ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Jóṣúà 22
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

Ohun Tó Wà Nínú Ìwé Jóṣúà

      • Àwọn ẹ̀yà tó wà ní ìlà oòrùn pa dà sílé (1-8)

      • Wọ́n mọ pẹpẹ sí Jọ́dánì (9-12)

      • Wọ́n ṣàlàyé ohun tí pẹpẹ náà túmọ̀ sí (13-29)

      • Wọ́n yanjú ọ̀rọ̀ náà (30-34)

Jóṣúà 22:2

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 32:20-22; Di 3:18
  • +Joṣ 1:16

Jóṣúà 22:3

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 11:18
  • +Nọ 32:25-27

Jóṣúà 22:4

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ìyẹn, apá ìlà oòrùn.

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 21:44
  • +Nọ 32:33

Jóṣúà 22:5

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Wo Àlàyé Ọ̀rọ̀, “Ọkàn.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 6:6; 12:32; 2Ọb 21:8
  • +Di 6:5; 11:1; Mt 22:37
  • +Di 10:12
  • +Di 13:4; 1Jo 5:3
  • +Di 4:4; 10:20; Joṣ 23:8
  • +Di 4:29; 11:13; Mk 12:30, 33
  • +Di 6:13; Joṣ 24:15; Lk 4:8

Jóṣúà 22:7

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 13:29, 30
  • +Joṣ 17:5

Jóṣúà 22:8

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 28:8
  • +Nọ 31:27

Jóṣúà 22:9

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 32:1
  • +Nọ 32:33

Jóṣúà 22:10

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́ (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́),

    8/2018, ojú ìwé 5-6

Jóṣúà 22:11

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 13:12-15

Jóṣúà 22:12

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 18:1; 19:51

Jóṣúà 22:13

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 6:25; Nọ 25:11; Ond 20:28

Jóṣúà 22:14

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “agbo ilé.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 1:16; Di 1:13

Jóṣúà 22:16

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 22:11, 12
  • +Di 12:13, 14

Jóṣúà 22:17

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 25:3, 9; Di 4:3

Jóṣúà 22:18

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 7:1; 1Kr 21:14

Jóṣúà 22:19

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 34:2; Joṣ 1:11
  • +Joṣ 18:1
  • +Di 12:13, 14

Jóṣúà 22:20

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 7:1
  • +Joṣ 7:11, 15
  • +Joṣ 7:5, 24, 25

Jóṣúà 22:21

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “agbo ilé.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 22:13, 14

Jóṣúà 22:22

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “Jèhófà, Ọlọ́run, Olú Ọ̀run.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 10:17

Jóṣúà 22:23

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 12:11, 13

Jóṣúà 22:25

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “bẹ̀rù.”

Jóṣúà 22:27

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “àwọn ìran.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jẹ 31:48; Joṣ 24:27
  • +Di 12:5, 6

Jóṣúà 22:29

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 6:14
  • +Di 12:14

Jóṣúà 22:30

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “agbo ilé.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 22:13, 14

Jóṣúà 22:34

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Pẹ̀lú àlàyé tí wọ́n ṣe yìí, ó ṣeé ṣe kó jẹ́ pé Ẹ̀rí ni wọ́n pe pẹpẹ náà.

