí ìrọ̀lẹ́ láwọn ọjọ́ Wednesday àti Friday. Bákan náà, wọ́n ṣètò fún ìjẹ́rìí orí tẹlifóònù, wọ́n sì tún ṣètò láti ṣiṣẹ́ láwọn àgbègbè okòwò. Àwọn ìṣètò wọ̀nyí mú kí ìtara àwọn ará fún iṣẹ́ òjíṣẹ́ pọ̀ sí i débi pé ìjọ náà pinnu láti máa bá àwọn ìṣètò náà lọ.
5 Jẹ́ Aláápọn Nínú Ṣíṣe Ìpadàbẹ̀wò: Bí kò bá rọrùn ní ìpínlẹ̀ rẹ láti bá àwọn èèyàn nílé nígbà tó o bá lọ ṣe ìpadàbẹ̀wò, gbìyànjú láti rí i pé gbogbo ìgbà tó o bá lọ bẹ̀ wọ́n wò lẹ jọ máa ń fohùn ṣọ̀kan lórí ìgbà kan pàtó tí wàá padà wá, títí kan ìgbà àkọ́kọ́ tó o bá bá àwọn èèyàn sọ̀rọ̀. Lẹ́yìn náà, rí i dájú pé o padà lọ. (Mát. 5:37) Bí onílé náà bá ní tẹlifóònù, o lè ní kó fún ọ ní nọ́ńbà tẹlifóònù rẹ̀, bó bá yẹ bẹ́ẹ̀. Èyí tún lè ràn ọ́ lọ́wọ́ láti tún kàn sí ẹni náà.
6 Ó dájú pé Jèhófà yóò bù kún ìsapá wa aláápọn láti wá àwọn ẹni yíyẹ rí àti láti padà lọ bẹ àwọn tó fìfẹ́ hàn wò.—Òwe 21:5.