-
Nọ́ńbà 28:26-31Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
26 “‘Ní ọjọ́ àkọ́pọ́n èso,+ tí ẹ bá mú ọrẹ ọkà tuntun wá fún Jèhófà,+ kí ẹ ṣe àpéjọ mímọ́ nígbà tí ẹ bá ń ṣe àsè àwọn ọ̀sẹ̀.+ Ẹ ò gbọ́dọ̀ ṣe iṣẹ́ agbára+ kankan. 27 Kí ẹ mú akọ ọmọ màlúù méjì wá pẹ̀lú àgbò kan àti akọ ọ̀dọ́ àgùntàn méje tí ọ̀kọ̀ọ̀kan jẹ́ ọlọ́dún kan+ láti fi rú ẹbọ sísun tó ń mú òórùn dídùn* jáde sí Jèhófà, 28 pẹ̀lú ìyẹ̀fun tó kúnná tí wọ́n pò mọ́ òróró láti fi ṣe ọrẹ ọkà, ìdá mẹ́ta nínú mẹ́wàá òṣùwọ̀n fún akọ màlúù kọ̀ọ̀kan, ìdá méjì nínú mẹ́wàá òṣùwọ̀n fún àgbò náà, 29 ìdá mẹ́wàá òṣùwọ̀n fún ọ̀kọ̀ọ̀kan akọ ọ̀dọ́ àgùntàn méje náà, 30 pẹ̀lú ọmọ ewúrẹ́ kan láti ṣe ètùtù fún yín.+ 31 Kí ẹ fi wọ́n rúbọ ní àfikún sí ẹbọ sísun ìgbà gbogbo àti ọrẹ ọkà rẹ̀. Pẹ̀lú àwọn ọrẹ ohun mímu wọn, kí àwọn ẹran+ náà jẹ́ èyí tí ara wọn dá ṣáṣá.
-