Àwọn míì

Jóṣ. 22:2Nọ 32:20-22; Di 3:18
Jóṣ. 22:2Joṣ 1:16
Jóṣ. 22:3Joṣ 11:18
Jóṣ. 22:3Nọ 32:25-27
Jóṣ. 22:4Joṣ 21:44
Jóṣ. 22:4Nọ 32:33
Jóṣ. 22:5Di 6:6; 12:32; 2Ọb 21:8
Jóṣ. 22:5Di 6:5; 11:1; Mt 22:37
Jóṣ. 22:5Di 10:12
Jóṣ. 22:5Di 13:4; 1Jo 5:3
Jóṣ. 22:5Di 4:4; 10:20; Joṣ 23:8
Jóṣ. 22:5Di 4:29; 11:13; Mk 12:30, 33
Jóṣ. 22:5Di 6:13; Joṣ 24:15; Lk 4:8
Jóṣ. 22:7Joṣ 13:29, 30
Jóṣ. 22:7Joṣ 17:5
Jóṣ. 22:8Di 28:8
Jóṣ. 22:8Nọ 31:27
Jóṣ. 22:9Nọ 32:1
Jóṣ. 22:9Nọ 32:33
Jóṣ. 22:11Di 13:12-15
Jóṣ. 22:12Joṣ 18:1; 19:51
Jóṣ. 22:13Ẹk 6:25; Nọ 25:11; Ond 20:28
Jóṣ. 22:14Nọ 1:16; Di 1:13
Jóṣ. 22:16Joṣ 22:11, 12
Jóṣ. 22:16Di 12:13, 14
Jóṣ. 22:17Nọ 25:3, 9; Di 4:3
Jóṣ. 22:18Joṣ 7:1; 1Kr 21:14
Jóṣ. 22:19Nọ 34:2; Joṣ 1:11
Jóṣ. 22:19Joṣ 18:1
Jóṣ. 22:19Di 12:13, 14
Jóṣ. 22:20Joṣ 7:1
Jóṣ. 22:20Joṣ 7:11, 15
Jóṣ. 22:20Joṣ 7:5, 24, 25
Jóṣ. 22:21Joṣ 22:13, 14
Jóṣ. 22:22Di 10:17
Jóṣ. 22:23Di 12:11, 13
Jóṣ. 22:27Jẹ 31:48; Joṣ 24:27
Jóṣ. 22:27Di 12:5, 6
Jóṣ. 22:29Di 6:14
Jóṣ. 22:29Di 12:14
Jóṣ. 22:30Joṣ 22:13, 14
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
  • 1
  • 2
  • 3
  • 4
  • 5
  • 6
  • 7
  • 8
  • 9
  • 10
  • 11
  • 12
  • 13
  • 14
  • 15
  • 16
  • 17
  • 18
  • 19
  • 20
  • 21
  • 22
  • 23
  • 24
  • 25
  • 26
  • 27
  • 28
  • 29
  • 30
  • 31
  • 32
  • 33
  • 34
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
Jóṣúà 22:1-34

Jóṣúà

22 Jóṣúà wá ránṣẹ́ pe àwọn ọmọ Rúbẹ́nì, àwọn ọmọ Gádì àti ààbọ̀ ẹ̀yà Mánásè, 2 ó sì sọ fún wọn pé: “Ẹ ti ṣe gbogbo ohun tí Mósè ìránṣẹ́ Jèhófà pa láṣẹ fún yín,+ ẹ sì ti tẹ̀ lé gbogbo ohun tí mo pa láṣẹ fún yín.+ 3 Ẹ ò pa àwọn arákùnrin yín tì ní gbogbo àsìkò yìí, títí dòní;+ ẹ sì ń ṣe àwọn ohun tí Jèhófà Ọlọ́run yín pa láṣẹ.+ 4 Jèhófà Ọlọ́run yín ti wá fún àwọn arákùnrin yín ní ìsinmi, bó ṣe ṣèlérí fún wọn.+ Torí náà, ẹ lè pa dà sí àgọ́ yín ní ilẹ̀ tí Mósè ìránṣẹ́ Jèhófà fún yín pé kí ẹ jogún ní òdìkejì* Jọ́dánì.+ 5 Kí ẹ ṣáà rí i pé ẹ̀ ń tẹ̀ lé àṣẹ àti Òfin tí Mósè ìránṣẹ́ Jèhófà fún yín,+ kí ẹ máa nífẹ̀ẹ́ Jèhófà Ọlọ́run yín,+ kí ẹ máa rìn ní gbogbo ọ̀nà rẹ̀,+ kí ẹ máa pa àwọn àṣẹ rẹ̀ mọ́,+ kí ẹ rọ̀ mọ́ ọn,+ kí ẹ sì máa fi gbogbo ọkàn yín àti gbogbo ara* yín+ sìn ín.”+

