ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • mwb20 August ojú ìwé 3
  • Ẹ Dúró Gbọn-in Bí Òpin Ṣe Ń Sún Mọ́lé

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ẹ Dúró Gbọn-in Bí Òpin Ṣe Ń Sún Mọ́lé
  • Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2020
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Àwọn Ànímọ́ Kristẹni Tó Yẹ Kó O Ní​—Ìgboyà
    Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Àwa Kristẹni​—Ìwé Ìpàdé (2017)
  • Kò Nira Jù Láti Jẹ́ Onígboyà
    Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2021
  • “Jẹ́ Onígboyà . . . Kí O sì Gbé Ìgbésẹ̀”
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2017
  • Jẹ́ Kí N Ní Ìgboyà
    “Fi Ayọ̀ Kọrin” sí Jèhófà
Àwọn Míì
Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2020
mwb20 August ojú ìwé 3

MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI

Ẹ Dúró Gbọn-in Bí Òpin Ṣe Ń Sún Mọ́lé

ÌDÍ TÓ FI ṢE PÀTÀKÌ: Láìpẹ́, àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ gbankọgbì máa dán wa wò, ìyẹn á sì fi hàn bóyá a nígboyà àti ìgbàgbọ́ nínú Jèhófà. Ìparun ìsìn èké ló máa bẹ̀rẹ̀ ìpọ́njú ńlá. (Mt 24:21; Ifi 17:​16, 17) Lákòókò tí nǹkan máa lé ganan yẹn, ó ṣeé ṣe ká máa kéde ọ̀rọ̀ ìdájọ́ tó dà bí òkúta yìnyín. (Ifi 16:21) Lẹ́yìn náà, Gọ́ọ̀gù ti ilẹ̀ Mágọ́gù máa gbéjà kò wá. (Isk 38:​10-12, 14-16) Ìyẹn ló máa mú kí Jèhófà gbégbèésẹ̀, kí “ogun ọjọ́ ńlá Ọlọ́run Olódùmarè” sì bẹ̀rẹ̀. (Ifi 16:​14, 16) Tá a bá ń fìgboyà kojú àwọn ohun tó lè dán ìgbàgbọ́ wa wò ní báyìí, àá túbọ̀ nígboyà láti kojú àwọn ohun tó ń bọ̀ lọ́jọ́ iwájú.

BÓ O ṢE LÈ ṢE É:

  • Fìgboyà dúró lórí àwọn ìlànà Jèhófà nípa ìwà rere.​—Ais 5:20

  • Máa jọ́sìn Jèhófà pẹ̀lú àwọn ará.​—Heb 10:​24, 25

  • Máa tẹ̀ lé ìlànà èyíkéyìí tí ètò Ọlọ́run bá fún wa láìjáfara.​—Heb 13:17

  • Máa ronú lórí bí Jèhófà ṣe gba àwọn èèyàn rẹ̀ là nígbà àtijọ́.​—2Pe 2:9

  • Máa gbàdúrà sí Jèhófà, kó o sì gbẹ́kẹ̀ lé e.​—Sm 112:​7, 8

WO FÍDÍÒ NÁÀ ÀWỌN OHUN TÓ MÁA ṢẸLẸ̀ LỌ́JỌ́ IWÁJÚ TÓ GBA PÉ KÁ NÍ ÌGBOYÀ​—ÀYỌLÒ, KÓ O SÌ DÁHÙN ÀWỌN ÌBÉÈRÈ YÌÍ:

  • Apá kan nínú fídíò ‘Àwọn Ohun Tó Máa Ṣẹlẹ̀ Lọ́jọ́ Iwájú Tó Gba Pé Ká Ní Ìgboyà.’ Nínú Gbọ̀ngàn Ìjọba, inú arábìnrin kan ò dùn nígbà tó rí ìjọ tóun máa lọ lẹ́yìn tí ìjọ wọn bá pín.

    Àdánwò wo làwọn àkéde kan kojú nígbà tí ìjọ wọn pín sí méjì?

  • Apá kan nínú fídíò ‘Àwọn Ohun Tó Máa Ṣẹlẹ̀ Lọ́jọ́ Iwájú Tó Gba Pé Ká Ní Ìgboyà.’ Arábìnrin náà ń ń bá arábìnrin méjì míì sọ̀rọ̀ nípa ibi tí wọ́n pín wọn sí.

    Tá a bá ń ṣègbọràn, báwo nìyẹn ṣe máa jẹ́ ká túbọ̀ nígboyà?

  • Apá kan nínú fídíò ‘Àwọn Ohun Tó Máa Ṣẹlẹ̀ Lọ́jọ́ Iwájú Tó Gba Pé Ká Ní Ìgboyà.’ Àyà ọ̀dọ́kùnrin kan ń já nígbà tó rí àwòrán Amágẹ́dọ́nì nínú ìwé ‘Ìjọba Ọlọ́run Ti Ń Ṣàkóso!’

    Kí nìdí tá a fi máa nílò ìgboyà nígbà tí Amágẹ́dọ́nì bá dé?

  • Apá kan nínú fídíò ‘Àwọn Ohun Tó Máa Ṣẹlẹ̀ Lọ́jọ́ Iwájú Tó Gba Pé Ká Ní Ìgboyà.’ Jèhóṣáfátì àtàwọn ọmọ Júdà dé ojú ogun, wọ́n sì rí i pé gbogbo àwọn ọmọ ogun ọ̀tá ti kú.

    Múra sílẹ̀ ní báyìí bó o ṣe ń retí àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ ọjọ́ iwájú tó máa gba pé ká nígboyà

    Ìtàn Bíbélì wo ló lè mú kó túbọ̀ dá wa lójú pé Jèhófà máa gbà wá là?​—2Kr 20:​1-24

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́