ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 8/11 ojú ìwé 5
  • A Ṣètò Àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà Láti Wàásù Ìhìn Rere

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • A Ṣètò Àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà Láti Wàásù Ìhìn Rere
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2011
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Iṣẹ́ Ìwàásù Tó Lókìkí Tó Báyìí Ò Tíì Wáyé Rí!
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2007
  • Awọn Ẹlẹ́rìí Jehofa Eto-ajọ ti Ó Wà Lẹhin Orukọ Naa
    Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1993
  • Àwọn Irin Iṣẹ́ Tó Ń Kọ́ni Lẹ́kọ̀ọ́, Tó Ń Súnni Ṣiṣẹ́, Tó sì Tún Ń Fúnni Lókun
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2000
  • Fídíò Tuntun Tí A Ó Máa Fi Bẹ̀rẹ̀ Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2014
Àwọn Míì
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2011
km 8/11 ojú ìwé 5

A Ṣètò Àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà Láti Wàásù Ìhìn Rere

Ó ti lé ní ọgọ́rùn-ún ọdún báyìí tá a ti ṣètò àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà láti máa wàásù ìhìn rere. À ń lo ọgọ́rọ̀ọ̀rún-ún èdè láti wàásù ìhìn rere náà, a sì ń wàásù ní ilẹ̀ tó lé ní ọ̀gọ́rùn-ún méjì ó lé ọgbọ̀n [230], èyí sì ni iṣẹ́ ìwàásù tó tíì gbòòrò jù lọ lórí ilẹ̀ ayé. (Mát. 24:14) Kí nìdí tó fi yẹ ká ṣe iṣẹ́ yìí? Báwo la ṣe ń ṣe é jákèjádò ayé? Fídíò náà, A Ṣètò Àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà Láti Wàásù Ìhìn Rere, ìyẹn Jehovah’s Witnesses—Organized to Share the Good News, dáhùn àwọn ìbéèrè yìí, ó sì tún ṣe ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ àlàyé nípa onírúurú ọ̀nà tá à ń gbà ṣe iṣẹ́ ìwàásù kárí ayé. Lẹ́yìn tó o bá ti wo fídíò náà, ronú nípa àwọn ìbéèrè yìí.

Báwo ni fídíò náà ṣe mú kó o túbọ̀ mọrírì (1) ìsapá tí ètò Jèhófà ńṣe láti wàásù ìhìn rere? (2 Tím. 4:2) (2) ìdílé Bẹ́tẹ́lì tó wà káàkiri ayé? (3) ìdálẹ́kọ̀ọ́ tá à ń fún àwọn míṣọ́nnárì àtàwọn alábòójútó? (2 Tím. 2:2) (4) bó ti ṣe pàtàkì tó láti bẹ̀rẹ̀ ọjọ́ kọ̀ọ̀kan pẹ̀lú kíka ẹsẹ Bíbélì kan àti mímúra sílẹ̀ fún ìpàdé lọ́sọ̀ọ̀sẹ̀? (Ìṣe 17:11) (5) àǹfààní tó wà nínú lílọ sí àwọn ìpàdé Kristẹni? (Héb. 10:24, 25) (6) àǹfààní tó o máa ní nígbà tí Párádísè bá dé? (Aísá. 11:9) (7) àǹfààní tó o ní láti máa kópa nínú iṣẹ́ ìkórè tó ń lọ lọ́wọ́?—Jòh. 4:35.

Fídíò yìí ti jẹ́ irinṣẹ́ tó wúlò gan-an láti mú kí àwọn olùfìfẹ́hàn mọ̀ nípa iṣẹ́ ìwàásù tí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ń ṣe kárí ayé. (8) Ìgbà wo ló dára jù lọ láti fi fídíò yìí han àwọn tá à ń kọ́ lẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì, ìbátan wa àtàwọn míì? (9) Àwọn ọ̀rọ̀ tó wúni lórí wo làwọn èèyàn sọ nígbà tó o fi fídíò náà hàn wọ́n?

Bá a ṣe ń ronú nípa àwọn ohun tí Jèhófà ti gbé ṣe, ó ń sún wa láti tún ọ̀rọ̀ onísáàmù yìí sọ pé: “Ọ̀pọ̀ nǹkan ni ìwọ fúnra rẹ ti ṣe, Ìwọ Jèhófà Ọlọ́run mi, àní àwọn iṣẹ́ àgbàyanu rẹ àti ìrònú rẹ sí wa; kò sí ẹnì kankan tí a lè fi ọ́ wé.” (Sm. 40:5) Ẹ jẹ́ ká máa lo fídíò náà lọ́nà táá mú kí àwọn èèyàn túbọ̀ mọrírì Jèhófà àti ètò rẹ̀!

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́