6 Jóṣúà wá súre fún wọn, ó ní kí wọ́n máa lọ, wọ́n sì lọ sí àgọ́ wọn. 7 Mósè ti fún ààbọ̀ ẹ̀yà Mánásè ní ogún ní Báṣánì,+ Jóṣúà sì ti fún ààbọ̀ ẹ̀yà náà tó kù àti àwọn arákùnrin wọn ní ilẹ̀ ní ìwọ̀ oòrùn Jọ́dánì.+ Bákan náà, nígbà tí Jóṣúà ní kí wọ́n máa lọ sí àgọ́ wọn, ó súre fún wọn, 8 ó sì sọ fún wọn pé: “Ẹ kó ọ̀pọ̀lọpọ̀ ohun ìní pa dà lọ sí àgọ́ yín, pẹ̀lú ẹran ọ̀sìn tó pọ̀, fàdákà àti wúrà, bàbà àti irin àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ aṣọ.+ Ẹ kó ìpín yín nínú ẹrù àwọn ọ̀tá yín,+ ẹ̀yin àtàwọn arákùnrin yín.”

9 Lẹ́yìn náà, àwọn ọmọ Rúbẹ́nì, àwọn ọmọ Gádì àti ààbọ̀ ẹ̀yà Mánásè kúrò lọ́dọ̀ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì yòókù, ní Ṣílò, ní ilẹ̀ Kénáánì, wọ́n sì pa dà sí ilẹ̀ Gílíádì,+ ilẹ̀ tí wọ́n jogún tí wọ́n sì ń gbé bí Jèhófà ṣe pa á láṣẹ nípasẹ̀ Mósè.+ 10 Nígbà tí wọ́n dé agbègbè Jọ́dánì ní ilẹ̀ Kénáánì, àwọn ọmọ Rúbẹ́nì, àwọn ọmọ Gádì àti ààbọ̀ ẹ̀yà Mánásè mọ pẹpẹ kan síbẹ̀ lẹ́gbẹ̀ẹ́ Jọ́dánì, pẹpẹ náà tóbi, ó sì fani mọ́ra. 11 Nígbà tó yá, àwọn ọmọ Ísírẹ́lì yòókù gbọ́+ táwọn èèyàn sọ pé: “Ẹ wò ó! Àwọn ọmọ Rúbẹ́nì, àwọn ọmọ Gádì àti ààbọ̀ ẹ̀yà Mánásè ti mọ pẹpẹ kan sí ààlà ilẹ̀ Kénáánì ní agbègbè Jọ́dánì, lápá ibi tó jẹ́ ti àwọn ọmọ Ísírẹ́lì.” 12 Nígbà tí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì gbọ́ nípa rẹ̀, gbogbo àpéjọ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì kóra jọ ní Ṣílò+ láti lọ bá wọn jà.

13 Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì wá rán Fíníhásì+ ọmọ àlùfáà Élíásárì sí àwọn ọmọ Rúbẹ́nì, àwọn ọmọ Gádì àti ààbọ̀ ẹ̀yà Mánásè ní ilẹ̀ Gílíádì, 14 ìjòyè mẹ́wàá sì bá a lọ, ìjòyè kan látinú agbo ilé kọ̀ọ̀kan ní gbogbo ẹ̀yà Ísírẹ́lì, ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn jẹ́ olórí agbo ilé bàbá rẹ̀ láàárín àwọn ẹgbẹẹgbẹ̀rún* Ísírẹ́lì.+ 15 Nígbà tí wọ́n dé ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Rúbẹ́nì, àwọn ọmọ Gádì àti ààbọ̀ ẹ̀yà Mánásè ní ilẹ̀ Gílíádì, wọ́n sọ fún wọn pé:

