ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 12/09 ojú ìwé 2
  • Ìtòlẹ́sẹẹsẹ Àpéjọ Àkànṣe ti Ọdún 2010

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ìtòlẹ́sẹẹsẹ Àpéjọ Àkànṣe ti Ọdún 2010
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2009
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • ‘Oúnjẹ Ní Àkókò Tí Ó Bẹ́tọ̀ọ́ Mu’
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2010
  • Ọ̀nà Tuntun Tí A Ó Máa Gbà Ṣe Àtúnyẹ̀wò Ìtòlẹ́sẹẹsẹ Àpéjọ Àyíká àti Àkànṣe
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2004
  • Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run Ń Sa Agbára
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2013
  • Ìtòlẹ́sẹẹsẹ Tuntun fún Àpéjọ Àkànṣe
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2001
Àwọn Míì
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2009
km 12/09 ojú ìwé 2

Ìtòlẹ́sẹẹsẹ Àpéjọ Àkànṣe ti Ọdún 2010

1. (a) Kí ni díẹ̀ lára ẹṣin ọ̀rọ̀ àwọn àpéjọ àkànṣe tá a gbé karí Ìwé Mímọ́ tá a ti ṣe sẹ́yìn? (b) Ǹjẹ́ àwọn ohun pàtó kan wà nínú àpéjọ àkànṣe tá a ti ṣe sẹ́yìn tó ti ràn ẹ́ lọ́wọ́ lẹ́nu iṣẹ́ òjíṣẹ́ rẹ?

1 Díẹ̀ lára àkọlé àwọn àpéjọ àkànṣe tá a ti ṣe sẹ́yìn ni: “Rí Àrídájú Awọn Ohun Tí Wọn Ṣe Pataki Jù,” “Dídúró Gírígírí Gẹgẹbi Agbo Kan,” “Máa Báa Nìṣó Ní Jíjẹ́rìí sí Òtítọ́” àti “Amọ̀ Ni Wá, Jèhófà Ló Ń Mọ Wá.” (Fílí. 1:9, 10; 1:27; Jòh. 18:37; Aísá. 64:8) Ǹjẹ́ ò ń fojú sọ́nà fún àpéjọ àkànṣe ti ọdún 2010? Ẹṣin ọ̀rọ̀ àpéjọ àkànṣe náà ni: “Àkókò Tí Ó Ṣẹ́ Kù Ti Dín Kù.” A gbé e ka ìwé 1 Kọ́ríńtì 7:29.

2. Báwo la ṣe lè máa fojú sọ́nà fún àpéjọ yìí?

2 Gbàrà tí wọ́n bá ti ṣèfilọ̀ ọjọ́ tí ìjọ yín máa ṣe àpéjọ àkànṣe ni kó o ti bẹ̀rẹ̀ sí fìtara múra sílẹ̀ fún un. Káwọn ọmọ wọn lè máa wọ̀nà fún ọjọ́ tí wọ́n máa ṣe àpéjọ, àwọn òbí kan máa ń sàmì sí ọjọ́ náà lórí kàlẹ́ńdà, wọ́n á sì kọ ohun tí wọ́n máa nílò, wọ́n á wá bẹ̀rẹ̀ sí í ka iye ọjọ́ tó kù kí ọjọ́ náà pé. Nígbà tẹ́ ẹ bá ń ṣe Ìjọsìn Ìdílé yín, ẹ lè ṣàtúnyẹ̀wò àwọn ohun tẹ́ ẹ kọ sílẹ̀ láwọn àpéjọ àkànṣe tẹ́ ẹ ti ṣe kọjá. Ẹ tún lè múra ọkàn yín sílẹ̀ fún àpéjọ yìí, nípa ṣíṣàyẹ̀wò ohun tó wà nínú ìwé Jàǹfààní Nínú Ilé Ẹ̀kọ́ Ìjọba Ọlọ́run, ojú ìwé 13 sí 16, kẹ́ ẹ lè túbọ̀ “fiyè sí bí ẹ ṣe ń fetí sílẹ̀.”—Lúùkù 8:18.

3. Báwo la ṣe lè jàǹfààní kíkún látinú ìtòlẹ́sẹẹsẹ àpéjọ náà?

3 Fi Ohun Tó Ò Ń Kọ́ Sílò: Ohun tí ọ̀pọ̀ sábà máa ń sọ lẹ́yìn àpéjọ ni pé, “Ìtòlẹ́sẹẹsẹ yìí mà kàmàmà o!” Òótọ́ sì ni, torí pé àwọn àpéjọ wa jẹ́ ọ̀kan lára àwọn ìpèsè yanturu tá à ń rí gbà látọ̀dọ̀ Jèhófà. (Òwe 10:22) Kí ohun tó ò ń gbọ́ tó lè ṣe ẹ́ láǹfààní, o gbọ́dọ̀ máa ṣàṣàrò lórí rẹ̀ kó o sì fi í sọ́kàn. (Lúùkù 8:15) Nígbà tẹ́ ẹ bá ń pa dà sílé láti àpéjọ yìí, ẹ jíròrò ohun tẹ́ ẹ kọ́ gẹ́gẹ́ bí ìdílé tàbí pẹ̀lú àwọn tẹ́ ẹ bá jọ wà nínú ọkọ̀. Ẹ sọ̀rọ̀ nípa àfojúsùn tí ẹnì kọ̀ọ̀kan yín ní àti àwọn ohun tó máa ràn yín lọ́wọ́ lẹ́nu iṣẹ́ òjíṣẹ́ yín. Bẹ́ ẹ bá ń ṣe bẹ́ẹ̀, èyí á jẹ́ kẹ́ ẹ lè máa báa nìṣó láti jàǹfààní látinú àpéjọ náà lẹ́yìn tí àpéjọ náà bá ti parí.—Ják. 1:25.

4. Àǹfààní àkànṣe wo la máa jẹ látinú àpéjọ yìí?

4 Inú wa sábà máa ń dùn gan-an nígbà tá a bá gba ẹ̀bùn kan tó bọ́ sákòókò. Ṣé ara wa ti wà lọ́nà láti mọ ohun tí Jèhófà ní nípamọ́ fún wa nígbà àpéjọ àkànṣe wa tó ń bọ̀? Ó dá wa lójú pé ó máa wúlò fún wa ní gbogbo ọ̀nà. A mọ̀ pé ẹ̀bùn tá a nílò gan-an ni Baba wa ọ̀run, Jèhófà máa fún wa, ìyẹn ìṣírí àti ìdánilẹ́kọ̀ọ́ táá mú ká lè ṣe iṣẹ́ tó gbé lé wa lọ́wọ́.—2 Tím. 4:2; Ják. 1:17.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́