16 “Ohun tí gbogbo àpéjọ Jèhófà sọ nìyí: ‘Irú ìwà ọ̀dàlẹ̀ wo lẹ hù sí Ọlọ́run Ísírẹ́lì yìí?+ Ẹ ti pa dà lẹ́yìn Jèhófà lónìí, torí pé ẹ mọ pẹpẹ kan fún ara yín, ẹ sì wá ṣọ̀tẹ̀ sí Jèhófà.+ 17 Ṣé ẹ̀ṣẹ̀ tí a dá ní Péórì kò tíì tó wa ni? A ò tíì wẹ ara wa mọ́ nínú rẹ̀ títí dòní, láìka ti àjàkálẹ̀ àrùn tó jà láàárín àpéjọ Jèhófà.+ 18 Ẹ wá fẹ́ pa dà lẹ́yìn Jèhófà lónìí! Tí ẹ bá ṣọ̀tẹ̀ sí Jèhófà lónìí, ó máa bínú sí gbogbo àpéjọ Ísírẹ́lì lọ́la.+ 19 Tó bá jẹ́ torí pé ilẹ̀ yín jẹ́ aláìmọ́ ni, ẹ sọdá sí ilẹ̀ Jèhófà+ níbi tí àgọ́ ìjọsìn Jèhófà wà,+ kí ẹ sì máa gbé láàárín wa, àmọ́ ẹ má ṣọ̀tẹ̀ sí Jèhófà, ẹ má sì mọ pẹpẹ fún ara yín yàtọ̀ sí pẹpẹ Jèhófà Ọlọ́run wa, kí ẹ sì fìyẹn sọ wá di ọlọ̀tẹ̀.+ 20 Nígbà tí Ákánì+ ọmọ Síírà hùwà àìṣòótọ́ lórí ọ̀rọ̀ ohun tí a máa pa run, ṣebí gbogbo àpéjọ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ni Ọlọ́run bínú sí?+ Òun nìkan kọ́ ló kú torí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.’”+

21 Ni àwọn ọmọ Rúbẹ́nì, àwọn ọmọ Gádì àti ààbọ̀ ẹ̀yà Mánásè bá dá àwọn olórí ẹgbẹẹgbẹ̀rún* Ísírẹ́lì+ lóhùn pé: 22 “Jèhófà, Ọlọ́run àwọn ọlọ́run!* Jèhófà, Ọlọ́run àwọn ọlọ́run!+ Ó mọ̀, Ísírẹ́lì náà sì máa mọ̀. Tí a bá ṣọ̀tẹ̀, tí a sì dalẹ̀ Jèhófà, má ṣe dá ẹ̀mí wa sí lónìí. 23 Tó bá jẹ́ torí ká lè pa dà lẹ́yìn Jèhófà la ṣe mọ pẹpẹ, ká sì lè máa rú àwọn ẹbọ sísun, ọrẹ ọkà àti ẹbọ ìrẹ́pọ̀ lórí rẹ̀, kí Jèhófà fìyà jẹ wá.+ 24 Ọ̀rọ̀ ò rí bẹ́ẹ̀ rárá, nǹkan míì la rò tí a fi ṣe bẹ́ẹ̀, torí a sọ pé, ‘Lọ́jọ́ iwájú, àwọn ọmọ yín máa sọ fún àwọn ọmọ wa pé: “Kí ló pa ẹ̀yin àti Jèhófà Ọlọ́run Ísírẹ́lì pọ̀? 25 Jèhófà ti fi Jọ́dánì ṣe ààlà láàárín àwa àti ẹ̀yin, àwọn ọmọ Rúbẹ́nì àti àwọn ọmọ Gádì. Ẹ ò ní ìpín kankan lọ́dọ̀ Jèhófà.” Àwọn ọmọ yín ò sì ní jẹ́ kí àwọn ọmọ wa jọ́sìn* Jèhófà.’

26 “Torí náà, a sọ pé, ‘Ẹ jẹ́ ká rí i pé a ṣe nǹkan kan, ká mọ pẹpẹ kan, kì í ṣe fún ẹbọ sísun tàbí àwọn ẹbọ, 27 àmọ́ kó lè jẹ́ ẹ̀rí láàárín ẹ̀yin àti àwa+ pẹ̀lú àwọn àtọmọdọ́mọ* wa lẹ́yìn wa pé a máa fi àwọn ẹbọ sísun wa, àwọn ẹbọ wa àti àwọn ẹbọ ìrẹ́pọ̀+ wa jọ́sìn Jèhófà níwájú rẹ̀, kí àwọn ọmọ yín má bàa sọ fún àwọn ọmọ wa lọ́jọ́ iwájú pé: “Ẹ ò ní ìpín kankan lọ́dọ̀ Jèhófà.”’ 28 A wá sọ pé, ‘Tí wọ́n bá sọ bẹ́ẹ̀ fún àwa àti àwọn àtọmọdọ́mọ wa lọ́jọ́ iwájú, a máa sọ pé: “Ẹ wo irú pẹpẹ Jèhófà tí àwọn baba ńlá wa mọ, kì í ṣe fún ẹbọ sísun tàbí fún àwọn ẹbọ, àmọ́ ó jẹ́ ẹ̀rí láàárín ẹ̀yin àti àwa.”’ 29 Kò ṣeé gbọ́ pé a ṣọ̀tẹ̀ sí Jèhófà, ká sì pa dà lẹ́yìn Jèhófà+ lónìí torí pé a mọ pẹpẹ láti máa fi rú ẹbọ sísun, ọrẹ ọkà àti àwọn ẹbọ, yàtọ̀ sí pẹpẹ Jèhófà Ọlọ́run wa tó wà níwájú àgọ́ ìjọsìn rẹ̀!”+

30 Nígbà tí Fíníhásì àlùfáà, àwọn ìjòyè àpéjọ náà àti àwọn olórí ẹgbẹẹgbẹ̀rún* Ísírẹ́lì tí wọ́n wà pẹ̀lú rẹ̀ gbọ́ ohun tí àwọn àtọmọdọ́mọ Rúbẹ́nì, Gádì àti àwọn ọmọ Mánásè sọ, ó tẹ́ wọn lọ́rùn.+ 31 Ni Fíníhásì ọmọ àlùfáà Élíásárì bá sọ fún àwọn àtọmọdọ́mọ Rúbẹ́nì, Gádì àti àwọn ọmọ Mánásè pé: “Lónìí, a mọ̀ pé Jèhófà wà láàárín wa, torí ẹ ò hùwà ọ̀dàlẹ̀ yìí sí Jèhófà. Ẹ ti gba àwọn ọmọ Ísírẹ́lì sílẹ̀ lọ́wọ́ Jèhófà.”

32 Fíníhásì ọmọ àlùfáà Élíásárì àti àwọn ìjòyè wá kúrò lọ́dọ̀ àwọn ọmọ Rúbẹ́nì àti àwọn ọmọ Gádì ní ilẹ̀ Gílíádì lọ sí ilẹ̀ Kénáánì, wọ́n sì wá jábọ̀ fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì tó kù. 33 Ìròyìn náà tẹ́ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì lọ́rùn. Torí náà, àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ń yin Ọlọ́run, wọn ò sì sọ pé àwọn máa lọ bá àwọn ọmọ Rúbẹ́nì àti àwọn ọmọ Gádì jà mọ́, kí wọ́n lè run ilẹ̀ tí wọ́n ń gbé.

34 Àwọn ọmọ Rúbẹ́nì àti àwọn ọmọ Gádì wá sọ pẹpẹ náà lórúkọ,* torí pé “ó jẹ́ ẹ̀rí láàárín wa pé Jèhófà ni Ọlọ́run tòótọ́.”

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́